< Jeremiah 34 >

1 Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
Sana, joka tuli Jeremialle Herralta, kun Nebukadnessar, Baabelin kuningas, ja koko hänen sotajoukkonsa ja kaikki hänen valtansa alaisen maan valtakunnat ja kaikki kansat sotivat Jerusalemia ja kaikkia sen alaisia kaupunkeja vastaan; se kuului näin:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
"Näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Mene ja sano Sidkialle, Juudan kuninkaalle, sano hänelle: Näin sanoo Herra: Katso, minä annan tämän kaupungin Baabelin kuninkaan käsiin, ja hän polttaa sen tulella.
3 Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
Ja sinä et pääse hänen käsistään, vaan sinut otetaan kiinni ja annetaan hänen käsiinsä, ja sinun täytyy nähdä Baabelin kuningas silmästä silmään, ja hän puhuu sinun kanssasi suusta suuhun, ja sinä joudut Baabeliin.
4 “‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
Mutta kuule Herran sana, Sidkia, Juudan kuningas: Näin sanoo Herra sinusta: Sinä et ole kuoleva miekkaan.
5 ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
Sinä saat kuolla rauhassa; ja niinkuin sinun isillesi, aikaisemmille kuninkaille, jotka olivat ennen sinua, niin poltetaan sinun kunniaksesi kuolinsuitsutus ja sinulle pidetään valittajaiset ja huudetaan: 'Voi herraamme!' Sillä minä olen sen sanonut, sanoo Herra."
6 Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
Ja profeetta Jeremia puhui Sidkialle, Juudan kuninkaalle, kaikki nämä sanat Jerusalemissa,
7 Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
kun Baabelin kuninkaan sotajoukko taisteli Jerusalemia vastaan ja kaikkia vielä jäljellä olevia Juudan kaupunkeja vastaan, Laakista ja Asekaa vastaan, sillä nämä olivat jääneet jäljelle Juudan kaupungeista, varustetuista kaupungeista.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
Sana, joka tuli Jeremialle Herralta, sen jälkeen kuin kuningas Sidkia oli tehnyt liiton kaiken kansan kanssa, joka oli Jerusalemissa, ja heille julistanut vapautuksen,
9 Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
että jokaisen tuli päästää vapaaksi orjansa ja orjattarensa, hebrealainen mies ja hebrealainen nainen, niin etteivät heitä orjinansa pitäisi, ei kukaan juutalaista veljeänsä.
10 Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
Ja sen kuulivat kaikki päämiehet ja kaikki kansa, jotka olivat menneet tähän liittoon, että jokaisen tuli päästää vapaaksi orjansa ja orjattarensa eikä enää pitää heitä orjinansa; ja he tottelivat ja päästivät heidät.
11 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
Mutta jälkeenpäin he peräytyivät liitosta ja ottivat takaisin ne orjat ja orjattaret, jotka he olivat päästäneet vapaiksi, ja pakottivat heidät orjikseen ja orjattarikseen.
12 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Silloin tuli Jeremialle Herralta tämä Herran sana:
13 “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
"Näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Minä tein teidän isäinne kanssa liiton silloin, kun minä vein heidät pois Egyptin maasta, orjuuden pesästä, sanoen:
14 ‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
Seitsemän vuoden kuluttua päästäkää veljenne, hebrealainen: joka on myynyt itsensä sinulle ja palvellut sinua kuusi vuotta, se päästä luotasi vapaaksi. Mutta teidän isänne eivät kuulleet minua, eivät korvaansa kallistaneet.
15 Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
Vaan nyt te olette kääntyneet ja tehneet teon, joka on oikea minun silmissäni, julistaessanne vapautuksen kukin lähimmäisellensä, ja olette tehneet liiton minun kasvojeni edessä temppelissä, joka on otettu minun nimiini.
16 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
Mutta sitten te olette jälleen kääntyneet pois ja häväisseet minun nimeni: olette ottaneet takaisin jokainen orjansa ja orjattarensa, jotka olitte päästäneet vapaiksi omiin valtoihinsa, ja olette pakottaneet heidät olemaan orjinanne ja orjattarinanne.
17 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
Sentähden näin sanoo Herra: Te ette kuulleet minua ettekä julistaneetkaan vapautusta kukin veljellensä ja lähimmäisellensä; katso, minä julistan teille vapautuksen, sanoo Herra: menon miekkaan, ruttoon ja nälkään. Ja minä teen teidät kauhistukseksi kaikille valtakunnille maan päällä.
18 Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
Ja minä annan ne miehet, jotka ovat rikkoneet minun liittoni, jotka eivät ole pitäneet sen liiton sanoja, jonka he tekivät minun edessäni halkaisten kahtia uhrivasikan ja käyden sen puolikkaiden välitse, nämä miehet-
19 Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
Juudan ruhtinaat ja Jerusalemin ruhtinaat, hoviherrat ja papit sekä kaiken maan kansan, jotka kävivät vasikan puolikkaiden välitse-
20 Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
ne minä annan heidän vihollistensa käsiin, niiden käsiin, jotka etsivät heidän henkeänsä; ja heidän ruumiinsa joutuvat taivaan lintujen ja maan eläinten ruuaksi.
21 “Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
Ja Sidkian, Juudan kuninkaan, ja hänen ruhtinaansa minä annan heidän vihollistensa käsiin, niiden käsiin, jotka etsivät heidän henkeänsä, Baabelin kuninkaan sotajoukon käsiin, joka on lähtenyt pois teidän kimpustanne.
22 Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”
Katso, minä käsken heitä, sanoo Herra, ja palautan heidät tämän kaupungin kimppuun, ja he sotivat sitä vastaan, valloittavat sen ja polttavat sen tulella; ja Juudan kaupungit minä teen autioiksi, asujattomiksi."

< Jeremiah 34 >