< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Parole adressée à Jérémie par l’Eternel au temps de Joïakim, fils de Josias, roi de Juda, en ces termes:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
Va trouver la famille des Rêkhabites, adresse-leur la parole, et amène-les au temple du Seigneur, dans une des salles; et là tu leur offriras du vin à boire.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
J’Allai donc chercher Yazania, fils de Jérémie, fils de Habacinia, avec ses frères, tous ses fils et toute la famille des Rêkhabites,
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
et je les amenai au temple du Seigneur, dans la salle des fils de Hanan, fils de Ygdalia, l’homme de Dieu, salle qui était proche de la salle des grands et au-dessus de la salle de Masséya, fils de Challoum, le gardien du seuil.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Je plaçai devant les membres de la famille des Rêkhabites des calices remplis de vin et des coupes, et je leur dis: Buvez du vin.
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Mais ils répondirent: "Nous ne buvons pas de vin! car notre père Jonadab, fils de Rêkhab, nous l’a défendu en disant: Vous ne boirez jamais de vin, ni vous ni vos enfants.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
Vous ne bâtirez pas non plus de maison, vous ne sèmerez pas de graines, vous ne planterez pas de vignes et ne posséderez rien de tout cela; mais vous habiterez sous des tentes pendant toute votre existence, afin que vous viviez de longs jours sur le sol où vous séjournerez.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Or, nous avons écouté la voix de notre père Jonadab, fils de Rêkhab, suivi toutes ses prescriptions, en nous abstenant de boire du vin notre vie durant, nous, nos femmes, nos fils et nos filles;
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
de construire des maisons pour y demeurer, de posséder des vignes, des champs et des graines pour ensemencer.
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
Nous avons habité sous des tentes; nous avons exécuté docilement tout ce que nous avait prescrit Jonadab, notre père.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Seulement, quand Nabuchodonosor, roi de Babylone, a envahi ce pays, nous nous sommes dit: Allons, retirons-nous à Jérusalem devant l’armée des Chaldéens et devant l’armée des Araméens. C’Est ainsi que nous nous sommes établis à Jérusalem."
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Alors la parole de l’Eternel fut adressée à Jérémie en ces termes:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
"Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Va et dis aux gens de Juda et aux habitants de Jérusalem: Ne profiterez-vous pas de la leçon, en obéissant à mes commandements? dit l’Eternel.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
On a exécuté les ordres de Jonadab, fils de Rêkhab, qui prescrivait à ses enfants de ne pas boire de vin: ils n’en ont pas bu jusqu’à ce jour, dociles aux recommandations de leur père, et moi, je vous ai adressé la parole chaque matin, sans relâche, sans que vous m’ayez écouté!
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Je vous ai envoyé tous mes serviteurs, les prophètes, sans fin ni trêve, pour vous dire: Que chacun de vous revienne de sa voie pernicieuse, amendez vos actes, ne suivez pas le culte des dieux étrangers; de la sorte, vous demeurerez sur le sol que je vous ai donné, à vous et à vos ancêtres. Mais vous n’avez point prêté l’oreille, vous ne m’avez pas écouté.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Les enfants de Jonadab, fils de Rêkhab, ont exécuté, eux, l’ordre que leur avait donné leur père, tandis que ce peuple ne m’a point obéi.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
C’Est pourquoi l’Eternel, Dieu-Cebaot, Dieu d’Israël, parle ainsi: Voici, je vais faire fondre sur Juda et sur tous les habitants de Jérusalem tous les maux que j’ai décrétés contre eux, puisque je leur ai parlé et qu’ils n’ont point écouté, puisque je les ai appelés et qu’ils n’ont pas répondu!"
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Mais à la famille des Rêkhabites Jérémie dit: "Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Puisque vous avez obéi à l’ordre de Jonadab, votre père, observé toutes ses prescriptions et exécuté tout ce qu’il vous a recommandé,
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
c’est pourquoi, dit l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël, en aucun temps, il ne manquera à Jonadab, fils de Rêkhab, des hommes pour se tenir en ma présence."

< Jeremiah 35 >