< Jeremiah 34 >

1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
Ilizwi elafika kuJeremiya livela eNkosini, lapho uNebhukadinezari inkosi yeBhabhiloni, lebutho lakhe lonke, lemibuso yonke yomhlaba yokubusa kwesandla sakhe, lazo zonke izizwe, babesilwa bemelene leJerusalema bemelene layo yonke imizi yayo, lisithi:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
Itsho njalo iNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli: Hamba ukhulume kuZedekhiya inkosi yakoJuda uthi kuye: Itsho njalo iNkosi: Khangela, nginikela lumuzi esandleni senkosi yeBhabhiloni, ukuthi iwutshise ngomlilo.
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
Lawe kawuyikuphunyuka esandleni sayo, kodwa uzabanjwa isibili, unikelwe esandleni sayo; lamehlo akho azabona amehlo enkosi yeBhabhiloni, lomlomo wayo uzakhuluma lomlomo wakho; njalo uzakuya eBhabhiloni.
4 “‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
Kodwa zwana ilizwi leNkosi, Zedekhiya, nkosi yakoJuda: Itsho njalo iNkosi ngawe: Kawuyikufa ngenkemba.
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
Uzakufa ngokuthula, lanjengokubaselwa kwaboyihlo, amakhosi endulo, ayephambi kwakho, ngokunjalo bazakubasela, bakulilele, besithi: Maye inkosi! Ngoba mina ngilikhulumile lelolizwi, itsho iNkosi.
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
UJeremiya umprofethi wasewakhuluma wonke lamazwi kuZedekhiya inkosi yakoJuda eJerusalema,
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
lapho ibutho lenkosi yeBhabhiloni lisilwa limelene leJerusalema limelene layo yonke imizi yakoJuda eyayisele, limelene leLakishi limelene leAzeka; ngoba yiyo imizi ebiyelweyo eyayisisele phakathi kwemizi yakoJuda.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
Ilizwi elafika kuJeremiya livela eNkosini, emva kokuthi inkosi uZedekhiya esenzile isivumelwano labo bonke abantu ababeseJerusalema ukumemezela inkululeko kubo,
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
ukuthi ngulowo lalowo ayekele isigqili sakhe sihambe sikhululekile, langulowo lalowo isigqilikazi sakhe, umHebheru kumbe umHebherukazi, ukuze kungabi khona umuntu owenza umJuda engumfowabo abe yisigqili.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Kwasekulalela zonke iziphathamandla labo bonke abantu ababengene lesosivumelwano sokuthi ngulowo lalowo ayekele isigqili sakhe langulowo lalowo isigqilikazi sakhe sihambe sikhululekile, bangaphindi bazenze zibe yizigqili; basebelalela, baziyekela zahamba.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
Kodwa emva kwalokho baphenduka, bazibuyisa izigqili lezigqilikazi ababeziyekele zihambe zikhululekile, bazehlisela phansi zaba yizigqili lezigqilikazi.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Ngakho ilizwi leNkosi lafika kuJeremiya livela eNkosini, lisithi:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
Itsho njalo iNkosi, uNkulunkulu kaIsrayeli: Mina ngenza isivumelwano laboyihlo mhla ngibakhupha elizweni leGibhithe, endlini yobugqili, ngisithi:
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
Ekupheleni kweminyaka eyisikhombisa lizayekela ahambe, ngulowo lalowo umfowabo umHebheru owayethengiswe kuwe, esekusebenzele iminyaka eyisithupha, umyekele ahambe ekhululekile esuka kuwe. Kodwa oyihlo kabangilalelanga, kababekanga indlebe yabo.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
Lina seliphendukile lamuhla, lenza okulungileyo emehlweni ami, limemezela inkululeko, ngulowo lalowo kumakhelwane wakhe, lenza isivumelwano phambi kwami endlini ebizwa ngebizo lami.
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
Kodwa liphendukile, langcolisa ibizo lami, libuyisa, ngulowo lalowo isigqili sakhe langulowo lalowo isigqilikazi sakhe, ebeliziyekele zahamba zikhululekile njengokufisa kwazo, lazehlisela phansi, zaba yizigqili lezigqilikazi zenu.
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
Ngakho itsho njalo iNkosi: Lina kalingilalelanga, ukumemezela inkululeko, kube ngulowo lalowo kumfowabo langulowo lalowo kumakhelwane wakhe; khangelani, ngizamemezela kini, itsho iNkosi, inkululeko enkembeni, kumatshayabhuqe wesifo, lendlaleni; ngilinikele libe yisesabiso kuyo yonke imibuso yomhlaba.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
Nginikele amadoda aseqileyo isivumelwano sami, angaqinisanga amazwi esivumelwano asenza phambi kwami, lapho adabula ithole kabili, adlula phakathi kweziqa zalo;
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
iziphathamandla zakoJuda, leziphathamandla zeJerusalema, abathenwa, labapristi, labo bonke abantu belizwe, abadabula phakathi kweziqa zethole.
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
Yebo, ngizabanikela esandleni sezitha zabo lesandleni salabo abadinga impilo yabo; lezidumbu zabo zizakuba yikudla kwenyoni zamazulu lenyamazana zomhlaba.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
LoZedekhiya inkosi yakoJuda leziphathamandla zakhe ngizabanikela esandleni sezitha zabo, lesandleni salabo abadinga impilo yabo, lesandleni sebutho lenkosi yeBhabhiloni, abenyuke basuka kini.
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
Khangelani, ngizalaya, itsho iNkosi, ngibabuyise kulumuzi; njalo bazakulwa bemelene lawo, bawuthumbe, bawutshise ngomlilo; lemizi yakoJuda ngizayenza ibe lunxiwa olungelamhlali.

< Jeremiah 34 >