< Jeremiah 33 >

1 Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
Jeremiah thongim thung paung o naah, Angraeng ih lok anih khaeah angzoh let;
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
long sahkung Angraeng, Angraeng mah ni hmuen boih to sak moe, caksak; anih ih ahmin loe Angraeng, tiah oh.
3 ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
Na kawk oh, kang pathim o han; na panoek o ai ih, kalen parai hmuennawk to kang thuih o han, tiah a thuih.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
Israel Sithaw, Angraeng mah, misa pakaahaih ahmuen, sumsen hoiah kamro hae vangpui thung ih im hoi Judah siangpahrang ih im kawng pongah hae tiah thuih;
5 nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
Khaldian kaminawk loe misatuk hanah angzoh o, toe hae ahmuen loe palung ka phuihaih, kanung parai palungphuihaih hoiah ka hum ih kami qok hoiah ni koi tih; Jerusalem kaminawk mah sak o ih sethaihnawk pongah hae vangpui hoiah mikhmai ka hawk ving boeh.
6 “‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
Khenah, to tiah oh pacoengah nganprakhaih hoi ngantuihaih to kang sin han; nihcae to ngan ka tuisak moe, monghaih hoi loktang to kam tuengsak han.
7 Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
Judah hoi Israel loe misong ohhaih thung hoiah kam laemsak moe, nihcae to tangsuek nathuem ih baktih toengah ka ohsak let han.
8 Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
Ka nuiah a sak o ih zaehaihnawk to ka ciimsak boih han; kai misa ah ang suek o haih, zaehaihnawk to ka tahmen pae boih han boeh.
9 Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
To naah hae vangpui loe kang hoehaih, long kaminawk boih hmaa ah pakoehhaih hoi saphawhaih ah om ueloe, hae vangpui han ka sak ih hoihaihnawk boih to panoek o tih boeh; hae vangpui ah ka sak ih hoihaih hoi khosak hoihaihnawk boih pongah, kaminawk mah zithaih hoi tasoehhaih doeh tawn o tih.
10 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
Angraeng mah hae tiah thuih: Nangcae mah, hae ahmuen loe pongsut boeh, kami hoi taw ih moi doeh om ai boeh, tiah na thuih o. Toe kami om ai, moi doeh om ai; Judah vangnawk loe angqai krang boeh, tiah na thuih o ih ahmuen hoi Jerusalem loklamnawk ah,
11 Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
anghoehaih lok, oephaih lok, zu la kami hoi sava sah kaminawk ih lok thaih lethaih to om tih. Angraeng loe hoih, a palungnathaih loe zungzan khoek to cak poe pongah, misatuh kaminawk ih Angraeng to saphaw oh, tiah thui kaminawk ih lok, Angraeng im ah pakoehhaih hoi angbawnhaih sah kaminawk ih lok to thaih o let tih; misong ah kalaem prae kaminawk to tangsuek ih baktiah ka ohsak let han, tiah Angraeng mah thuih.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
Misatuh kaminawk ih Angraeng Sithaw mah, Kami om ai, moi kasan doeh om ai ah kapong sut, hae ahmuen hoi vangpuinawk boih loe tuu toep kaminawk mah angmacae ih tuu pacahhaih ahmuen ah om let tih.
13 Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
Mae nui ih vangpui, azawn ih vangpui, aloih bang ih vangpui, Benjamin prae, Jerusalem taeng ih ahmuen, Judah vangpuinawk ah tuu toep kaminawk mah tuu pacah o let tih, tiah Angraeng mah thuih.
14 “‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
Khenah, Israel hoi Judah imthung takoh khaeah, kahoih hmuen sak hanah lokkam ih baktiah koephaih ni to om tih.
15 “‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
To ni hoi atue naah loe David thung hoiah toenghaih tanghang to ka tacawtsak han; anih loe toenghaih hoi kamsoem ah lokcaek tih.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
To na niah Judah to pahlong ueloe, Jerusalem loe kamongah om tih boeh; anih ih ahmin loe aicae toenghaih Angraeng, tiah kawk o tih.
17 Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
Angraeng mah hae tiah thuih; Israel imthung takoh ih angraeng tangkhang nuiah anghnu han koi David ih atii loe boeng thai mak ai;
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
ka hmaa ah hmai angbawnhaih kasah, angbawnhaih moi hmai pakhaem, Levi acaeng qaimanawk doeh, boeng thai ai angbawnhaih to sak hanah kami vawt o sut mak ai, tiah a thuih.
19 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
Angraeng ih lok Jeremiah khaeah angzoh moe,
20 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
Angraeng mah, Ka suek ih khodai lokmaihaih hoi khoving lokmaihaih to na phraek o thaih moe, angmah ih atue ah khodai hoi khoving om ai naah ni,
21 Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Ka tamna David hoi ka sak ih lokmaihaih to amro ueloe, David ih angraeng tangkhang nuiah anghnu han koi David ih caa doeh om mak ai.
22 Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
Van ih cakaehnawk loe kroek laek ai moe, tuipui ih savuet doeh tah laek thai ai baktih toengah, ka tamna David ih atii hoi ka hmaa ah toksah Levi kaminawk to kang pungsak han, tiah thuih.
23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
Angraeng ih lok Jeremiah khaeah angzoh,
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
Angraeng mah qoih ih imthong hnetto loe vah ving boeh, tiah prae kalah kaminawk mah thuih o ih lok to na thaih maw? Nihcae mah kai ih acaengnawk to acaeng kami ai baktiah khet patoek o boeh.
25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
Angraeng mah, Jeremiah Kai loe khodai hoi khoving hanah lok ka maihaih to ka phrae ai, van hoi long mah lok tahngai hanah ukhaih dan doeh ka caksak.
26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”
To pongah Abraham, Issac hoi Jacob ih caanawk to ka va ving mak ai; Jacob ih caa hoi ka tamna David ih caanawk loe nihcae ukkung siangpahrang ah om o poe tih, tiah lok ka maihaih doeh ka phrae mak ai; nihcae to misong hoi kam laemsak let han, nihcae nuiah tahmenhaih ka tawnh han boeh, tiah a thuih.

< Jeremiah 33 >