< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
La parole qui fut adressée à Jérémie de la part de Yahvé, au temps de Jojakim, fils de Josias, roi de Juda, en ces termes:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
« Va à la maison des Rechabites, parle-leur, fais-les entrer dans la maison de Yahvé, dans l'une des chambres, et donne-leur du vin à boire. »
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
Je pris Jaazania, fils de Jérémie, fils de Habazzinia, avec ses frères, tous ses fils, et toute la maison des Récabites;
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
et je les fis entrer dans la maison de l'Éternel, dans la chambre des fils de Hanan, fils d'Igdalia, homme de Dieu, qui était près de la chambre des princes, au-dessus de la chambre de Maaséja, fils de Schallum, gardien du seuil.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Je plaçai devant les fils de la maison des Récabites des coupes pleines de vin et des gobelets, et je leur dis: « Buvez du vin! »
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Mais ils dirent: « Nous ne boirons pas de vin, car Jonadab, fils de Rechab, notre père, nous a donné cet ordre: « Vous ne boirez pas de vin, ni vous ni vos enfants, à jamais.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
Vous ne construirez pas de maison, vous ne sèmerez pas de graines, vous ne planterez pas de vigne et vous n'en aurez pas; mais tous vos jours, vous habiterez sous des tentes, afin de vivre longtemps dans le pays où vous vivez en nomades.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Nous avons obéi à la voix de Jonadab, fils de Rechab, notre père, dans tout ce qu'il nous a ordonné, de ne pas boire de vin toute notre vie, ni nous, ni nos femmes, ni nos fils, ni nos filles,
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
et de ne pas nous construire de maisons pour y habiter. Nous n'avons ni vigne, ni champ, ni semence;
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
mais nous avons habité sous des tentes, et nous avons obéi et fait tout ce que Jonadab, notre père, nous avait ordonné.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Mais lorsque Nabuchodonosor, roi de Babylone, est monté dans le pays, nous avons dit: « Venez! Allons à Jérusalem, par crainte de l'armée des Chaldéens et par crainte de l'armée des Syriens; ainsi nous habiterons à Jérusalem.'"
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Alors la parole de Yahvé fut adressée à Jérémie, en ces mots:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Yahvé des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Va dire aux hommes de Juda et aux habitants de Jérusalem: « Ne recevrez-vous pas l'instruction d'écouter mes paroles? » dit Yahvé.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
« Les paroles de Jonadab, fils de Réchab, qui avait ordonné à ses fils de ne pas boire de vin, se sont accomplies; et jusqu'à ce jour, ils n'en boivent pas, car ils obéissent au commandement de leur père; mais moi, je vous ai parlé, je me suis levé de bonne heure et j'ai parlé, et vous ne m'avez pas écouté.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
J'ai aussi envoyé vers vous tous mes serviteurs les prophètes, je me suis levé de bonne heure et je les ai envoyés, en disant: « Que chacun de vous revienne maintenant de sa mauvaise voie, qu'il corrige ses actions, et qu'il n'aille pas après d'autres dieux pour les servir. Vous habiterez alors dans le pays que j'ai donné à vous et à vos pères. » Mais vous n'avez pas prêté l'oreille et vous ne m'avez pas écouté.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Les fils de Jonadab, fils de Récab, ont exécuté le commandement que leur père leur avait donné, mais ce peuple ne m'a pas écouté.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
« C'est pourquoi Yahvé, le Dieu des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Voici que je vais faire venir sur Juda et sur tous les habitants de Jérusalem tous les malheurs que j'ai prononcés contre eux, parce que je leur ai parlé et qu'ils n'ont pas écouté, parce que je les ai appelés et qu'ils n'ont pas répondu. »"
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Jérémie dit à la maison des Rechabites: « L'Éternel des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Parce que vous avez obéi au commandement de Jonadab, votre père, que vous avez observé toutes ses ordonnances et que vous avez fait tout ce qu'il vous a commandé,
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
l'Éternel des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Jonadab, fils de Rechab, ne manquera pas d'un homme pour se tenir devant moi à jamais ».

< Jeremiah 35 >