< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Az a beszéd, a melyet szóla az Úr Jeremiásnak, Jojákimnak, Jósiás, Júda királya fiának idejében, mondván:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
Menj el a Rékábiták házához, és szólj velök, és vidd be őket az Úr házába, a kamarák egyikébe, és adj nékik bort inni.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
És mellém vevém Jaazániát, Jeremiásnak fiát, ki fia vala Habasániának, és az ő rokonait és minden fiait és a Rékábiták egész háznépét.
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
És bevivém őket az Úr házába, a Hanán fiainak a kamarájába, ki Igdaliásnak, az Isten emberének fia vala, a mely a fejedelmek kamarája mellett vala, Mahásiásnak, Sallum fiának kamaráján felül, a ki az ajtónak őrizője vala.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
És a Rékábiták háza népének fiai elé borral telt kancsókat és poharakat tevék, és ezt mondám nékik: Igyatok bort!
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
És felelének: Nem iszunk bort, mert Jónadáb, Rékábnak fia, a mi atyánk parancsolta nékünk, mondván: Ne igyatok ti bort soha, se a ti fiaitok.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
Se házat ne építsetek, se vetést ne vessetek, se szőlőt ne ültessetek, se ne tartsatok; hanem sátorokban lakjatok teljes életetekben, hogy sok ideig éljetek e földnek színén, a melyben ti jövevények vagytok.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
És hallgattunk Jónadábnak a Rékáb fiának, a mi atyánknak szavára mindabban, a miket parancsolt nékünk, hogy teljes életünkben bort ne igyunk mi, a mi feleségeink, a mi fiaink és a mi leányaink.
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
Se házakat ne építsünk, hogy azokban lakjunk, se szőlőnk, se mezőnk, se vetésünk ne legyen nékünk.
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
Hanem lakozzunk sátorokban. Hallgattunk azért, és a szerint cselekedtünk, a mint nékünk Jónadáb, a mi atyánk megparancsolta vala.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Mikor pedig feljöve Nabukodonozor, a babiloni király a földre, akkor ezt mondánk: Jertek el, menjünk be Jeruzsálembe a káldeai sereg előtt és a Siriabeli sereg előtt; és Jeruzsálemben lakoztunk.
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
És szóla az Úr Jeremiásnak, mondván:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Így szól a Seregek Ura, az Izráel Istene: Menj el, mondd meg a Júda férfiainak és Jeruzsálem lakosainak: Nem veszitek-é fel az intést, hogy hallgassatok az én beszédeimre? azt mondja az Úr.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Jónadábnak, a Rékáb fiának intései teljesedtek, a melyekkel megparancsolta az ő fiainak, hogy bort ne igyanak, és mindez ideig sem ittak bort; mert hallgattak az ő atyjok parancsolatjára; én is szóltam néktek; szóltam pedig jó reggel, de nem engedtetek nékem.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
És elküldtem hozzátok minden én szolgámat, a prófétákat, és pedig jó reggel küldém, mondván: Kérlek, kiki térjen meg az ő gonosz útjáról, jobbítsátok meg cselekedeteiteket, és idegen istenek után ne járjatok, hogy nékik szolgáljatok, és lakoztok a földön, a melyet néktek és a ti atyáitoknak adtam, de fületeket sem hajtátok reá, és nem hallgattatok reám.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Mivelhogy Jónadábnak, a Rékáb fiának fiai teljesítik az ő atyjoknak parancsolatját, melyet parancsolt vala nékik, e nép pedig nem hallgata reám;
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
Azért ezt mondja az Úr, a Seregek Istene, az Izráel Istene: Ímé, én rábocsátom Júdára és Jeruzsálemnek minden lakóira mindama veszedelmet, a melyről szóltam nékik; azért mert szóltam nékik, de nem hallották, kiáltottam nékik, de nem feleltek.
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
A Rékábiták házának pedig monda Jeremiás: Ezt mondja a Seregek Ura, az Izráel Istene: Mivelhogy hallgattatok Jónadábnak, a ti atyátoknak parancsolatjára, és megtartottátok minden parancsolatját, és úgy cselekedtetek, a mint meghagyta volt néktek:
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
Azért ezt mondja a Seregek Ura, az Izráel Istene: Nem fogyatkozik el Jónadábnak, a Rékáb fiának maradéka, a ki előttem álljon mindenkor.

< Jeremiah 35 >