< Jeremiah 34 >

1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
Ятэ кувынтул спус луй Иеремия дин партя Домнулуй кынд Небукаднецар, ымпэратул Бабилонулуй, ку тоатэ оштиря са ши тоате ымпэрэцииле пэмынтулуй де суб стэпыниря луй ши тоате попоареле фэчяу рэзбой ымпотрива Иерусалимулуй ши ымпотрива тутурор четэцилор каре циняу де ел:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
„Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Ду-те де спуне луй Зедекия, ымпэратул луй Иуда, ши зи-й: «Аша ворбеште Домнул: ‹Ятэ, дау четатя ачаста ын мыниле ымпэратулуй Бабилонулуй ши о ва арде ку фок.
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
Ши ту ну вей скэпа дин мыниле луй, чи вей фи луат ши дат ын мына луй, вей да окь ку ымпэратул Бабилонулуй, ел ыць ва ворби гурэ кэтре гурэ ши вей мерӂе ла Бабилон.›»’
4 “‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
Нумай, аскултэ Кувынтул Домнулуй, Зедекия, ымпэратул луй Иуда! Аша ворбеште Домнул деспре тине: ‘Ну вей мури учис де сабие,
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
чи вей мури ын паче ши, кум ау арс миресме пентру пэринций тэй, векий ымпэраць, каре ау фост ынаинтя та, тот аша вор арде ши пентру тине ши те вор жели, зикынд: «Вай, доамне!» Кэч Еу ам ростит кувынтул ачеста’, зиче Домнул.”
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
Пророкул Иеремия а спус тоате ачесте кувинте луй Зедекия, ымпэратул луй Иуда, ла Иерусалим,
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
пе кынд оастя ымпэратулуй Бабилонулуй лупта ымпотрива Иерусалимулуй ши ымпотрива тутурор челорлалте четэць але луй Иуда, ымпотрива Лакисулуй ши Азекей, кэч ачестя ерау четэциле каре май рэмэсесерэ дин тоате четэциле ынтэрите але луй Иуда.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
Ятэ кувынтул спус луй Иеремия дин партя Домнулуй, дупэ че ымпэратул Зедекия фэкусе о ынвоялэ ку тот попорул Иерусалимулуй ка сэ вестяскэ слобозения робилор,
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
пентру ка фиекаре сэ ласе слобозь пе робул ши роаба са, пе евреу ши пе еврейкэ, ши нимень сэ ну май цинэ ын робие пе фрателе сэу иудеу.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Тоате кэпетенииле ши тот попорул каре фэкусерэ ынвояла с-ау легат сэ ласе слобозь фиекаре пе робул ши роаба луй ши сэ ну-й май цинэ ын робие. Ей ау аскултат ши ле-ау дат друмул.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
Дар, май пе урмэ, с-ау рэзгындит, ау луат ынапой пе робий ши роабеле пе каре-й слобозисерэ ши й-ау силит сэ ле фие ярэшь робь ши роабе.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Атунч, Кувынтул Домнулуй а ворбит луй Иеремия дин партя Домнулуй астфел:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
„Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Еу ам фэкут ун легэмынт ку пэринций воштри ын зиуа кынд й-ам скос дин цара Еӂиптулуй, дин каса робией ши ле-ам зис:
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
«Дупэ шапте ань, фиекаре дин вой сэ ласе слобод пе фрателе сэу евреу каре и се винде луй; шасе ань сэ-ць служяскэ ши апой сэ-л лашь слобод де ла тине.» Дар пэринций воштри ну М-ау аскултат ши н-ау луат аминте ла Мине.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
Вой в-аць ынторс астэзь ын вой ыншивэ, аць фэкут че есте бине ынаинтя Мя, вестинд фиекаре слобозения пентру апроапеле сэу, ши аць фэкут о ынвоялэ ынаинтя Мя, ын Каса песте каре есте кемат Нумеле Меу.
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
Дар пе урмэ в-аць луат ворба ындэрэт ши Мь-аць пынгэрит Нумеле, луынд ярэшь ынапой фиекаре пе робий ши роабеле пе каре-й слобозисерэць ши-й лэсасерэць ын воя лор, ши й-аць силит сэ вэ фие ярэшь робь ши роабе.’
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
Де ачея аша ворбеште Домнул: ‘Ну М-аць аскултат ка сэ вестиць слобозения фиекаре пентру фрателе сэу, фиекаре пентру апроапеле сэу. Ятэ, Еу вестеск ымпотрива воастрэ’, зиче Домнул, ‘слобозения сабией, чумей ши фоаметей ши вэ вой фаче де поминэ принтре тоате ымпэрэцииле пэмынтулуй.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
Ши пе оамений каре ау кэлкат легэмынтул Меу, каре н-ау пэзит ындаторириле ынвоелий пе каре о фэкусерэ ынаинтя Мя, тэинд ун вицел ын доуэ ши трекынд принтре челе доуэ жумэтэць але луй,
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
ши ануме пе кэпетенииле луй Иуда ши пе кэпетенииле Иерусалимулуй, пе фамений дрегэторь, пе преоць ши пе тот попорул цэрий, каре ау трекут принтре букэциле вицелулуй,
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
ый вой да ын мыниле врэжмашилор лор, ын мыниле челор че вор сэ ле я вяца, ши трупуриле лор моарте вор служи ка хранэ пэсэрилор черулуй ши фярелор кымпулуй.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
Дар пе Зедекия, ымпэратул луй Иуда, ши пе кэпетенииле луй, ый вой да ын мыниле врэжмашилор лор, ын мыниле челор че вор сэ ле я вяца, ын мыниле оштирий ымпэратулуй Бабилонулуй, каре а плекат де ла вой!
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
Ятэ, вой да порункэ’, зиче Домнул, ‘ши-й вой адуче ынапой ымпотрива четэций ачестея; о вор бате, о вор луа ши о вор арде ку фок. Ши вой префаче четэциле луй Иуда ынтр-ун пустиу фэрэ локуиторь.’”

< Jeremiah 34 >