< Jeremiah 33 >
1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
Кувынтул Домнулуй а ворбит луй Иеремия а доуа оарэ, пе кынд ера ынкэ ынкис ын куртя темницей:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
„Аша ворбеште Домнул, каре фаче ачесте лукрурь, Домнул, каре ле урзеште ши ле ынфэптуеште, Ел, ал кэруй Нуме есте Домнул:
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
‘Кямэ-Мэ, ши-ць вой рэспунде ши ыць вой вести лукрурь марь, лукрурь аскунсе, пе каре ну ле куношть.’
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Кэч аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел деспре каселе четэций ачестея ши деспре каселе ымпэрацилор луй Иуда, каре вор фи сурпате ка сэ факэ лок пентру шанцуриле де ынтэрире ши пентру сэбий,
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
кынд вор ынаинта сэ лупте ымпотрива халдеенилор ши кынд се вор умпле ку трупуриле моарте але оаменилор пе каре-й вой лови ын мыния Мя ши ын урӂия Мя ши дин причина рэутэций кэрора Ымь вой аскунде Фаца де ачастэ четате:
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
‘Ятэ, ый вой да виндекаре ши сэнэтате, ый вой виндека ши ле вой дескиде ун извор богат ын паче ши крединчошие.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Вой адуче ынапой пе принший де рэзбой ай луй Иуда ши пе принший де рэзбой ай луй Исраел ши-й вой ашеза ярэшь ка одиниоарэ.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Ый вой курэци де тоате нелеӂюириле пе каре ле-ау сэвыршит ымпотрива Мя, ле вой ерта тоате нелеӂюириле прин каре М-ау супэрат ши прин каре с-ау рэзврэтит ымпотрива Мя.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
Четатя ачаста ва фи пентру Мине о причинэ де лаудэ ши де славэ принтре тоате нямуриле пэмынтулуй. Еле вор афла тот бинеле пе каре ли-л вой фаче, вор рэмыне мирате ши уймите де тоатэ феричиря ши де тоатэ пропэширя пе каре ле-о вой да.’
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Аша ворбеште Домнул: ‘Се вор май аузи ярэшь ын локул ачеста, деспре каре зичець кэ есте пустиу, кэ ну май аре оамень, нич добитоаче, се вор май аузи ярэшь ын четэциле луй Иуда ши пе улицеле Иерусалимулуй, пустиите, липсите де оамень, де локуиторь, де добитоаче,
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
стригэтеле де букурие ши стригэтеле де веселие, кынтечеле мирелуй ши кынтечеле миресей, гласул челор че зик: «Лэудаць пе Домнул оштирилор, кэч Домнул есте бун, кэч ын вяк цине ындураря Луй!», гласул челор че адук жертфе де мулцумире ын Каса Домнулуй. Кэч вой адуче ынапой пе принший де рэзбой ай цэрий ши ый вой ашеза ярэшь ка одиниоарэ’, зиче Домнул.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Аша ворбеште Домнул оштирилор: ‘Ын локул ачеста пустиу, фэрэ оамень ши фэрэ добитоаче, ши ын тоате четэциле луй, вор май фи ярэшь локуинце де пэсторь, каре-шь вор одихни турмеле. Ын четэциле де ла мунте,
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
ын четэциле дин кымпие, ын четэциле де ла мязэзи, ын цара луй Бениамин ши ын ымпрежуримиле Иерусалимулуй, ши ын четэциле луй Иуда, вор май трече ярэшь оиле пе суб мына челуй че ле нумэрэ’, зиче Домнул.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
‘Ятэ, вин зиле’, зиче Домнул, ‘кынд вой ымплини кувынтул чел бун пе каре л-ам спус деспре каса луй Исраел ши деспре каса луй Иуда.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
Ын зилеле ачеля ши ын времуриле ачеля вой фаче сэ рэсарэ луй Давид о Одраслэ неприхэнитэ, каре ва ынфэптуи дрептатя ши жудеката ын царэ.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
Ын зилеле ачеля, Иуда ва фи мынтуит ши Иерусалимул ва локуи ын линиште. Ши ятэ кум Ыл вор нуми: «Домнул, Неприхэниря ноастрэ».’
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Кэч аша ворбеште Домнул: ‘Давид ну ва фи липсит ничодатэ де ун урмаш каре сэ стя пе скаунул де домние ал касей луй Исраел.
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
Нич преоций ши левиций ну вор фи липсиць ничодатэ ынаинтя Мя де урмашь каре сэ адукэ ардерь-де-тот, сэ ардэ тэмые ымпреунэ ку даруриле де мынкаре ши сэ адукэ жертфе ын тоате зилеле.’”
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Кувынтул Домнулуй а ворбит луй Иеремия астфел:
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
„Аша ворбеште Домнул: ‘Дакэ путець сэ рупець легэмынтул Меу ку зиуа ши легэмынтул Меу ку ноаптя, аша ынкыт зиуа ши ноаптя сэ ну май фие ла время лор,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
атунч се ва путя рупе ши легэмынтул Меу ку робул Меу Давид, аша ынкыт сэ ну май айбэ фий каре сэ домняскэ пе скаунул луй де домние, ши легэмынтул Меу ку левиций, преоций, каре Ымь фак служба.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Ка оштиря черурилор, каре ну се поате нумэра, ши ка нисипул мэрий, каре ну се поате мэсура, аша вой ынмулци сэмынца робулуй Меу Давид ши пе левиций каре-Мь служеск.’”
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Кувынтул Домнулуй а ворбит луй Иеремия астфел:
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
„Н-ай бэгат де сямэ че зик оамений ачештя: ‘А лепэдат Домнул челе доуэ фамилий пе каре ле алесесе’? Атыт де мулт диспрецуеск ей пе попорул Меу кэ ну-л май привеск ка ун попор.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Аша ворбеште Домнул: ‘Дакэ н-ам фэкут легэмынтул Меу ку зиуа ши ку ноаптя, дакэ н-ам ашезат леӂиле черурилор ши але пэмынтулуй,
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
атунч вой лепэда ши сэмынца луй Иаков ши а робулуй Меу Давид ши ну вой май луа дин сэмынца луй пе чей че вор стэпыни песте урмаший луй Авраам, луй Исаак ши луй Иаков, кэч вой адуче ынапой пе принший лор де рэзбой ши вой авя милэ де ей!’”