< Jeremiah 38 >

1 Ṣefatia ọmọ Mattani, Gedaliah ọmọ Paṣuri, Jehukali ọmọ Ṣelemiah, àti Paṣuri ọmọ Malkiah, gbọ́ ohun tí Jeremiah ń sọ fún àwọn ènìyàn nígbà tí ó sọ wí pé,
[Four officials, ] Shephatiah the son of Mattan, Gedaliah the son of Pashhur, Jehucal the son of Shelemiah, and Pashhur the son of Malkijah, heard what I had been telling all the people.
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ẹnikẹ́ni tó bá dúró nínú ìlú yìí yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tó bá lọ sí Babeli yóò yè; yóò sá àsálà, yóò sì yè.’
[I had been telling them] that Yahweh was saying, “Everyone who stays in Jerusalem will die. They will be killed by [their enemies’] swords or from famines or from diseases. But those who surrender to the Babylonian army, they will be spared. They will not be killed.
3 Àti pé èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Ìdánilójú wà wí pé a ó fi ìlú náà lé ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun ọba Babeli; tí yóò sì kó wa nígbèkùn.’”
Yahweh also says that the army of the King of Babylon will certainly capture this city [DOU].”
4 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè wí fún ọba pé, “Ó yẹ kí a pa ọkùnrin yìí; ó ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ-ogun tókù nínú ìlú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn nípa ohun tí ó ń sọ fún wọn. Ọkùnrin yìí kò fẹ́ ìre fún àwọn ènìyàn bí kò ṣe ìparun.”
So those officials [went] to the king and said, “This man [Jeremiah] should be executed! Because of what he is saying, he is discouraging our soldiers who remain in the city. He is also discouraging the people. He is not saying things that will help us; he is saying things that will defeat us.”
5 Sedekiah ọba sì wí pé, “Ó wà lọ́wọ́ yín. Ọba kò lè ṣe ohunkóhun láti takò yín.”
King Zedekiah said, “All right, do to him what you want to; I do not have the power to stop you.”
6 Wọ́n gbé Jeremiah sọ sínú ihò Malkiah, ọmọ ọba, tí ó wà ní àgbàlá ilé túbú; wọ́n fi okùn sọ Jeremiah kalẹ̀ sí ìsàlẹ̀ ihò; kò sì ṣí omi nínú ihò náà bí kò ṣe ẹrọ̀fọ̀, Jeremiah sì rì sínú ẹrọ̀fọ̀ náà.
So those officials took me from my cell and lowered me by ropes into a well in the courtyard. The well belonged to Malkijah, who was a son of the king. There was no water in the well, but there was [a lot of] mud, so I sank [down deep] into the mud.
7 Ṣùgbọ́n, Ebedimeleki, ará Kuṣi ìjòyè nínú ààfin ọba gbọ́ pé wọ́n ti ju Jeremiah sínú kànga. Nígbà tí ọba jókòó ní ẹnu-bodè Benjamini.
But Ebed-Melech, a palace official from Ethiopia, heard [someone say] that I was in the well. [At that time] the king was deciding/judging people’s cases at the Benjamin Gate.
8 Ebedimeleki jáde kúrò láàfin ọba, ó sì sọ fún un pé,
Ebed-Melech went out of the palace and said to the king,
9 “Olúwa mi ọba, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti ṣe ohun búburú sí Jeremiah wòlíì Ọlọ́run. Wọ́n ti gbé e sọ sínú kànga níbi tí kò sí oúnjẹ kankan nínú ìlú mọ́.”
“Your majesty, those men have done a very evil thing. They have put the prophet Jeremiah in a well. [Almost] all the food in the city is gone, [so they will not be able to bring him any food] and as a result he will die from hunger!”
10 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Ebedimeleki ará Kuṣi pé, “Mú ọgbọ̀n ọkùnrin láti ibí pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì fa wòlíì Jeremiah sókè láti inú ihò, kí ó tó kú.”
So the king told Ebed-Melech, “Take thirty of my men/soldiers with you, and pull Jeremiah out of the well, in order that he does not die!”
11 Ebedimeleki kó àwọn ọkùnrin náà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n lọ sínú yàrá kan nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn aṣọ àkísà àti okùn tọ Jeremiah lọ nínú kànga.
So Ebed-Melech took thirty men with him and they went into a room in the palace below the room where they stored very valuable things. There they found some old rags and discarded clothing. They took those things and went to the well. They fastened them to a rope and lowered the rope to me.
12 Ebedimeleki ará Kuṣi sọ fún Jeremiah pé, “Fi àkísà àti okùn bọ abẹ́ abíyá rẹ, Jeremiah sì ṣe bẹ́ẹ̀.”
Then Ebed-Melech called down to me, “Put these rags underneath your armpits, to protect you from [being injured by] the ropes!” So I did that.
13 Báyìí ni wọ́n ṣe fi okùn yọ Jeremiah jáde, wọ́n sì mu un gòkè láti inú ihò wá, Jeremiah sì wà ní àgbàlá ilé túbú.
Then they pulled me out of the well. I [returned] to the courtyard where the palace guards stayed, and I stayed there.
14 Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ pe, Jeremiah òjíṣẹ́ Ọlọ́run àti láti mú un wá sí ẹnu ibodè kẹta nílé Olúwa. Ọba sì sọ fún Jeremiah pé, “Èmi yóò bi ọ́ ní ohun kan; má sì ṣe fi ohun kan pamọ́ fún mi.”
[One day] King Zedekiah summoned me, and I was brought to the king, [who was waiting for me] at the entrance of the temple. He said to me, “I want to ask you something. I want you [to answer me truthfully, and] and to not conceal anything.”
15 Jeremiah sì sọ fún Sedekiah pé, “Tí mo bá fún ọ ní èsì, ṣé o kò nípa mí? Tí mo bá gbà ọ́ nímọ̀ràn, o kò ní gbọ́ tèmi.”
I replied, “If I tell you [the truth], you will [command that I] be executed. And if I give you [good] advice, you will not pay attention to what I say.”
16 Ṣùgbọ́n ọba Sedekiah búra ní ìkọ̀kọ̀ fún Jeremiah wí pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó fún wa ní ẹ̀mí, èmi kò nípa ọ́ tàbí fà ọ́ fún àwọn tó ń lépa ẹ̀mí rẹ.”
But King Zedekiah secretly promised me, “[Tell me the truth]! And as surely as Yahweh lives, I will not [cause] you to be executed, and I will not hand you over to those who are wanting to kill you.”
17 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún Sedekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Àyàfi bí o bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn olóyè ọba Babeli, a ó dá ẹ̀mí rẹ sí àti pé ìlú yìí kò ní di jíjó ní iná; ìwọ àti ilé rẹ yóò sì wà láààyè.
[So] then I said to Zedekiah, “This is what the Commander of the armies of angels, the God whom [we] Israelis [worship], says: ‘If you surrender to the officers of the king of Babylon, you and your family will (be spared/not be killed), and this city will not be burned.
18 Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè ọba Babeli, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Babeli. Wọn yóò sì fi iná sun ún, ìwọ gan an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’”
But if you refuse to surrender to them, you will not escape. And the army from Babylonia will capture this city and completely burn it.’”
19 Ọba Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Babeli, nítorí pé àwọn ará Babeli lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”
The king replied, “But I am afraid [to surrender to the soldiers from Babylon], because their officers may hand me over to the people of Judah who have already joined the soldiers from Babylonia, and those people from Judah will mistreat me.”
20 Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.
I replied, “If you obey Yahweh by doing what I tell you to do, they will not hand you over to our people. Things will go well for you, and you will remain alive.
21 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fihàn mí.
But if you refuse to surrender, this is what Yahweh has revealed to me:
22 Gbogbo àwọn obìnrin tókù ní ààfin ọba Juda ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè ọba Babeli. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé: “‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì borí rẹ. Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú ẹrọ̀fọ̀; àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’
All the women who remain in your palace will be brought out and given to the officers of the king of Babylon. Then those women will say to you: ‘You had friends whom [you thought] you could trust, but they have deceived you and caused you to make a wrong decision. Now [it is as though] you are stuck in mud, and your friends have abandoned you.’
23 “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Babeli. Ìwọ gan an kò ní bọ́ níbẹ̀, ọba Babeli yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”
All of your wives and children [in the city] will be led out to the soldiers from Babylonia, and you also will not escape. [The soldiers of] the King of Babylon will seize you, and they will burn down this city.”
24 Nígbà náà ni Sedekiah sọ fún Jeremiah pé, “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, tàbí kí o kú.
Then Zedekiah said to me, “Do not tell anyone what you told me; if you tell anyone, my officials may kill you.
25 Tí àwọn ìjòyè bá mọ̀ pé mo bá ọ sọ̀rọ̀, tí wọ́n bá wá bá ọ wí pé, ‘Sọ fún wa ohun tí o bá ọba sọ tàbí ohun tí ọba sọ fún ọ; má ṣe fi pamọ́ fún wa tàbí kí a pa ọ́,’
If my officials find out that I talked to you, perhaps they will come to you and say, ‘Tell us what you and the king were talking about. If you do not tell us, we will kill you.’
26 nígbà náà kí o sọ fún wọn, ‘Mò ń bẹ ọba láti má jẹ́ kí n padà lọ sí ilé Jonatani láti lọ kú síbẹ̀.’”
If that happens, [just] tell them that you pleaded with me not to send you back to the [dungeon/cell in] Jonathan’s house, [because you were afraid that] you would die [if you were put there again].”
27 Gbogbo àwọn olóyè sì wá sí ọ̀dọ̀ Jeremiah láti bi í léèrè, ó sì sọ gbogbo ohun tí ọba ní kí ó sọ. Wọn kò sì sọ ohunkóhun mọ́, nítorí kò sí ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ tí òun àti ọba jọ sọ.
And [that is what happened]. The king’s officials came to me and asked [why the king had summoned me. But] I told them what the king told me to tell them. So they did not ask me any more [questions], because no one had heard what the king and I had said to each other.
28 Jeremiah wà nínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́ títí di ọjọ́ tí wọ́n fi kó Jerusalẹmu:
So I remained being guarded in the courtyard [of the palace], until the day that [the army of Babylonia] captured Jerusalem.

< Jeremiah 38 >