< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Slovo, kteréž se stalo k Jeremiášovi od Hospodina za dnů Joakima syna Joziášova, krále Judského, řkoucí:
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
Jdi mezi Rechabitské, a promluvě s nimi, doveď je k domu Hospodinovu do jednoho z pokojů, a dej jim píti vína.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
Tedy pojav Jazaniáše syna Jeremiášova, syna Chabaciniášova, a bratří jeho i všecky syny jeho se vší rodinou Rechabitských,
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
Dovedl jsem je k domu Hospodinovu do pokoje synů Chanana syna Igdaliášova, muže Božího, kterýž byl při pokoji knížat, jenž byl nad pokojem Maaseiáše syna Sallumova, ostříhajícího prahu.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Potom postavě před syny domu Rechabitských koflíky plné vína a číše, i řekl jsem jim: Píte víno.
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Kteříž řekli: Nepíjíme vína. Nebo Jonadab syn Rechabův, otec náš, zapověděl nám, řka: Nepíjejte vína, vy, ani synové vaši na věky.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
A domu nestavějte, ani semene nerozsívejte, vinice také neštěpujte, ani mívejte, ale v staních přebývejte po všecky dny vaše, abyste živi byli mnoho dnů na tváři země, v níž pohostinu jste.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Protož uposlechli jsme hlasu Jonadaba syna Rechabova, otce našeho, ve všem, což přikázal nám, abychom nepili vína po všecky dny své, my, manželky naše, synové naši, i dcery naše,
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
Abychom nestavěli domů k bydlení svému, a vinice, ani rolí, ani nic osátého nemívali.
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
Ale abychom bydlili v staních. Uposlechli jsme, pravím, a děláme všecko, jakž přikázal nám Jonadab otec náš.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Stalo se pak, když vtrhl Nabuchodonozor král Babylonský do země, že jsme řekli: Poďte, a ujděme do Jeruzaléma před vojskem Kaldejským, a před vojskem Syrským. Takž bydlíme v Jeruzalémě.
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Tedy stalo se slovo Hospodinovo k Jeremiášovi, řkoucí:
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Jdi a rci mužům Judským a obyvatelům Jeruzalémským: Což nepřijmete naučení, abyste poslouchali slov mých? dí Hospodin.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
K vykonání přichází všeliké slovo Jonadaba syna Rechabova, kterýž přikázal synům svým, aby nepili vína. Nepili zajisté až do tohoto dne, nebo poslouchají přikázaní otce svého. Já pak mluvím k vám, ráno přivstávaje, a to ustavičně, a však neposloucháte mne.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Nadto posílám k vám všecky služebníky své proroky, ráno přivstávaje, a to ustavičně, říkaje: Navraťte se již jeden každý z cesty své zlé, a polepšte předsevzetí svých, a nechoďte za bohy cizími, sloužíce jim, a tak přebývejte v zemi této, kterouž jsem dal vám i otcům vašim: však nenakloňujete uší svých, aniž mne posloucháte.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Ješto synové Jonadabovi syna Rechabova plní přikázaní otce svého, kteréž přikázal jim, lid pak tento neposlouchají mne.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
Protož takto praví Hospodin Bůh zástupů, Bůh Izraelský: Aj, já uvedu na Judu a na všecky obyvatele Jeruzalémské všecko to zlé, kteréž jsem vyřkl proti nim, proto že jsem mluvíval k nim, a neposlouchali, a volával jsem na ně, ale neohlásili se.
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Rodině pak Rechabitských řekl Jeremiáš: Takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Protože posloucháte přikázaní Jonadaba otce vašeho, a ostříháte všech přikázaní jeho, anobrž děláte všecko, jakž přikázal vám,
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
Protož takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Nebudeť vypléněn muž z rodu Jonadabova syna Rechabova, ješto by nestál před oblíčejem mým po všecky dny.

< Jeremiah 35 >