< Jeremiah 33 >

1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la Ieremia a doua oară, în timp ce el era încă închis în curtea închisorii, spunând:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
Astfel spune DOMNUL făcătorul acestei cetăți, DOMNUL care a format-o, pentru a o întemeia; DOMNUL este numele lui:
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
Cheamă-mă și îți voi răspunde și îți voi arăta lucruri mari și puternice, pe care nu le cunoști.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Pentru că astfel spune DOMNUL, Dumnezeul lui Israel referitor la casele acestei cetăți și referitor la casele împăraților lui Iuda, care sunt dărâmate prin valurile de pământ și prin sabie;
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
Ei vin să lupte cu caldeenii, dar aceasta este pentru a le umple cu trupurile moarte ale oamenilor pe care i-am ucis în mânia mea și în furia mea și pentru toți cei a căror stricăciune, mi-am ascuns fața de această cetate.
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Iată, îi voi aduce sănătate și vindecare, și îi voi vindeca și le voi descoperi abundența păcii și adevărului.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Și îi voi face să se întoarcă pe cei captivi ai lui Iuda și pe cei captivi ai lui Israel și îi voi zidi ca la început.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Și îi voi curăți de toată nelegiuirea lor cu care au păcătuit împotriva mea; și le voi ierta toate nelegiuirile, prin care au păcătuit împotriva mea și prin care au încălcat legea împotriva mea.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
Și aceasta îmi va fi un nume de bucurie, o laudă și o onoare înaintea tuturor națiunilor pământului, care vor auzi despre tot binele pe care îl fac pentru ei; și ei se vor teme și se vor cutremura pentru toată bunătatea și pentru toată prosperitatea pe care i-o dau.
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Astfel spune DOMNUL: Din nou se va auzi în acest loc, despre care voi spuneți că va fi pustiit, fără om și fără animal, în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului, care sunt pustii, fără om și fără locuitor și fără animal,
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
Vocea bucuriei și vocea veseliei, vocea mirelui și vocea miresei, vocea celor care vor spune: Lăudați pe DOMNUL oștirilor, pentru că DOMNUL este bun, pentru că mila lui dăinuiește pentru totdeauna; și a celor care vor aduce sacrificiul de laudă în casa DOMNULUI. Pentru că voi face să se întoarcă pe cei captivi ai țării, ca la început, spune DOMNUL.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Din nou, în acest loc, care este pustiit, fără om și fără animal; și în toate cetățile lui, va fi o locuință de păstori care vor face turmele lor să se odihnească.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
În cetățile din munți, în cetățile din vale și în cetățile de la sud și în țara lui Beniamin și în locurile dimprejurul Ierusalimului și în cetățile lui Iuda vor trece din nou turmele pe sub mâinile celui care le numără, spune DOMNUL.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
Iată, vin zilele, spune DOMNUL, când voi împlini acel lucru bun pe care l-am promis casei lui Israel și casei lui Iuda.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
În acele zile și în acel timp voi face Lăstarul dreptății să crească pentru David; și el va face judecată și dreptate în țară.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
În acele zile Iuda va fi salvat și Ierusalimul va locui în siguranță; și acesta este numele cu care va fi numit: DOMNUL dreptatea noastră.
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Pentru că astfel spune DOMNUL: Lui David nu îi va lipsi niciodată un bărbat să șadă pe tronul casei lui Israel;
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
Nici preoților, leviților, nu le va lipsi un bărbat înaintea mea pentru a oferi ofrande arse și pentru a aprinde daruri de mâncare și pentru a face sacrificii continuu.
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Și cuvântul DOMNULUI a venit la Ieremia, spunând:
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
Astfel spune DOMNUL: Dacă puteți să rupeți legământul meu referitor la ziuă și legământul meu referitor la noapte astfel încât să nu fie zi și noapte la timpul lor;
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Atunci poate de asemenea fi rupt legământul meu cu David, servitorul meu, ca el să nu aibă fiu să domnească pe tronul lui; și cu leviții, preoții, servitorii mei.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Așa cum oștirea cerului nu poate fi numărată, nici nisipul mării măsurat; tot astfel voi înmulți sămânța lui David, servitorul meu, și pe leviții care îmi servesc.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la Ieremia, spunând:
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
Nu ai luat aminte la ceea ce acest popor a vorbit, spunând: Cele două familii pe care DOMNUL le-a ales, le-a lepădat el? Astfel, ei au disprețuit pe poporul meu, ca ei să nu mai fie o națiune înaintea lor.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Astfel spune DOMNUL: Dacă legământul meu nu este nici cu ziua, nici cu noaptea; și dacă eu nu am rânduit rânduielile cerului și ale pământului;
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
Atunci voi lepăda eu sămânța lui Iacob și pe David, servitorul meu, astfel încât să nu iau pe vreunii din sămânța lui să fie conducători peste sămânța lui Avraam, Isaac și Iacob, pentru că îi voi face să se întoarcă din captivitate și voi avea milă de ei.

< Jeremiah 33 >