< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana za dni Joakima, syna Jozyjaszowego, króla Judzkiego, mówiąc:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
Idź do domu Rechabitów, a mów z nimi, i wprowadź ich do domu Pańskiego, do jednej komory, a daj im pić wino.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
Wziąłem tedy z sobą Jasanijasza, syna Jeremijaszowego, syna Chabazymijaszowego, i braci jego, i wszystkich synów jego, i wszystek dom Rechabitów,
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
I wprowadziłem ich do domu Pańskiego, do komory synów Chanana, syna Jegdalijaszowego, męża Bożego, która była podle komory książęcej, która była nad komorą Maasejasza, syna Sallumowego, strzegącego progu.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Potem postawiłem przed synami domu Rechabitów czaszę pełną wina i kubki, i mówiłem do nich: Pijcie wino.
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Którzy odpowiedzieli: Nie pijamy wina; bo Jonadab, syn Rechabowy, ojciec nasz, zakazał nam, mówiąc: Nie pijajcie wina, wy i synowie wasi aż na wieki;
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
A domu nie budujcie, i nasienia nie rozsiewajcie, i winnicy nie sadźcie, ani miewajcie; ale w namiotach mieszkajcie po wszystkie dni wasze, abyście żyli przez wiele dni na obliczu ziemi, w której jesteście przechodniami.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Przetoż usłuchaliśmy głosu Jonadaba, syna Rechabowego, ojca naszego, we wszystkiem, co nam rozkazał, żebyśmy nie pili wina po wszystkie dni nasze, my, żony nasze, synowie nasi, i córki nasze;
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
I żebyśmy nie budowali domów ku mieszkaniu naszemu, a winnicy, i roli, i żadnego siewu nie mieli,
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
Ale abyśmy mieszkali w namiotach; i usłuchaliśmy, i uczynimy według wszystkiego, co nam rozkazał Jonadab, ojciec nasz.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
A gdy przyciągnął, Nabuchodonozor król Babiloński, do ziemi naszej, rzekliśmy: Pójdźcie, a ustąpmy do Jeruzalemu przed wojskiem Chaldejskiem, i przed wojskiem Syryjskiem; a takeśmy zostali w Jeruzalemie.
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
I stało się słowo Pańskie do Jeremijasza, mówiąc:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Idź, a rzecz mężom Judzkim i obywatelom Jeruzalemskim: I nie przyjmiecież ćwiczenia, abyście posłuszni byli słowom moim? mówi Pan.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Ważne są słowa Jonadaba, syna Rechabowego, które przykazał synom swoim, żeby nie pili wina; i nie piją go aż do dnia tego, bo posłuszni są przykazaniu ojca swego; ale Ja mówię do was, rano wstawając i mówiąc, a przecie jesteście nieposłuszni.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Posyłam też do was wszystkich sług swych, proroków w rano wstawając i posyłając, aby mówili: Nawróćcie się już każdy od złej drogi swej, a polepszajcie spraw swoich, a nie naśladujcie bogów cudzych, ani im służcie; a tak mieszkajcie w tej ziemi, którąm dał wam, i ojcom waszym; aleście nie nakłonili ucha swego, aniście mię usłuchali;
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Choć synowie Jonadaba, syna Rechabowego, dosyć uczynili rozkazaniu ojca swego, które im przykazał, ale ten lud nie jest mi posłuszny.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
Przetoż tak mówi Pan, Bóg zastępów, Bóg Izraelski: Oto Ja przywiodę na Judę i na wszystkich obywateli Jeruzalemskich wszystko złe, którem wyrzekł przeciwko im, przeto, żem mówił do nich, a nie słuchali, i wołałem ich, a nie ozwali mi się.
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
A domowi Rechabitów rzekł Jeremijasz: Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Dlatego, żeście posłuszni rozkazaniu Jonadaba, ojca waszego, i strzeżecie wszystkich przykazań jego, a czynicie według wszystkiego, co wam rozkazał:
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
Przetoż tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Nie będzie wygładzony mąż z rodu Jonadaba, syna Rechabowego, któryby stał przed obliczem mojem po wszystkie dni.

< Jeremiah 35 >