< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Beseda, ki je prišla Jeremiju od Gospoda v dneh Jojakíma, Jošíjevega sina, Judovega kralja, rekoč:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
»Pojdi v hišo Rehábovcev in jim govori in jih privedi v Gospodovo hišo, v eno izmed sob in jim daj piti vino.«
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
Potem sem vzel Jaazanjá, Jeremijevega sina, sina Habacinjájevega in njegove brate in vse njegove sinove in celotno hišo Rehábovcev;
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
in jih privedel v Gospodovo hišo, v sobo sinov Hanána, Jigdaljájevega sina, Božjega moža, ki je bila pri sobi princev, ki je bila nad sobo Šalúmovega sina Maasejája, čuvaja vrat.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Pred sinove hiše Rehábovcev sem postavil vrče, polne vina in čaše ter jim rekel: »Pijte vino.«
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Toda rekli so: »Nobenega vina ne bomo pili, kajti Jonadáb, sin Rehába, naš oče, nam je zapovedal, rekoč: ›Nobenega vina ne boste pili niti vi niti vaši sinovi na veke.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
Niti ne boste gradili hiše, niti sejali semena, niti sadili vinograda, niti imeli karkoli, temveč boste vse svoje dni prebivali v šotorih, da boste lahko mnogo dni živeli v deželi, kjer ste tujci.‹
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Tako smo ubogali glas Rehábovega sina Jonadába, našega očeta, v vsem, kar nam je določil, da vse naše dni ne pijemo nobenega vina, ne mi, ne naše žene, ne naši sinovi, niti naše hčere,
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
niti da si ne gradimo hiš, da bi prebivali v njih, niti nimamo vinograda, niti polja, niti semena,
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
temveč smo prebivali v šotorih in ubogali in storili glede na vse, kar nam je naš oče Jonadáb zapovedal.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Toda pripetilo se je, ko je babilonski kralj Nebukadnezar prišel gor v to deželo, da smo rekli: ›Pridimo in pojdimo v Jeruzalem zaradi strahu pred vojsko Kaldejcev in zaradi strahu pred sirsko vojsko‹ in tako prebivajmo pri Jeruzalemu.‹«
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Potem je prišla beseda od Gospoda Jeremiju, rekoč:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
»Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Pojdite in povejte ljudem Juda in prebivalcem Jeruzalema: ›Ali ne boste sprejeli poučevanja, da prisluhnete mojim besedam?‹ govori Gospod.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
›Besede Rehábovega sina Jonadába, ki jih je zapovedal svojim sinovom, naj ne pijejo vina, se izvršujejo, kajti do današnjega dne ne pijejo, temveč ubogajo zapoved svojega očeta. Vendar sem vam jaz govoril, vzdigujoč zgodaj in govoreč, toda niste mi prisluhnili.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
K vam sem pošiljal tudi vse svoje služabnike preroke, vzdigujoče zgodaj in jih pošiljal, rekoč: ›Vrnite se sedaj, vsakdo ali vsak človek iz svoje zle poti in poboljšajte svoja dejanja in ne pojdite za drugimi bogovi, da jim služite in boste prebivali v deželi, ki sem jo dal vam in vašim očetom.‹ Toda niste nagnili svojega ušesa niti mi niste prisluhnili.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Ker so sinovi Rehábovega sina Jonadába izvajali zapoved svojega očeta, ki jim jo je zapovedal, toda to ljudstvo mi ni prisluhnilo,
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
zato tako govori Gospod, Bog nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Glejte, privedel bom nad Juda in nad vse prebivalce Jeruzalema, vse zlo, ki sem ga proglasil zoper njih, ker sem jim govoril, toda niso slišali, in klical k njim, toda niso odgovorili.‹«
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Jeremija je hiši Rehábovcev rekel: »Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Ker ste ubogali zapoved Jonadába, svojega očeta in se držali vseh njegovih predpisov in storili glede na vse, kar vam je zapovedal,
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
zato tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Rehábovemu sinu Jonadábu ne bo manjkal moški, da bi stal pred menoj na veke.‹«

< Jeremiah 35 >