< Jeremiah 33 >
1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
I doðe rijeè Gospodnja Jeremiji drugi put dok još bijaše zatvoren u trijemu od tamnice, govoreæi:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
Ovako veli Gospod koji èini to, Gospod koji udešava i potvrðuje to, kojemu je ime Gospod:
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
Zovi me, i odazvaæu ti se, i kazaæu ti velike i tajne stvari, za koje ne znaš.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Jer ovako veli Gospod Bog Izrailjev za domove ovoga grada i za domove careva Judinijeh koji æe se razvaliti opkopima i maèem,
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
I za one koji doðoše da se biju s Haldejcima, ali æe ih napuniti mrtvijem tjelesima ljudi koje æu pobiti u gnjevu svom i u jarosti svojoj odvrativ lice svoje od toga grada za svu zloæu njihovu:
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Evo, ja æu ga iscijeliti i zdravlje mu dati, iscijeliæu ih i pokazaæu im obilje mira, postojanoga mira.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Jer æu povratiti roblje Judino i roblje Izrailjevo, i sazidaæu ih kao prije.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
I oèistiæu ih od svakoga bezakonja njihova kojim mi sagriješiše, i oprostiæu im sva bezakonja njihova, kojima mi sagriješiše i kojima se odmetnuše od mene.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
I biæe mi milo ime i hvala i slava u svijeh naroda na zemlji koji æe èuti za sve dobro što æu im uèiniti, i uplašiæe se i drktaæe radi svega dobra i radi svega mira što æu im ja dati.
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Ovako veli Gospod: na ovom mjestu, za koje vi velite da je pusto i nema u njemu ni èovjeka ni živinèeta, u gradovima Judinijem i po ulicama Jerusalimskim opustjelim da nema èovjeka ni stanovnika ni živinèeta, opet æe se èuti
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
Glas radostan i glas veseo, glas ženikov i glas nevjestin, glas onijeh koji æe govoriti: slavite Gospoda nad vojskama, jer je dobar Gospod, jer je dovijeka milost njegova; koji æe prinositi prinose zahvalne u domu Gospodnjem; jer æu vratiti roblje ove zemlje kao što je bilo prije, govori Gospod.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Ovako veli Gospod nad vojskama: na ovom mjestu pustom, gdje nema èovjeka ni živinèeta, i u svijem gradovima njegovijem opet æe biti torovi pastirski da poèivaju stada.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
U gradovima po gorama, u gradovima po ravnici i u gradovima južnijem i u zemlji Venijaminovoj i oko Jerusalima i po gradovima Judinijem opet æe prolaziti stada ispod ruku brojaèevijeh, veli Gospod.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
Evo, idu dani, govori Gospod, kad æu izvršiti ovu dobru rijeè koju rekoh za dom Izrailjev i za dom Judin.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
U te dane i u to vrijeme uèiniæu da proklija Davidu klica prava, koja æe èiniti sud i pravdu na zemlji.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
U te dane spašæe se Juda, i Jerusalim æe stajati bez straha, i zvaæe se: Gospod pravda naša.
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Jer ovako veli Gospod: neæe nestati Davidu èovjeka koji bi sjedio na prijestolu doma Izrailjeva.
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
Ni sveštenicima Levitima neæe nestati preda mnom èovjeka koji bi prinosio žrtvu paljenicu i palio dar i klao žrtvu dovijeka.
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Potom doðe rijeè Gospodnja Jeremiji govoreæi:
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
Ovako veli Gospod: ako možete ukinuti zavjet moj za dan i zavjet moj za noæ da ne bude dana ni noæi na vrijeme,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Onda æe se ukinuti i moj zavjet s Davidom slugom mojim, da nema sina koji bi carovao na prijestolu njegovu, i s Levitima sveštenicima slugama mojim.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Kao što se ne može izbrojiti vojska nebeska ni izmjeriti pijesak morski, tako æu umnožiti sjeme Davida sluge svojega i Levita sluga svojih.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Opet doðe rijeè Gospodnja Jeremiji govoreæi:
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
Nijesi li vidio što reèe taj narod govoreæi: dvije porodice, koje bješe izabrao Gospod, odbaci ih? I ruže moj narod kao da veæ nije narod pred njima.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Ovako veli Gospod: ako nijesam postavio zavjeta svojega za dan i za noæ i uredbe nebesima i zemlji,
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
Onda æu i sjeme Jakovljevo i Davida sluge svojega odbaciti da ne uzimam od sjemena njegova onijeh koji æe vladati sjemenom Avramovijem, Isakovijem i Jakovljevijem; jer æu povratiti roblje njihovo i smilovaæu se na njih.