< Jeremiah 34 >
1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
Cuvântul care a venit la Ieremia de la DOMNUL, când Nebucadnețar, împăratul Babilonului și toată armata lui și toate împărățiile pământului ale stăpânirii lui și toate popoarele, au luptat împotriva Ierusalimului și împotriva tuturor cetăților lui, spunând:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Du-te și vorbește-i lui Zedechia împăratul lui Iuda, și spune-i: Astfel spune DOMNUL: Iată, voi da această cetate în mâna împăratului Babilonului și el o va arde cu foc;
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
Și tu nu vei scăpa din mâna lui, ci, negreșit, vei fi prins și dat în mâna lui; și ochii tăi vor privi ochii împăratului Babilonului și el va vorbi cu tine gură către gură și tu vei merge în Babilon.
4 “‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
Totuși ascultă cuvântul DOMNULUI, Zedechia, împărate al lui Iuda: Astfel spune DOMNUL despre tine: tu nu vei muri de sabie;
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
Ci vei muri în pace; și cu arderile părinților tăi, a împăraților dinainte care au fost înaintea ta, tot astfel ei vor arde mirodenii pentru tine; și te vor plânge, spunând: Ah, doamne! pentru că eu am vestit cuvântul, spune DOMNUL.
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
Atunci profetul Ieremia a vorbit toate aceste cuvinte lui Zedechia, împăratul lui Iuda, în Ierusalim,
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
Când armata împăratului Babilonului a luptat împotriva Ierusalimului și împotriva tuturor cetăților lui Iuda care au rămas, împotriva Lachisului și împotriva Azechei, pentru că aceste cetăți apărate au rămas dintre cetățile lui Iuda.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
Acesta este cuvântul care a venit la Ieremia de la DOMNUL, după ce împăratul Zedechia făcuse un legământ cu tot poporul care era în Ierusalim, pentru a le vesti libertatea;
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
Ca fiecare om să lase pe servitorul său și fiecare om pe servitoarea sa, fiind un evreu sau o evreică, să plece liberi; ca nimeni să nu se servească de ei, adică, de un iudeu, fratele său.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Și, când toți prinții și tot poporul care intrase în legământ, au auzit porunca împăratului, ca fiecare să lase pe servitorul său și fiecare pe servitoarea sa, să plece liberi, ca nimeni să nu se mai servească de ei, atunci au dat ascultare și i-au lăsat să plece.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
Dar după aceea s-au întors și i-au făcut pe servitorii și pe servitoarele, pe care îi lăsaseră să plece liberi, să se întoarcă, și i-au adus în supunere ca servitori și servitoare.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
De aceea cuvântul DOMNULUI a venit la Ieremia de la DOMNUL, spunând:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Am încheiat un legământ cu părinții voștri în ziua când i-am scos din țara Egiptului, din casa robilor, spunând,
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
La sfârșitul a șapte ani, fiecare să lăsați să plece, pe fratele său, un evreu, care ți s-a fost vândut; și după ce ți-a servit șase ani, să îl lași să plece liber de la tine; dar părinții voștri nu mi-au dat ascultare, nici nu și-au plecat urechea.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
Și voi v-ați întors acum și ați făcut ce este drept înaintea ochilor mei, vestind, fiecare, libertatea aproapelui său; și ați încheiat un legământ înaintea mea în casa care este numită după numele meu;
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
Dar voi, v-ați întors și ați murdărit numele meu și fiecare, ați făcut pe servitorul său și fiecare, pe servitoarea sa, cărora le-ați dat libertate după plăcerea lor, să se întoarcă și i-ați adus în supunere, să vă fie ca servitori și servitoare.
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
De aceea astfel spune DOMNUL: Voi nu mi-ați dat ascultare, vestind fiecare, libertatea fratelui său și fiecare, aproapelui său; iată, eu, spune DOMNUL, vă vestesc libertatea sabiei, a ciumei și a foametei; și vă voi da spre apăsare în toate împărățiile pământului.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
Și voi da pe oamenii care au călcat legământul meu, care nu au împlinit cuvintele legământului pe care îl făcuseră înaintea mea, când au tăiat vițelul în două și au trecut printre părțile lui,
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
Pe prinții lui Iuda și pe prinții Ierusalimului, pe fameni și pe preoți și pe tot poporul țării care a trecut printre părțile vițelului;
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
Îi voi da chiar în mâna dușmanilor lor și în mâna celor care le caută viața; și trupurile lor moarte vor fi ca hrană pentru păsările cerului și pentru fiarele pământului.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
Și pe Zedechia împăratul lui Iuda și pe prinții lui îi voi da în mâna dușmanilor lor și în mâna celor care le caută viața și în mâna armatei împăratului Babilonului care au plecat de la voi.
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
Iată, eu poruncesc, spune DOMNUL, și îi voi face să se întoarcă la această cetate; și ei vor lupta împotriva ei și o vor lua și o vor arde cu foc; și voi face cetățile lui Iuda o pustiire fără vreun locuitor.