< Jeremiah 36 >
1 Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
Yehuda padishahi Yosiyaning oghli Yehoakimning tötinchi yili, Yeremiyagha Perwerdigardin töwendiki söz keldi: —
2 “Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
Özüngge oram qeghez alghin; uninggha Yosiyaning künliride sanga söz qilghinimdin tartip bügünki kün’giche Men Israilni eyibligen, Yehudani eyibligen hem barliq ellerni eyibligen, sanga éytqan sözlerning hemmisini yazghin.
3 Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
Yehudaning jemeti belkim Men béshigha chüshürmekchi bolghan barliq balayi’apetni anglap, herbiri özlirining rezil yolidin yanarmikin; ular shundaq qilsa, Men ularning qebihlikini we gunahini kechürüm qilimen.
4 Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
Shuning bilen Yeremiya Nériyaning oghli Baruqni chaqirdi; Baruq Yeremiyaning aghzidin chiqqanlirini anglap Perwerdigarning uninggha éytqan sözlirining hemmisini bir oram qeghezge yézip berdi.
5 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
Yeremiya Baruqqa tapilap mundaq dédi: — Özüm qamap qoyulghanmen; Perwerdigarning öyige kirishimge ruxset yoq; lékin özüng bérip kirgin;
6 Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
Perwerdigarning öyide roza tutqan bir künide, sen aghzimdin chiqqanlirini anglap yazghan, Perwerdigarning bu oram yazmida xatirilen’gen sözlirini xelqning qulaqlirigha yetküzgin; hemme sheherlerdin kelgen Yehudadikilerning quliqighimu yetküzgin.
7 Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
Ular belkim Perwerdigar aldigha dua-tilawitini qilip herbiri özlirining rezil yolidin yanarmikin; chünki Perwerdigarning bu xelqqe agahlandurghan ghezipi we qehri dehshetliktur.
8 Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
Nériyaning oghli Baruq Yeremiya peyghember uninggha tapilighinining hemmisini ada qilip, Perwerdigarning öyide Perwerdigarning sözlirini oqup jakarlidi.
9 Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
Yehuda padishahi Yosiyaning oghli Yehoakim textke olturghan beshinchi yili toqquzinchi ayda shundaq boldiki, barliq Yérusalémdikiler hemde Yehuda sheherliridin chiqip Yérusalémgha kelgen barliq xelq üchün, Perwerdigar aldida bir mezgil roza tutushimiz kérek dep élan qilindi.
10 Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
Shu waqit Baruq Perwerdigarning öyige kirip, pütükchi Shafanning oghli Gemariyaning öyide turup, Yeremiyaning sözlirini barliq xelqning quliqigha yetküzüp oqudi; bu öy Perwerdigarning öyining yuqiriqi hoylisidiki «Yéngi derwaza»gha jaylashqanidi.
11 Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
Shafanning newrisi, Gemariyaning oghli Mikah bolsa yazmidin Perwerdigarning sözlirining hemmisige qulaq saldi.
12 Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
Andin u padishahning ordisigha chüshüp pütükchining öyige kiriwidi, mana, emirlerning hemmisi shu yerde olturatti; pütükchi Elishama, Shémayaning oghli Délaya, Akborning oghli Elnatan, Shafanning oghli Gemariya we Hananiyaning oghli Zedekiya qatarliq barliq emirler shu yerde olturatti.
13 Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
Shuning bilen Mikah Baruqning sözligenlirini xelqning quliqigha yetküzüp oqughanda özi anglighan barliq sözlerni ulargha bayan qildi.
14 Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
Shuning bilen barliq emirler Kushining ewrisi, Shelemiyaning newrisi, Netaniyaning oghli Yehudiyni Baruqning yénigha ewetip uninggha: «Sen xelqning quliqigha yetküzüp oqughan oram yazmini qolunggha élip yénimizgha kel» — dédi. Shuning bilen Nériyaning oghli Baruq oram yazmini qoligha élip ularning yénigha keldi.
15 Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!” Nígbà náà ni Baruku sì kà á ní etí wọn.
Ular uninggha: «Oltur, uni quliqimizgha yetküzüp oqup ber» — dédi. Baruq uni ulargha anglitip oqudi.
16 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
Shundaq boldiki, ular barliq sözlerni anglighanda, alaqzade bolup bir-birige qariship: «Bu sözlerning hemmisini padishahqa yetküzmisek bolmaydu» — dédi.
17 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
Andin Baruqtin: «Bizge dégin emdi, sen bu sözlerning hemmisini qandaq yazding? Ularni Yeremiyaning öz aghzidin anglidingmu?» — dep soridi.
18 Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
Baruq ulargha: «U bu sözlerning hemmisini öz aghzi bilen manga éytti, men oram qeghezge siyah bilen yazdim» — dédi.
19 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
Emirler Baruqqa: «Barghin, sen we Yeremiya möküwélinglar. Qeyerde bolsanglar héchkimge bildürmenglar» — dédi.
20 Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
Shuning bilen ular oram yazmini pütükchi Elishamaning öyige tiqip qoyup, ordigha kirip padishahning yénigha kélip, bu barliq sözlerni uning quliqigha yetküzdi.
21 Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
Padishah Yehudiyni yazmini élip kélishke ewetti, u uni Elishamaning öyidin épkeldi. Yehudiy uni padishahning quliqigha we padishahning yénida turghan barliq emirlerning qulaqlirigha yetküzüp oqudi.
22 Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
Shu chagh toqquzinchi ay bolup, padishah «qishliq öy»ide olturatti; uning aldidiki ochaqta ot qalaqliq idi.
23 Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
Shundaq boldiki, Yehudiy uningdin üch-töt sehipini oqughanda, padishah qelemtirashi bilen bu qismini késip, yazmining hemmisini bir-birlep otta köyüp yoqighuche ochaqtiki otqa tashlidi.
24 Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
Lékin bu barliq sözlerni anglighan padishah yaki xizmetkarlirining héchqaysisi qorqmidi, ulardin kiyim-kécheklirini yirtqanlar yoq idi.
25 Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
Uning üstige Elnatan, Délaya we Gemariyalar padishahtin oram yazmini köydürmeslikini ötün’genidi, lékin u ulargha qulaq salmidi.
26 Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
Padishah bolsa shahzade Yérahmeel, Azrielning oghli Séraya we Abdeelning oghli Shelemiyani pütükchi Baruqni we Yeremiya peyghemberni qolgha élishqa ewetti; lékin Perwerdigar ularni yoshurup saqlidi.
27 Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
Padishah Baruq Yeremiyaning aghzidin anglap yazghan sözlerni xatiriligen oram yazmini köydürüwetkendin kéyin, Perwerdigarning sözi Yeremiyagha kélip mundaq déyildi: —
28 “Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
Yene bir oram qeghezni élip, uninggha Yehuda padishahi Yehoakim köydürüwetken birinchi oram yazmida xatirilen’gen barliq sözlerni yazghin.
29 Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
We Yehuda padishahi Yehoakimgha mundaq dégin: — Perwerdigar mundaq deydu: — Sen bu oram yazmini köydürüwetting we Méning toghruluq: Sen buninggha: «Babil padishahi choqum kélip bu zéminni weyran qilidu, uningdin hem insanni hem haywanni yoqitidu» — dep yézishqa qandaqmu pétinding?» — déding.
30 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
Shunga Perwerdigar Yehuda padishahi Yehoakim toghruluq mundaq deydu: — Uning neslidin Dawutning textige olturushqa héch adem bolmaydu; uning jesiti sirtqa tashliwétilip kündüzde issiqta, kéchide qirawda ochuq yatidu.
31 Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’”
Men uning we neslining béshigha, xizmetkarlirining béshigha qebihlikining jazasini chüshürimen; Men ularning üstige, Yérusalémda turuwatqanlarning üstige hem Yehudaning ademliri üstige Men ulargha agahlandurghan barliq külpetlerni chüshürimen; chünki ular Manga héch qulaq salmighan.
32 Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.
Shuning bilen Yeremiya bashqa bir oram qeghezni élip Nériyaning oghli Baruqqa berdi; u Yeremiyaning aghzigha qarap Yehuda padishahi Yehoakim otta köydürüwetken oram yazmida xatirilen’gen hemme sözlerni yazdi; ular bu sözlerge oxshaydighan bashqa köp sözlernimu qoshup yazdi.