< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
Judah siangpahrang Josiah capa Jehoiakim a bawi nah BAWIPA koehoi Jeremiah koe ka tho e lawk ni,
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
Rekhab imthung koe cet nateh pato, BAWIPA im dawk e imrakhan buet touh dawk kâenkhai nateh misur nei hane poe telah ati.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
Hadazziniah capa Jeremiah capa Jaazaniah hoi a hmaunawnghanaw hoi a capanaw pueng hoi Rekhab imthungnaw pueng ka ceikhai.
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
Cathut e tami Igdaliah capa Hanan capanaw e imrakhan, BAWIPA e im dawk ka kâenkhai, hote imrakhan teh kahrawikungnaw e imrakhan teng longkha ka ring e Shallum capa Naser imrakhan thung kaawm e doeh.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
Hahoi Rekhab catoun naw thung hoi tongpanaw hmalah hlaam hoi manang dawk kakawilah misurtui ka phung teh ahnimouh koe, misurtui heh net awh, telah ka ti pouh.
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
Hatei ahnimouh misurtui teh ka net awh mahoeh, na kaukkung Rekhab capa Jonadab ni, nama hoi na catounnaw ni hai nâtuek hai misurtui na net awh mahoeh.
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
Im sak hanh awh, cati hai tu hanh awh, misur takha hai sak hanh awh, hote hnonaw tawn hanh na onae ram dawk kasawlah na hring thai awh na han, na hring awh na thung lukkarei dawk kho na sak awh han, telah kâ na poe.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Hottelah, na kaukkung Rekhab capa Jonadab ni a pahni dawk hoi lawk a dei e ka hring awh na thung, kamamouh hoi ka yunaw hoi ka capa hoi ka canunaw ni misurtui nei hoeh hane hoi,
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
kho ka sak awh nahane im sak hoeh hane hoi misur takha thoseh, cati thoseh tawn hoeh hanelah ka tarawi awh e doeh.
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
Lukkarei dawk kho ka sak awh teh, na kaukkung Jonadab e kâpoe lawknaw pueng ka tarawi teh ka hringkhai awh.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
Hahoi, Babilon Siangpahrang Nebukhadnezar ni ram a tuk navah kaimouh ni tho awh, Khaldean ransahu hoi Siria ransahu taki awh dawkvah Jerusalem lah cet awh sei telah ka ti awh teh, atu Jerusalem vah ka o awh telah ati awh.
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Hahoi BAWIPA e lawk Jeremiah koe a pha.
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
Isarel Cathut ransahu BAWIPA ni telah a dei Judah ram e taminaw hoi Jerusalem kho ka sak taminaw koe dei pouh, ka lawk ngai hanelah cangkhainae hah na dâw awh mahoeh maw telah BAWIPA ni a dei.
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Rekhab capa Jonadab ni a capanaw koe kâ a la poe e, misurtui nei hoeh hanelah a tarawi awh teh, sahnin totouh net awh hoeh, kakhekung e kâpoelawk a tarawi awh katang, kai ni teh amom ka thaw teh nangmouh koe lawk ka dei ei, na thai ngai awh hoeh.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
Ka thaw ka tawk e profetnaw amom a thaw awh teh, nangmouh koe ka patoun, tamipueng na hringnuen yonnae dawk hoi bout ban awh leih, ouk na sak awh e hnonaw hah pathoup awh leih, Cathut alouke thaw tawk hanlah tarawi awh hanh leih, hat pawiteh namamouh hoi na kakhekungnaw koe ka poe e ram dawk kho na sak awh telah ka ti. Hatei hnâ na tabuem awh teh na thai ngai awh hoeh.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Rekhab capa Jonadab catounnaw ni teh kakhekung e kâpoelawk a tarawi awh, hete taminaw ni teh ka lawk thai ngai awh hoeh.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
Hatdawkvah, Isarel BAWIPA Cathut, ransahu Cathut ni hettelah a dei, khenhaw Judah hoi Jerusalem kho ka sak e taminaw pueng koe hawihoehnae ahnimae lathueng phasak hanelah ka dei e hah kakuep sak han. Bangkongtetpawiteh, ahnimouh koe lawk ka dei e thai ngai awh hoeh. Ahnimouh ka kaw awh eiteh na pato ngai awh hoeh teh lah ati.
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Hahoi Jeremiah ni Rekhab catounnaw koevah, ransahu BAWIPA, Isarel Cathut ni hettelah a dei, na kakhekung Jonadab e kâpoelawk na tarawi awh teh, a dei e naw pueng na tarawi awh teh kâpoe e patetlah na sak awh dawkvah.
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
Rekhab capa Jonadab ni a yungyoe hoi ka hmalah kangdout hane tami vout mahoeh, telah ransahu BAWIPA, Isarel Cathut ni a dei.

< Jeremiah 35 >