< Jeremiah 37 >

1 Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
Potem królował król Sedekiasz, syn Jozjasza, w miejsce Choniasza, syna Joakima, którego Nabuchodonozor, król Babilonu, ustanowił królem w ziemi Judy.
2 Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
Lecz ani on, ani jego słudzy, ani lud tej ziemi nie słuchali słów PANA, które wypowiedział przez proroka Jeremiasza.
3 Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Król Sedekiasz jednak posłał Jehuchala, syna Szelemiasza, i Sofoniasza, syna Maasejasza, kapłana, do proroka Jeremiasza, aby powiedzieli: Módl się za nas do PANA, naszego Boga.
4 Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
Jeremiasz zaś chodził swobodnie wśród ludu, gdyż jeszcze nie wtrącono go do więzienia.
5 Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
Tymczasem wojsko faraona wyruszyło z Egiptu. A gdy usłyszeli tę wieść Chaldejczycy oblegający Jerozolimę, odstąpili od Jerozolimy.
6 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
I słowo PANA doszło do proroka Jeremiasza mówiące:
7 “Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
To mówi PAN, Bóg Izraela: Tak powiedzcie królowi Judy, który posłał was do mnie, abyście się mnie radzili: Oto wojsko faraona, które wyruszyło wam na pomoc, wróci do swojej ziemi, do Egiptu.
8 Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
I Chaldejczycy powrócą, i będą walczyli przeciwko temu miastu, zdobędą je i spalą ogniem.
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
Tak mówi PAN: Nie zwódźcie samych siebie, mówiąc: Z pewnością Chaldejczycy odstąpią od nas. Bo nie odstąpią.
10 Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
Choćbyście nawet pobili całe wojsko Chaldejczyków, którzy walczą z wami, i zostaliby z nich tylko ranni, to [ci] powstaliby ze swoich namiotów i ogniem spaliliby to miasto.
11 Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
A gdy wojsko Chaldejczyków odstąpiło od Jerozolimy przed wojskiem faraona;
12 Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
Jeremiasz wychodził z Jerozolimy, aby udać się do ziemi Beniamina, by tym sposobem ujść stamtąd pośród ludu.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
A gdy był [już] w Bramie Beniamina, znajdował się tam dowódca straży, imieniem Jirijasz, syn Szelemiasza, syna Chananiasza; ten pojmał proroka Jeremiasza, mówiąc: Przechodzisz do Chaldejczyków!
14 Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
Jeremiasz odpowiedział: Nieprawda, nie przechodzę do Chaldejczyków. Ale [tamten] nie chciał go słuchać. Jirijasz pojmał Jeremiasza i przyprowadził go do książąt.
15 Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
Książęta rozgniewali się na Jeremiasza, bili go i wsadzili do więzienia w domu Jonatana, pisarza, bo ten zamieniono na więzienie.
16 Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
A gdy Jeremiasz wszedł do tego lochu i do celi, i siedział tam Jeremiasz przez wiele dni;
17 Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
Wtedy król Sedekiasz posłał, aby go przyprowadzono. I król wypytywał go potajemnie w swoim domu: Czy jest [jakieś] słowo od PANA? Jeremiasz odpowiedział: Jest. I dodał: Będziesz wydany w ręce króla Babilonu.
18 Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
Nadto Jeremiasz powiedział do króla Sedekiasza: Czym zgrzeszyłem [przeciwko] tobie, twoim sługom lub twemu ludowi, że wsadziliście mnie do tego więzienia?
19 Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
Gdzie są wasi prorocy, którzy wam prorokowali, mówiąc: Król Babilonu nie nadciągnie przeciwko wam ani przeciwko tej ziemi.
20 Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
Teraz więc słuchaj, proszę, królu, mój panie. Niech moja prośba dotrze do ciebie: Nie odsyłaj mnie do domu Jonatana, pisarza, abym tam nie umarł.
21 Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.
Król Sedekiasz rozkazał więc oddać Jeremiasza pod straż na dziedzińcu więzienia i aby dawano mu bochenek chleba dziennie z ulicy Piekarzy, póki nie został wyczerpany cały chleb w mieście. A Jeremiasz pozostał na dziedzińcu więzienia.

< Jeremiah 37 >