< Jeremiah 33 >

1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
La parole de l’Eternel fut adressée une seconde fois à Jérémie, alors qu’il était encore détenu dans la cour de la prison, en ces termes:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
"Voici ce que dit l’Eternel qui prépare tout cela, qui le conçoit et le réalise l’Eternel est son nom:
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
Invoque-moi et je te répondrai; je te révélerai de grandes choses, des choses inaccessibles que tu ne connais point.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Oui, ainsi parle l’Eternel, Dieu d’Israël, au sujet des maisons de cette ville et des maisons des rois de Juda détruites par les machines de guerre et le glaive,
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
maisons d’où l’on est allé combattre les Chaldéens, de façon à les joncher de corps humains que j’ai frappés dans ma colère et mon indignation, après avoir détourné ma face de cette ville, si pleine de perversité:
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Voici, j’apporterai à cette ville un remède efficace, la guérison, je rétablirai leur santé et leur ouvrirai une source abondante de paix et de vérité.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Je ramènerai les captifs de Juda et les captifs d’Israël et les installerai comme autrefois.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Je les purifierai de toutes les fautes commises contre moi, je pardonnerai tous les péchés par lesquels ils se sont rendus coupables et infidèles à mon égard.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
Et cette ville sera pour moi une gloire, une cause de joie, un honneur et un triomphe en face de toutes les nations de la terre, qui apprendront tout le bien dont je la comble, et seront saisies d’émoi et de crainte à la vue de tout ce bien-être et de cette pleine sécurité que je lui octroie.
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Ainsi parle l’Eternel: De nouveau on entendra dans ce lieu-ci qui, dites-vous, est ruiné, privé d’hommes et d’animaux, dans les villes de Juda et les rues de Jérusalem, désolées faute d’hommes, faute d’habitants et faute de bétail,
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
on entendra des accents d’allégresse, des cris de joie, le chant du fiancé et le chant de la fiancée, la voix de ceux qui s’écrient: "Rendez hommage à l’Eternel-Cebaot, car l’Eternel est bon et sa grâce est immuable!" tout en apportant des offrandes au Temple du Seigneur, car je rétablirai les exilés de ce pays, comme ils y étaient jadis, dit l’Eternel.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: De nouveau, il y aura dans cette contrée qui est en ruines, privée aussi bien d’animaux que d’hommes, et dans toutes ses villes, des stations pour les bergers qui y feront gîter leurs troupeaux.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
Dans les villes de la montagne, dans les villes de la plaine, dans les villes du Midi, sur le territoire de Benjamin, aux alentours de Jérusalem et dans les villes de Juda, les brebis défileront de nouveau sous les regards pour être comptées, dit l’Eternel.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
Voici, des jours vont venir, dit l’Eternel, où j’accomplirai la bonne promesse que j’ai faite à la maison d’Israël et à la maison de Juda.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
En ces jours et à cette époque, je ferai sortir de David un rejeton juste, qui exercera le droit et la justice dans le pays.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
En ces jours, Juda sera libéré et Jérusalem vivra en sécurité, et voici le nom dont on la désignera: "l’Eternel est notre droit!"
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Ainsi, en effet, parle l’Eternel: "Jamais il ne manquera à David un descendant pour s’asseoir sur le trône de la maison d’Israël.
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
De même, les prêtres-lévites ne cesseront d’avoir devant moi des descendants pour offrir des holocaustes, faire fumer des oblations et pourvoir aux sacrifices en tout temps."
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
La parole de l’Eternel fut adressée à Jérémie en ces termes:
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
"Ainsi parle le Seigneur: Si vous pouvez rompre mon pacte avec le jour et mon pacte avec la nuit, empêcher le jour et la nuit d’apparaître en leur temps,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
alors aussi pourra être rompu mon pacte avec David, pour qu’il n’ait plus de fils occupant son trône, ainsi que mon pacte avec les lévites, les prêtres, mes ministres.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
L’Armée céleste ne saurait être dénombrée, ni mesuré le sable de la mer: ainsi je multiplierai la postérité de mon serviteur David et les lévites attachés à mon service."
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
La parole du Seigneur fut adressée à Jérémie en ces termes:
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
"Ne vois-tu pas quels discours tiennent ces gens? Ils disent: Les deux familles que l’Eternel avait élues, il les a rejetées! De la sorte ils outragent mon peuple comme s’il avait cessé de former une nation à leurs yeux.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Ainsi parle le Seigneur: Si mon pacte avec le jour et la nuit pouvait ne plus subsister, si je cessais de fixer des lois au ciel et à la terre,
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
alors seulement je pourrais repousser la postérité de Jacob et de mon serviteur David, en n’y prenant pas de princes pour régner sur les enfants d’Abraham, d’Isaac et de Jacob, quand je les aurai ramenés de l’exil et pris en pitié."

< Jeremiah 33 >