< Jeremiah 36 >

1 Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
Dans la quatrième année du règne de Joïakim, fils de Josias, roi de Juda, la parole que voici fut adressée à Jérémie de la part de l’Eternel:
2 “Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
"Prends un rouleau de parchemin et mets-y par écrit toutes les paroles que je t’ai adressées au sujet d’Israël, de Juda et de toutes les nations, depuis le jour où j’ai communiqué avec toi, à l’époque de Josias, jusqu’à ce jour.
3 Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
Peut-être les gens de Juda tiendront-ils compte de tous les maux que j’ai dessein de leur infliger, pour qu’ils abandonnent leur voie pernicieuse et que je puisse pardonner leur iniquité et leurs fautes."
4 Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
Jérémie fit venir Baruch, fils de Néria, et celui-ci, sous la dictée de Jérémie, écrivit sur un rouleau de parchemin toutes les paroles que Dieu lui avait adressées.
5 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
Puis Jérémie fit à Baruch la recommandation suivante: "Je suis retenu en prison et ne puis me rendre dans la maison de l’Eternel.
6 Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
Tu iras donc, toi, et, dans ce rouleau que tu as écrit sous ma dictée, tu liras les paroles de l’Eternel en présence du peuple, réuni dans la maison de l’Eternel à l’occasion d’un jour de jeûne. Tu les liras aussi en présence de tous les Judéens qui sont arrivés de leurs villes.
7 Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
Peut-être leurs supplications se répandront-elles devant l’Eternel, et chacun d’eux abandonnera-t-il sa voie pernicieuse; car grandes sont la colère et l’indignation dont l’Eternel a menacé ce peuple."
8 Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
Baruch, fils de Néria, se conforma fidèlement aux instructions de Jérémie, le prophète, en lisant au Temple les paroles de l’Eternel, consignées sur le livre.
9 Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
Dans la cinquième année du règne de Joïakim, fils de Josias, roi de Juda, au cours du neuvième mois, on convoqua pour un jeûne devant l’Eternel tous les habitants de Jérusalem et toute la population qui, des villes de Juda, s’était rendue à Jérusalem.
10 Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
Baruch lut alors, d’après son rouleau, les paroles de Jérémie, au Temple de l’Eternel, dans la salle de Ghemaria, fils du secrétaire Chafan, située dans la Cour supérieure, à l’entrée de la porte neuve du Temple. C’Était en présence de tout le peuple.
11 Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
Or, Mikhaïhou, fils de Ghemaria, fils de Chafan, ayant entendu toutes les paroles de l’Eternel, consignées sur le livre,
12 Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
descendit au palais du roi, dans la salle du secrétaire, où se trouvaient réunis tous les hauts fonctionnaires: Elichama, le secrétaire, Delaïa, fils de Chemaya, Elnathan, fils d’Akhbor, Ghemaria, fils de Chafan, Sédécias, fils de Hanania, et tous les seigneurs.
13 Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
Mikhaïhou leur rapporta toutes les paroles qu’il avait entendues, lorsque Baruch avait fait la lecture du livre en présence du peuple.
14 Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
Tous ces seigneurs dépêchèrent alors à Baruch lehoudi„ fils de Netania, fils de Chélémia, fils de Couchi, pour lui dire: "Ce rouleau que tu as lu à haute voix devant le peuple, emporte-le avec toi et viens." Baruch, fils de Néria, prit le rouleau dans sa main et se rendit auprès d’eux.
15 Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!” Nígbà náà ni Baruku sì kà á ní etí wọn.
Ils lui dirent: "Prends donc place, et fais-nous-en la lecture." Et Baruch le, lut devant eux.
16 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
Lorsqu’ils entendirent toutes ces paroles, ils se regardèrent avec effroi les uns! es autres et dirent à Baruch: "Il faut que nous rapportions au roi toutes ces paroles!"
17 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
Et ils interrogèrent Baruch en ces termes: "Dis-nous donc de quelle façon tu as écrit ces paroles sous sa dictée?"
18 Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
Baruch leur répondit: "Il me dictait de vive voix toutes ces paroles, et moi je les transcrivais avec de l’encre sur le livre."
19 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
Les seigneurs dirent à Baruch: "Va te mettre en sûreté, toi ainsi que Jérémie; que personne ne sache où vous êtes!"
20 Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
Puis ils se rendirent à la Cour auprès du roi, après avoir déposé le rouleau dans la salle d’Elichama, le secrétaire, et ils racontèrent au roi tous ces faits.
21 Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
Le roi envoya chercher le rouleau par lehoudi, qui le retira de la salle d’Elichama, le secrétaire. Et lehoudi en donna lecture en présence du roi et en présence de tous les grands qui se tenaient debout devant le roi.
22 Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
Or, le roi était assis dans son appartement d’hiver (on était au neuvième mois), et devant lui il y avait un brasier allumé.
23 Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
A mesure que lehoudi achevait de lire trois ou quatre colonnes, le roi les détachait avec un canif de scribe et les jetait au feu dans le brasier, jusqu’à ce que tout le rouleau eût été ainsi consumé par le feu du brasier.
24 Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
Le roi et ses officiers qui avaient entendu toutes ces paroles n’en avaient éprouvé aucune crainte ni n’avaient déchiré leurs vêtements.
25 Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
Elnathan, Delaïa et Ghemaria avaient bien supplié le roi de ne pas brûler le rouleau, mais il ne les avait point écoutés.
26 Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
Le roi ordonna même à lerahmeêl, prince royal, à Seraïa, fils d’Azriel, et Chélémia, fils d’Abdiel, de se saisir de Baruch, le secrétaire, et de Jérémie, le prophète, mais l’Eternel les tint cachés.
27 Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
La parole de l’Eternel fut adressée à Jérémie, après que le roi eut brûlé le rouleau et les discours qu’y avait écrits Baruch sous la dictée de Jérémie.
28 “Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
"Va, dit-il, prendre derechef un autre rouleau, et inscris-y toutes les paroles primitives qui figuraient sur le premier rouleau, brûlé par Joïakim, roi de Juda.
29 Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
Et à propos de Joïakim, roi de Juda, tu diras: "Ainsi parle l’Eternel: Tu as jeté au feu ce rouleau en t’écriant: Pourquoi y as-tu inscrit ces mots: "A coup sûr, il viendra le roi de Babylone, il ruinera ce pays et en fera disparaître hommes et bêtes"?
30 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
Eh bien! voici ce que décrète l’Eternel au sujet de Joïakim, roi de Juda: "Il n’aura point d’héritier siégeant sur le trône de David, et son cadavre se trouvera exposé à la chaleur du jour et au froid de la nuit.
31 Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’”
Je le châtierai, lui, sa race, ses officiers, pour leurs crimes, et je ferai fondre sur eux, sur les habitants de Jérusalem et les gens de Juda toutes les calamités que je leur ai annoncées, sans qu’ils voulussent écouter."
32 Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.
Jérémie se munit donc d’un autre rouleau, qu’il remit à Baruch, fils de Néria, le secrétaire. Celui-ci écrivit, sous la dictée de Jérémie, toutes les paroles. inscrites dans le livre qu’avait livré au feu Joïakim, roi de Juda. Beaucoup d’autres paroles de même nature y furent encore ajoutées.

< Jeremiah 36 >