< Jeremiah 32 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
Esta é a palavra que veio de Javé a Jeremias no décimo ano de Zedequias, rei de Judá, que foi o décimo oitavo ano de Nabucodonosor.
2 Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
Agora, naquela época, o exército do rei da Babilônia estava sitiando Jerusalém. Jeremias, o profeta, estava fechado na corte da guarda, que estava na casa do rei de Judá.
3 Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
Pois Zedequias, rei de Judá, tinha-o calado, dizendo: “Por que profetizas e dizes: 'Javé diz: “Eis que eu entregarei esta cidade na mão do rei da Babilônia, e ele a tomará”;
4 Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
e Zedequias, rei de Judá, não escapará da mão dos caldeus, mas certamente será entregue na mão do rei da Babilônia, e falará com ele boca a boca, e seus olhos verão seus olhos;
5 Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
e ele trará Zedequias à Babilônia, e ele estará lá até que eu o visite”, diz Javé, “embora lutes com os caldeus, não prosperarás?”’”
6 Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Jeremias disse: “A palavra de Javé veio a mim, dizendo:
7 Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
'Eis que Hanamel, filho de Shallum, seu tio, virá a você, dizendo: “Compre meu campo que está em Anathoth; pois o direito de redenção é seu para comprá-lo””.
8 “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
“Então Hanamel, filho de meu tio, veio até mim na corte da guarda de acordo com a palavra de Javé, e me disse: “Por favor, compre meu campo que está em Anathoth, que está na terra de Benjamin; pois o direito de herança é seu, e a redenção é sua. Compre-o para si mesmo”. “Então eu sabia que esta era a palavra de Yahweh”.
9 Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
Comprei o campo que estava em Anathoth de Hanamel, filho de meu tio, e pesei-lhe o dinheiro, até dezessete siclos de prata.
10 Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
I assinou a escritura, selou-a, chamou testemunhas, e pesou o dinheiro na balança para ele.
11 Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
Então eu peguei a escritura da compra, tanto a que foi selada, contendo os termos e condições, como a que estava aberta;
12 Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
e entreguei a escritura da compra a Baruch o filho de Neriah, o filho de Mahseiah, na presença de Hanamel o filho de meu tio, e na presença das testemunhas que assinaram a escritura da compra, diante de todos os judeus que estavam sentados no tribunal da guarda.
13 “Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
“Ordenei a Baruch diante deles, dizendo:
14 èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
Yahweh dos Exércitos, o Deus de Israel, diz: 'Pegue estas escrituras, esta escritura de compra que é selada, e esta escritura que é aberta, e coloque-as num vaso de barro, para que durem muitos dias'.
15 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
Para Javé dos Exércitos, o Deus de Israel diz: 'Casas e campos e vinhedos serão mais uma vez comprados nesta terra'.
16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
Agora depois de ter entregue a escritura da compra a Baruch, o filho de Neriah, rezei para Yahweh, dizendo,
17 “Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
“Ah Senhor Yahweh! Eis que fizestes os céus e a terra por vosso grande poder e por vosso braço estendido. Não há nada muito difícil para você.
18 O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
Você demonstra bondade amorosa para com milhares, e retribui a iniquidade dos pais no seio de seus filhos depois deles. O grande, o poderoso Deus, Yahweh dos Exércitos é seu nome:
19 Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
grande em conselho e poderoso em trabalho; cujos olhos estão abertos a todos os caminhos dos filhos dos homens, para dar a todos segundo seus caminhos e segundo o fruto de seus feitos;
20 O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
que realizou sinais e maravilhas na terra do Egito, até hoje, tanto em Israel como entre outros homens; e fez-se um nome, como é hoje;
21 O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
e tirou seu povo Israel da terra do Egito com sinais, com maravilhas, com mão forte, com braço estendido e com grande terror;
22 Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
e lhes deu esta terra, que você jurou a seus pais dar-lhes, uma terra que fluía com leite e mel.
23 Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
Eles entraram e a possuíram, mas não obedeceram a sua voz e não entraram em sua lei. Eles não fizeram nada de tudo o que você lhes ordenou que fizessem. Portanto, o senhor fez com que todo esse mal lhes acontecesse.
24 “Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
“Eis que foram construídas rampas de cerco contra a cidade para tomá-la. A cidade é entregue na mão dos caldeus que lutam contra ela, por causa da espada, da fome e da pestilência. O que vocês disseram aconteceu. Vejam, vocês o vêem.
25 Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
O Senhor Javé me disse: “Compre o campo por dinheiro e chame testemunhas;” enquanto a cidade é entregue na mão dos caldeus”. '
26 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
Então veio a palavra de Javé a Jeremias, dizendo:
27 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
“Eis que eu sou Javé, o Deus de toda a carne”. Há algo muito difícil para mim?
28 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
Portanto Yahweh diz: Eis que eu entregarei esta cidade na mão dos caldeus, e na mão de Nabucodonosor, rei da Babilônia, e ele a tomará.
29 Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
Os caldeus, que lutam contra esta cidade, virão e incendiarão esta cidade, e a queimarão com as casas sobre cujos telhados ofereceram incenso a Baal, e derramaram ofertas de bebida a outros deuses, para me provocar à ira.
30 “Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
“Pois as crianças de Israel e as crianças de Judá só fizeram o que era mau aos meus olhos desde sua juventude; pois as crianças de Israel só me provocaram à raiva com o trabalho de suas mãos, diz Javé.
31 Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
Pois esta cidade tem sido para mim uma provocação da minha ira e da minha ira desde o dia em que a construíram até hoje, para que eu a removesse de diante da minha face,
32 Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
por causa de todo o mal dos filhos de Israel e dos filhos de Judá, que eles fizeram para me provocar à ira - eles, seus reis, seus príncipes, seus sacerdotes, seus profetas, os homens de Judá, e os habitantes de Jerusalém.
33 Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
Eles viraram as costas para mim, e não seus rostos. Embora eu os tenha ensinado, levantando-me cedo e ensinando-os, eles ainda não escutaram para receber instrução.
34 Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
Mas eles colocaram suas abominações na casa que é chamada pelo meu nome, para profaná-la.
35 Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
Construíram os lugares altos de Baal, que estão no vale do filho de Hinnom, para fazer passar seus filhos e suas filhas através do fogo a Molech, que eu não lhes ordenei. Nem me veio à mente, que eles deveriam fazer esta abominação, para fazer Judá pecar”.
36 “Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
Agora, portanto, Javé, o Deus de Israel, diz a respeito desta cidade, sobre a qual você diz: “Ela está entregue na mão do rei da Babilônia pela espada, pela fome e pela peste:”
37 Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
“Eis que os congregarei de todos os países onde os expulsei em minha ira, e em minha ira, e em grande indignação; e os trarei novamente a este lugar. Vou fazê-los habitar em segurança.
38 Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Então eles serão meu povo, e eu serei seu Deus.
39 Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
Dar-lhes-ei um coração e um caminho, para que me temam para sempre, para seu bem e para o bem de seus filhos depois deles.
40 Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
Farei um pacto eterno com eles, que não deixarei de segui-los, para fazer-lhes o bem. Porei meu medo em seus corações, para que eles não se afastem de mim.
41 Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
Yes, regozijar-me-ei por eles para fazê-los bem, e os plantarei nesta terra seguramente com todo o meu coração e com toda a minha alma”.
42 “Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
Para Yahweh diz: “Assim como trouxe todo este grande mal sobre este povo, assim trarei sobre eles todo o bem que lhes prometi”.
43 Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
Os campos serão comprados nesta terra, sobre a qual você diz: 'É desolada, sem homem nem animal'. É entregue na mão dos caldeus”.
44 Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”
Men comprará campos por dinheiro, assinará as escrituras, os selará e chamará testemunhas, na terra de Benjamim, e nos lugares ao redor de Jerusalém, nas cidades de Judá, nas cidades da região montanhosa, nas cidades da planície, e nas cidades do Sul; pois farei com que seu cativeiro seja revertido”, diz Yahweh.

< Jeremiah 32 >