< Jeremiah 34 >

1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
Detta är det ord som kom till Jeremia från HERREN, när Nebukadressar, konungen i Babel, med hela sin här och med alla de riken på jorden, som lydde under hans välde, och med alla folk angrep Jerusalem och alla dess lydstäder; han sade:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
Så säger HERREN, Israels Gud: Gå åstad och säg till Sidkia, Juda konung, ja, säg till honom: Så säger HERREN: Se, jag skall giva denna stad i den babyloniske konungens hand, och han skall bränna upp den i eld.
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
Och du själv skall icke kunna undkomma hans hand, utan skall förvisso bliva gripen och given i hans hand, så att du nödgas stå inför konungen i Babel, öga mot öga; och han skall muntligen tala med dig, och du skall komma till Babel.
4 “‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
Men hör HERRENS ord, du Sidkia, Juda konung: Så säger HERREN om dig: Du skall icke dö genom svärd.
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
Nej, i frid skall du dö; och likasom man har anställt förbränning till dina fäders, de förra konungarnas, ära, deras som hava varit före dig, så skall man ock anställa förbränning till din ära och hålla dödsklagan efter dig: "Ack ve, Herre!" Ty detta har jag talat, säger HERREN.
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
Och profeten Jeremia talade till Sidkia, Juda konung, allt detta i Jerusalem,
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
under det att den babyloniske konungens här belägrade Jerusalem och allt som ännu återstod av städer i Juda, nämligen Lakis och Aseka; ty dessa voro de enda av Juda städer, som ännu voro kvar och voro befästa.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
Detta är det ord som kom till Jeremia från HERREN, sedan konung Sidkia hade slutit ett förbund med allt folket i Jerusalem därom att de bland sig skulle utropa frihet,
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
så att var och en skulle släppa sin träl och sin trälinna fria, om det var en hebreisk man eller kvinna, på det att icke den ene juden skulle hava den andre till träl.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Och detta hörsammades av alla furstarna och allt folket, av dem som hade varit med om förbundet och lovat att var och en skulle släppa sin träl och sin trälinna fria, så att han icke mer skulle hava dem till trälar; de hörsammade det och släppte dem.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
Men sedermera ändrade de sig och togo tillbaka de trälar och trälinnor som de hade släppt fria, och gjorde dem åter till trälar och trälinnor.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Då kom HERRENS ord till Jeremia från HERREN; han sade:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
Så säger HERREN, Israels Gud: Jag själv slöt ett förbund med edra fäder på den tid då jag förde dem ut ur Egyptens land, ur träldomshuset; jag sade:
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
"När sju år äro förlidna, skall var och en av eder släppa sin broder, hebréen, som har sålt sig åt dig och tjänat dig i sex år; du skall då släppa honom fri ur din tjänst." Dock ville edra fäder icke höra på mig eller böja sina öron därtill.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
Men I haven nyss vänt om och gjort vad rätt är i mina ögon, i det att I haven utropat frihet var och en för sin broder. Och I haven härom slutit ett förbund inför mitt ansikte, i det hus som är uppkallat efter mitt namn.
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
Men nu haven I åter ändrat eder och ohelgat mitt namn och tagit tillbaka var och en sin träl och sin trälinna, dem som I haden släppt fria till att gå vart de ville; ja, I haven nu åter gjort dem till edra trälar och trälinnor.
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
Därför säger HERREN så: I haven icke hört på mig och utropat frihet var och en för sin broder och sin nästa. Så utropar då jag, säger HERREN, för eder frihet att hemfalla åt svärd, pest och hungersnöd; ja, jag skall göra eder till en varnagel för alla riken på jorden.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
Och de män som hava överträtt mitt förbund och icke hållit förpliktelserna vid det förbund de slöto inför mitt ansikte -- vid kalven som av dem blev huggen i två stycken, mellan vilka de gingo --
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
dessa män, nämligen Judas och Jerusalems furstar, hovmännen och prästerna och allt folket i landet, som gingo mellan styckena av kalven,
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
dem skall jag giva i deras fienders hand, i de mäns hand, som stå efter deras liv; och deras döda kroppar skola bliva mat åt himmelens fåglar och markens djur.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
Och Sidkia, Juda konung, med hans furstar skall jag giva i deras fienders hand, i de mäns hand, som stå efter deras liv, och i händerna på den babyloniske konungens här, som nu har dragit bort ifrån eder.
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
Se, jag skall giva dem befallning, säger HERREN, att de åter skola draga mot denna stad och belägra den; och de skola då intaga den och bränna upp den i eld. Och Juda städer skall jag göra till en ödemark, där ingen bor.

< Jeremiah 34 >