< Jeremiah 32 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
Słowo, które się stało do Jeremijasza od Pana roku dziesiątego Sedekijasza, króla Judzkiego, który jest rok ośmnasty Nabuchodonozora.
2 Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
(A wtenczas wojsko króla Babilońskiego obległo było Jeruzalem, a Jeremijasz prorok zamknięty był w sieni ciemnicy, która była w domu króla Judzkiego.
3 Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
Bo go był dał wsadzić Sedekijasz, król Judzki, mówiąc: Czemu ty prorokujesz, mówiąc: Tak mówi Pan: Oto Ja to miasto podam w rękę króla Babiolońskiego, i weźmie je?
4 Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
Sedekijasz także król Judzki nie ujdzie ręki Chaldejczyków; ale zapewne wydany będzie w rękę króla Babilońskiego, i będą mówiły usta jego z usty jego, a oczy jego oczy jego ogladają.
5 Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
I zawiedzie Sedekijasza do Babilonu, aby tam był, aż go nawiedzę, mówi Pan; ponieważ walczycie z Chaldejczykami, nie poszczęści się wam.)
6 Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Tedy rzekł Jeremijasz: Stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
7 Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
Oto Chanameel, syn Salluma, stryja twego, przyjdzie do ciebie, mówiąc: Kup sobie rolę moję, która jest w Anatot; bo tobie należy prawem bliskości, abyś ją kupił.
8 “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
A gdy przyszedł do mnie Chanameel, syn stryja mego, według słowa Pańskiego do sieni ciemnicy, i rzekł do mnie: Proszę, kup rolę moję, która jest w Anatot, które jest w ziemi Benjaminowej, bo tobie należy prawem dziedzicznem, i bliskościąć przypada, kupże ją sobie: tedy zrozumiawszy, że to było słowo Pańskie,
9 Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
Kupiłem od Chanameela, syna stryja swego onę rolę, która jest w Anatot, i odważyłem mu pieniędzy, siedmnaście syklów srebra;
10 Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
A uczyniwszy zapis zapieczętowałem i oświadczyłem świadkami, odważywszy pieniądze na wadze.
11 Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
Potemem wziął według przykazania i prawa zapis kupna zapieczętowany i otwarty;
12 Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
I oddałem on zapis kupna Baruchowi, synowi Neryjasza, syna Maasejaszowego, przed oczyma Chanameela, stryja swego, i przed oczyma świadków, którzy się podpisali w onym zapisie kupna, przed oczyma wszystkich Żydów, którzy byli usiedli w sieni ciemnicy;
13 “Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
I rozkazałem Baruchowi przed oczyma ich, mówiąc:
14 èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
Tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Weźmij te zapisy, ten zapis tego kupna, jako zapieczętowany, tak i ten zapis otworzony, a włóż je w naczynie gliniane, aby trwały przez wiele lat;
15 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
Bo tak mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski: Jeszcze będą kupowane domy, i role, i winnice w tej ziemi.
16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
Potem modliłem się Panu, kiedym oddał on zapis kupna Baruchowi, synowi Neryjaszowemu, mówiąc:
17 “Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
Ach panujący Panie! otoś ty uczynił niebo i ziemię mocą swoją wielką i ramianiem twoim wyciągnionem, nie jestci skryta przed tobą żadna rzecz;
18 O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
Czynisz miłosierdzie nad tysiącami, i oddajesz nieprawość ojcowską do łona synów ich po nich; Bóg wielki mocny, Pan zastępów imię twoje;
19 Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
Wielki w radzie i możny w sprawie, ponieważ oczy twoje otworzone są na wszystkie drogi synów ludzkich, abyś oddał każdemu według dróg jego, i według owoców spraw jego;
20 O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
Któryś uczynił znaki i cuda na ziemi Egipskiej aż do dnia tego, i w Izraelu, i między innymi ludźmi, i uczyniłeś sobie imię, jako się to dziś okazuje.
21 O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
Boś wywiódł lud twój Izraeski z ziemi Egipskiej w znakach i w cudach, i w ręce mocnej, i w ramieniu wyciągnionem i w strachu wielkim;
22 Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
A podałeś im tę ziemię, o którąś przysiągł ojcom ich, żeś im miał dać ziemię opływającą mlekiem i miodem.
23 Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
Ale że wszedłszy do niej, a posiadłszy ją, nie usłuchali głosu twojego, i w zakonie twoim nie chodzili, wszystkiego, coś im rozkazał czynić, nie czynili; przetoż sprawiłeś to, aby nań przyszło to wszystko złe.
24 “Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
Oto strzelbę zatoczono przeciwko miastu, aby je wzięto, a miasto podane jest w ręce Chaldejczyków walczących przeciw niemu przez miecz, i głód, o mór; a tak cośkolwiek rzekł, dzieje się, to sam widzisz.
25 Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
A ty przecie mówisz do mnie, panujący Panie: Kup sobie tę rolę za pieniądze, a oświadcz to świadkami, choć już to miasto podane jest w ręcę Chaldejczyków.
26 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
I stało się słowo Pańskie do Jeremijasza, mówiąc:
27 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
Otom Ja Pan, Bóg wszelkiego ciała; izaliż przedemną może być skryta która rzecz?
28 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
Przetoż tak mówi Pan: Oto Ja daję to miasto w rękę Chaldejczyków, i w rękę Nabuchodonozora, króla Babilońskiego, i weźmie je.
29 Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
A wszedłszy Chaldejczycy, którzy walczą przeciwko temu miastu, zapalą to miasto ogniem, i spalą je i te domy, na których dachach kadzili Baalowi, a sprawowali ofiary mokre bogom cudzym, aby mię wzruszali do gniewu.
30 “Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
Bo synowie Izraelscy i synowie Judzcy od dzieciństwa swego to tylko czynią, co jest złego przed oczyma mojemi; synowie, mówię, Izraelscy tylko mię draźnili sprawą rąk swoich, mówi Pan.
31 Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
Zaiste na zapalczywość moję, i na gniew mój robi sobie to miasto ode dnia, którego je zbudowali, aż do dnia tego, tak, że mi przyjdzie oddalić od oblicza mego;
32 Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
A to dla wszelkiej złości synów Izraelskich i synów Judzkich, którą popełniali, pobudzając mię do gniewu, sami, królowie ich, książęta ich, kapłani ich i prorocy ich, jako mężowie Judzcy, tak obywatele Jeruzalemscy.
33 Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
Obracając się do mnie tyłem a nie twarzą; a gdy ich nauczam rano wstawając i nauczając, wszakże nie słuchają, aby przyjęli naukę.
34 Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
Nadto nastawiali obrzydliwości swych w tym domu, który nazwany jest od imienia mego, aby go splugawili.
35 Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
Nabudowali, mówię, wyżyn Baalowi, które są w dolinie Ben Hennon, aby przenaszali przez ognień synów swoich i córki swoje Molochowi, chociażem im tego nie rozkazał, ani to wstąpiło na serce moje, aby kiedy czynić mieli tę obrzydliwość, a do grzech u Judą przywodzić.
36 “Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
A teraz dlatego tak mówi Pan, Bóg Izraelski, o tem mieście, o którem wy powiadacie: Podane jest w rękę króla Babilońskiego przez miecz, i głód, i mór:
37 Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
Oto Ja zgromadzę ich ze wszystkich ziem, do którychem ich wygnał w popędliwości mojej i w gniewie moim, i w zapalczywości wielkiej, i przywiodę ich zaś na to miejsce, i uczynie, aby bezpiecznie mieszkali;
38 Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
I będą ludem moim, a Ja będę Bogiem ich.
39 Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
I dam im serce jedno, i drogę jednę, aby się mnie bali po wszystkie dni, tak, aby się im dobrze działo, i synom ich po nich;
40 Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
I uczynię z nimi przymierze wieczne, że się nie odwrócę od nich, abym im nie miał dobrze czynić; nadto bojaźń moję dam do serca ich, aby nie odstępowali odemnie.
41 Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
I będę się weselił z nich, dobrze im czyniąc, gdyż ich wszczepię w tej ziemi warownie, ze wszystkiego serca mego i ze wszystkiej duszy mojej.
42 “Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
Bo tak mówi Pan: Jakom przywiódł na ten lud to wszystko wielkie złe, tak przywiodę na nich to wszystko dobre, o któremem z nimi mówił.
43 Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
Tedy będą kupować rolę w tej ziemi, o której wy powiadacie: Spustoszona jest tak, że w niej niemasz ani człowieka ani bydlęcia, podana jest w rękę Chaldejczyków.
44 Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”
Rolę za pieniądze kupować będą, i zapisem warować, i pieczętować, i świadkami oświadczać w ziemi Benjaminowej, i około Jeruzalemu, i w miastach Judzkich, jako w miastach na górach tak w miastach na równinach, i w miastach na południe, gdy zaś przywrócę pojmanych ich, mówi Pan.

< Jeremiah 32 >