< Jeremiah 33 >

1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
O mahinda-inĩ macio Jeremia aarĩ muohe kũu nja-inĩ ya arangĩri, ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyamũkinyĩire riita rĩa keerĩ, akĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
“Ũũ nĩguo Jehova ekuuga, o we ũrĩa wombire thĩ, Jehova ũrĩa watũmire thĩ ĩgĩe ho, na akĩmĩhaanda, Jehova nĩrĩo rĩĩtwa rĩake:
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
‘Ta kĩngaĩre, na niĩ nĩngũgwĩtĩka na ngwĩre maũndũ manene na matangĩtuĩrĩka, marĩa ũtooĩ.’
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Nĩgũkorwo ũũ nĩguo Jehova, Ngai wa Isiraeli, ekuuga ũhoro ũkoniĩ nyũmba iria irĩ itũũra rĩĩrĩ inene, o na nyũmba cia ũthamaki wa Juda o icio ciatharirio nĩguo indo iria ciakĩte kuo ihũthĩrwo kwĩgitĩra kuuma kũrĩ ihumbu cia tĩĩri iria cikũrigiicĩirie o na kuuma kũrĩ rũhiũ rwa njora,
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
makĩhũũrana na andũ a Babuloni: ‘Nyũmba icio ciothe nĩikaiyũrio ciimba cia andũ arĩa ngooragithia ndĩ na marakara na mangʼũrĩ. Nĩngahitha itũũra rĩĩrĩ inene ũthiũ wakwa nĩ ũndũ wa waganu wao wothe.
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
“‘No rĩrĩ, nĩngarĩrehera ũgima wa mwĩrĩ na ndĩrĩhonie. Ningĩ nĩngahonia andũ akwa na ndũme matũũre makenagĩra thayũ mũingĩ na ũgitĩri.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Nĩngacookia andũ a Juda na a Isiraeli gũkũ ndĩmarute kũrĩa matũũrĩte marĩ atahe, njooke ndĩmaake rĩngĩ, maikare o ta ũrĩa maatariĩ mbere.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Nĩngamatheria mathirwo nĩ mehia mothe marĩa mananjĩhĩria na ndĩmarekere mehia mao mothe ma kũrega kũnjathĩkĩra.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
Hĩndĩ ĩyo itũũra rĩĩrĩ inene nĩrĩkandehithĩria ngumo na gĩkeno, na gĩtĩĩo, na ũgooci, o na gwĩkĩrĩrwo mbere ya ndũrĩrĩ ciothe cia gũkũ thĩ rĩrĩa andũ akuo makaigua ũhoro wa maũndũ mothe mega marĩa ndĩmekagĩra; nĩkũgega makaagega na mainaine moona ũingĩ wa ũgaacĩru na thayũ ũrĩa ngaahe itũũra rĩu.’
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
“Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Mwaragia ũhoro ũkoniĩ kũndũ gũkũ, mũkoiga atĩrĩ, “Nĩ kũndũ kũnũhe gũtarĩ kĩndũ, na gũtarĩ andũ kana nyamũ.” No thĩinĩ wa matũũra ma Juda na njĩra-inĩ iria nene cia Jerusalemu, o kũu gũthaamĩtwo gũkaaga andũ kana nyamũ-rĩ, nĩgũgacooka kũiguuo
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
mĩgambo ya gĩkeno na ya gũcanjamũka, na mĩgambo ya mũhiki na mũhikania, o na mĩgambo ya andũ arĩa mararehe indo cia maruta ma gũcookia ngaatho nyũmba-inĩ ya Jehova, makiugaga atĩrĩ, “‘“Cookeriai Jehova Mwene-Hinya-Wothe ngaatho, nĩ ũndũ Jehova nĩ mwega; wendo wake ũtũũraga tene na tene.” Nĩgũkorwo nĩngacookeria bũrũri ũyũ ũgaacĩru waguo, o ta ũrĩa warĩ kuo mbere,’ nĩguo Jehova ekuuga.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
“O na ningĩ Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ: ‘Kũndũ gũkũ kũnũhe na gũtarĩ andũ kana nyamũ-rĩ, matũũra makuo mothe nĩmagacooka kũgĩa ũrĩithio kũrĩa arĩithi makaarahagia ndũũru ciao cia mbũri.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
Thĩinĩ wa matũũra ma bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma, o na marĩa marĩ magũrũ-inĩ ma irĩma cia mwena wa ithũĩro, o na ma Negevu, bũrũri-inĩ wa Benjamini, o na tũtũũra-inĩ tũrĩa tũrigiicĩirie Jerusalemu o na matũũra-inĩ ma Juda-rĩ, ndũũru cia mbũri nĩigacooka kũhĩtũkĩra guoko-inĩ kwa ũrĩa ũcitaraga,’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
“Jehova ekuuga atĩrĩ, ‘Matukũ nĩmagooka rĩrĩa ngaahingia kĩĩranĩro gĩakwa kĩa wega kĩrĩa nderĩire nyũmba ya Isiraeli na nyũmba ya Juda.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
“‘Matukũ-inĩ macio o na ihinda rĩu-rĩ, nĩngarahũrĩra Daudi mũndũ mũthingu ũgerekanĩtio na rũhonge rwa mũtĩ; nĩageekaga maũndũ marĩa magĩrĩire na ma kĩhooto bũrũri-inĩ.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
Matukũ-inĩ macio, Juda nĩgũkahonokanio, nakuo Jerusalemu gũtũũre kũrĩ kũgitĩre. Nake ageetagwo rĩĩtwa rĩĩrĩ Jehova-Ũthingu-Witũ.’
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Nĩgũkorwo Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Daudi ndarĩ hĩndĩ akaaga mũndũ wa gũikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene kĩa nyũmba ya Isiraeli,
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
kana athĩnjĩri-Ngai, arĩa Alawii, mage mũndũ wa gũikara mbere yakwa hĩndĩ ciothe acinage maruta ma njino, na maruta ma mũtu, o na arutage magongona marĩa ma o mũthenya.’”
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Ningĩ ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyakinyĩrĩire Jeremia akĩĩrwo atĩrĩ,
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
“Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Angĩkorwo inyuĩ mwahota gũthũkia kĩrĩkanĩro gĩakwa na mũthenya, na kĩrĩkanĩro gĩakwa na ũtukũ, nĩgeetha mũthenya na ũtukũ itigacooke kũgĩa hĩndĩ ĩrĩa yagĩrĩire-rĩ,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
nakĩo kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndaarĩkanĩire na Daudi ndungata yakwa, o na kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndaarĩkanĩire na Alawii arĩa athĩnjĩri-Ngai arĩa matungataga marĩ mbere yakwa, kĩahota gũthũkio, nake Daudi akĩage gũcooka kũgĩa na mũndũ wa rũciaro rwake wa gũthamakaga arĩ gĩtĩ-inĩ gĩake kĩa ũnene.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Nĩngatũma njiaro cia Daudi ndungata yakwa, o na Alawii acio matungataga marĩ mbere yakwa maingĩhe o ta njata cia igũrũ iria itangĩtarĩka nĩ ũndũ wa kũingĩha, o na ta mũthanga ũrĩa ũrĩ hũgũrũrũ-inĩ cia iria ũrĩa ũtangĩthimĩka ũrĩa ũigana.’”
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
O rĩngĩ ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyakinyĩrĩire Jeremia akĩĩrwo atĩrĩ,
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
“Kaĩ ũtamenyete andũ aya maroiga atĩrĩ, ‘Jehova nĩatete mothamaki marĩa meerĩ ethuurĩire’? Nĩ ũndũ ũcio mamenaga andũ akwa na matimoonaga ta marĩ rũrĩrĩ.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Angĩkorwo ndiigĩte kĩrĩkanĩro gĩakwa na mũthenya na ũtukũ, o na mawatho marĩa marũmu ma igũrũ na thĩ-rĩ,
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
hĩndĩ ĩyo nĩngagĩteanĩria njiaro cia Jakubu na cia Daudi ndungata yakwa, na njage gũthuura ũmwe wa aanake ake atuĩke wa gũthamakĩra njiaro cia Iburahĩmu, na cia Isaaka, na cia Jakubu. Nĩgũkorwo nĩngamacookeria ũgaacĩru wao na ndĩmaiguĩre tha.’”

< Jeremiah 33 >