< Jeremiah 33 >

1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
La parole de Yahweh fut adressée à Jérémie une seconde fois, lorsqu’il était encore enfermé dans la cour de garde, — en ces termes:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
Ainsi parle Yahweh qui fait cela, Yahweh qui le conçoit pour l’exécuter, — Yahweh est son nom: —
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
Invoque-moi et je te répondrai; je te manifesterai des choses grandes et inaccessibles, que tu ne sais pas.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Car ainsi parle Yahweh, Dieu d’Israël, au sujet des maisons de cette ville, et des maisons du roi de Juda, abattues pour faire face aux machines de guerre et à l’épée;
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
et au sujet de ceux qui vont combattre les Chaldéens, pour remplir ces maisons des cadavres des hommes, que je frappe dans ma colère et ma fureur, et à cause de la méchanceté desquels je cache ma face à cette ville:
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Voici que je lui applique un pansement, et que je la soigne pour la guérir; et je leur ferai voir une abondance de paix et de sécurité.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Je ramènerai les exilés de Juda et les exilés d’Israël, et je les rétablirai comme ils étaient autrefois.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Je les purifierai de toute leur iniquité, par laquelle ils ont péché contre moi; je leur pardonnerai toutes leurs iniquités, par lesquelles ils m’ont offensé, par lesquelles ils se sont révoltés contre moi.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
Et le nom de cette ville sera pour moi un nom de joie, de louange et de gloire parmi toutes les nations de la terre, qui apprendront tout le bien que je leur ferai; elles seront effrayées et frémiront, en voyant tout le bonheur et la prospérité que je leur donnerai.
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Ainsi parle Yahweh: On entendra encore — dans ce lieu dont vous dites: « C’est un désert sans homme ni bête »; dans les villes de Juda et dans les rues de Jérusalem, qui sont désolées, sans homme, sans habitant, ni bête —
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
les cris de joie et les cris d’allégresse, le chant du fiancé et le chant de la fiancée, la voix de ceux qui disent: « Louez Yahweh des armées, car Yahweh est bon, et sa miséricorde dure à jamais! » de ceux qui apportent leurs sacrifices d’actions de grâces à la maison de Yahweh. Car je ferai revenir les exilés de ce pays, pour qu’ils soient comme à l’origine, dit Yahweh.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Ainsi parle Yahweh des armées: Il y aura encore dans ce lieu, désert, sans homme, ni bête, et dans toutes ses villes, des abris, pour les pasteurs qui y feront reposer leurs troupeaux.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
Dans les villes de la montagne et dans les villes de la sephélah et dans les villes du négéb, dans le pays de Benjamin et dans les environs de Jérusalem, et dans les villes de Juda, les troupeaux passeront encore sous la main de celui qui les compte, dit Yahweh.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
Voici que des jours viennent, — oracle de Yahweh, où j’accomplirai la bonne parole que j’ai dite au sujet de la maison d’Israël et de la maison de Juda.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
En ces jours-là et en ce temps-là, je ferai germer à David un germe juste, qui exercera le droit et la justice sur la terre.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
En ces jours-là, Juda sera sauvé et Jérusalem habitera en assurance, et on l’appellera Yahweh-notre-justice.
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Car ainsi parle Yahweh: Il ne manquera jamais à David de descendant assis sur le trône de la maison d’Israël.
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
Et aux prêtres lévites, il ne manquera jamais devant moi d’homme, pour offrir l’holocauste, pour faire fumer l’oblation, et faire le sacrifice tous les jours.
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Et la parole de Yahweh fut adressée à Jérémie en ces termes:
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
Ainsi parle Yahweh: Si vous pouvez rompre mon alliance avec le jour, et mon alliance avec la nuit, en sorte que le jour et la nuit ne soient plus en leur temps,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
alors aussi mon alliance sera rompue avec David mon serviteur, en sorte qu’il n’ait plus de fils qui règne sur son trône, et avec les lévites prêtres qui font mon service.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Comme l’armée des cieux ne se compte pas, et comme le sable de la mer ne se mesure pas, ainsi je multiplierai la race de David, mon serviteur, et les lévites qui font mon service.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Et la parole de Yahweh fut adressée à Jérémie en ces termes:
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
N’as-tu pas vu ce que ce peuple dit en ces termes: « Yahweh a rejeté les deux familles qu’il avait choisies! » Ainsi ils méprisent mon peuple, au point que, devant eux, il n’est plus une nation!
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Ainsi parle Yahweh: Si je n’ai pas établi mon alliance avec le jour et la nuit, et si je n’ai pas posé les lois du ciel et de la terre,
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
je rejetterai aussi la postérité de Jacob et de David mon serviteur, au point de ne plus prendre dans sa postérité des chefs, pour la race d’Abraham, d’Isaac et de Jacob! Car je ferai revenir les captifs et j’aurai compassion d’eux.

< Jeremiah 33 >