< Jeremiah 36 >

1 Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
А четврте године Јоакима, сина Јосијиног цара Јудиног, дође ова реч Јеремији од Господа говорећи:
2 “Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
Узми књигу и напиши у њу све речи које сам ти рекао за Израиља и Јуду и за све народе, од када ти почех говорити, од времена Јосијиног, до данас;
3 Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
Еда би чуо дом Јудин све зло које им мислим учинити и вратио се свак са свог злог пута, да бих им опростио безакоње и грех њихов.
4 Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
Тада Јеремија дозва Варуха, сина Ниријиног, и написа Варух у књигу из уста Јеремијиних све речи Господње које му говори.
5 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
Потом заповеди Јеремија Варуху говорећи: Мени није слободно, те не могу отићи у дом Господњи.
6 Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
Него иди ти, и прочитај из књиге коју си написао из мојих уста, речи Господње, народу у дому Господњем у дан посни, и свим Јудејцима који дођу из градова својих прочитај;
7 Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
Не би ли, молећи се, припали ка Господу и вратили се сваки са свог пута злог, јер је велик гнев и јарост што је Господ изрекао за тај народ.
8 Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
И учини Варух, син Ниријин, све како му заповеди пророк Јеремија, и прочита из књиге речи Господње у дому Господњем.
9 Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
А пете године Јоакима сина Јосијиног цара Јудиног месеца деветог, огласише пост пред Господом свему народу јерусалимском и свему народу који дође из градова Јудиних у Јерусалим.
10 Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
И прочита Варух из књиге речи Јеремијине у дому Господњем, у клети Гемарије, сина Сафановог писара, у горњем трему код нових врата дома Господњег пред свим народом.
11 Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
А кад чу Михеј, син Гемарије, сина Сафановог, све речи Господње из књиге,
12 Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
Он сиђе у дом царев у клет писареву, и гле, онде сеђаху сви кнезови, Елисама писар, и Делаја син Семајин, и Елнатан син Ахворов, и Гемарија син Сафанов, и Седекија син Ананијин, и сви кнезови.
13 Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
И каза им Михеј све речи што чу кад Варух читаше књигу народу.
14 Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
Тада сви кнезови послаше к Варуху Јудија, сина Натаније сина Селемије, сина Хусијевог, и поручише му: Књигу коју си читао народу узми у руку и дођи овамо. И узе књигу у руку Варух, син Ниријин, и дође к њима.
15 Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!” Nígbà náà ni Baruku sì kà á ní etí wọn.
И они му рекоше: Седи и читај да чујемо. И Варух им је прочита.
16 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
А кад чуше све оне речи, сви се уплашише и рекоше Варуху: Казаћемо цару све те речи.
17 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
И запиташе Варуха говорећи: Кажи нам како си написао све те речи из уста његових.
18 Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
А Варух им рече: Из уста својих казива ми све те речи, а ја писах у књигу мастилом.
19 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
Тада рекоше кнезови Варуху: Иди, сакриј се и ти и Јеремија, да нико на зна где сте.
20 Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
Потом отидоше к цару у трем оставивши књигу у клети Елисаме писара, и казаше цару све те речи.
21 Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
А цар посла Јудија да донесе књигу; и донесе је из клети Елисаме писара, и стаде читати Јудије пред царем и пред свим кнезовима који стајаху око цара.
22 Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
А цар сеђаше у зимној кући деветог месеца, и пред њим беше живо угљевље.
23 Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
И кад Јудије прочита три четири листа, исече је цар ножем писарским, и баци у огањ на жеравицу, те изгоре сва књига огњем на жеравици.
24 Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
Али се не уплашише, нити раздреше хаљине своје цар нити који од слуга његових чувши све оне речи.
25 Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
И премда Елнатан и Делаја и Гемарија мољаху цара да не пали књигу, он их не послуша.
26 Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
Него заповеди цар Јерамеилу, сину царевом и Сераји сину Азриловом и Селемији сину Авдиловом, да ухвате Варуха писара и Јеремију пророка; али их сакри Господ.
27 Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
И дође реч Господња Јеремији, пошто цар сажеже књигу и речи које написа Варух из уста Јеремијиних, говорећи:
28 “Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
Узми опет другу књигу, и напиши у њу све пређашње речи које беху у првој књизи, коју сажеже Јоаким цар Јудин.
29 Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
А за Јоакима цара Јудиног реци: Овако вели Господ: Ти си сажегао ону књигу говорећи: Зашто си написао у њој и рекао: Доћи ће цар вавилонски и затрти ову земљу и истребити из ње и људе и стоку?
30 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
Зато, овако вели Господ за Јоакима цара Јудиног: Неће имати никога ко би седео на престолу Давидовом, и мртво ће тело његово бити бачено на припеку обдан и на мраз обноћ.
31 Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’”
Јер ћу походити њега и семе његово и слуге његове за безакоње њихово, и пустићу на њих и на становнике јерусалимске и на Јудејце све зло, за које им говорих али не послушаше.
32 Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.
И узе Јеремија другу књигу, и даде је Варуху сину Ниријином писару, а он написа у њу из уста Јеремијиних све речи што беху у оној књизи, коју сажеже Јоаким, цар Јудин огњем; и још би додано к оним много онаквих речи.

< Jeremiah 36 >