< Jeremiah 32 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
Telle fut la parole qui fut adressée à Jérémie de la part de Yahvé, la dixième année de Sédécias, roi de Juda, qui était la dix-huitième année de Nabuchodonosor.
2 Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
En ce temps-là, l'armée du roi de Babylone assiégeait Jérusalem. Jérémie, le prophète, était enfermé dans la cour des gardes, qui était dans la maison du roi de Juda.
3 Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
Car Sédécias, roi de Juda, l'avait fait taire, en disant: Pourquoi prophétises-tu, en disant: Yahvé dit: Voici, je livre cette ville entre les mains du roi de Babylone, et il la prendra;
4 Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
et Sédécias, roi de Juda, n'échappera pas à la main des Chaldéens, mais il sera livré entre les mains du roi de Babylone, il parlera avec lui bouche à bouche, et ses yeux verront ses yeux;
5 Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
et il emmènera Sédécias à Babylone, et il y restera jusqu'à ce que je le visite, dit Yahvé, bien que tu combattes les Chaldéens, tu ne prospéreras pas? »'"
6 Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Jérémie dit: « La parole de Yahvé m'a été adressée en ces termes:
7 Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
Voici que Hanamel, fils de Shallum, ton oncle, vient te voir et te dit: « Achète mon champ qui est à Anathoth, car le droit de rachat te revient pour l'acheter ».
8 “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
« Hanamel, fils de mon oncle, vint me voir dans la cour des gardes, selon la parole de Yahvé, et me dit: « Achète, je te prie, mon champ qui est à Anathoth, dans le pays de Benjamin, car le droit d'héritage est à toi, et le rachat est à toi. Achète-le pour toi-même. « Je sus alors que telle était la parole de Yahvé.
9 Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
J'achetai le champ d'Anathoth au fils de Hanamel, mon oncle, et je lui pesai l'argent, dix-sept sicles d'argent.
10 Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
J'ai signé l'acte, je l'ai scellé, j'ai appelé des témoins et je lui ai pesé l'argent dans les balances.
11 Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
Je pris l'acte d'achat, celui qui était scellé, contenant les conditions, et celui qui était ouvert;
12 Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
et je remis l'acte d'achat à Baruch, fils de Neriah, fils de Mahséja, en présence de Hanamel, fils de mon oncle, et en présence des témoins qui avaient signé l'acte d'achat, devant tous les Juifs qui siégeaient dans la cour des gardes.
13 “Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
J'ai donné cet ordre à Baruch en leur présence:
14 èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
L'Éternel des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Prends ces actes, cet acte d'achat scellé et cet acte ouvert, et mets-les dans un vase d'argile, pour qu'ils durent plusieurs jours.
15 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
Car Yahvé des armées, le Dieu d'Israël, dit: « On achètera encore dans ce pays des maisons, des champs et des vignes.
16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
Après avoir remis l'acte d'achat à Baruch, fils de Neriah, j'ai prié l'Éternel, en disant,
17 “Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
« Ah Seigneur Yahvé! Voici que tu as fait les cieux et la terre par ta grande puissance et par ton bras étendu. Rien n'est trop dur pour toi.
18 O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
Tu fais preuve de bonté envers des milliers de personnes, et tu reverses l'iniquité des pères dans le sein de leurs enfants après eux. Ton nom est le Dieu grand et puissant, le Yahvé des armées:
19 Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
grand par ses conseils et puissant par ses œuvres, qui a les yeux ouverts sur toutes les voies des enfants des hommes, pour rendre à chacun selon ses voies et selon le fruit de ses œuvres;
20 O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
qui a opéré des signes et des prodiges au pays d'Égypte, jusqu'à ce jour, tant en Israël que parmi les autres hommes; et tu t'es fait un nom, comme il l'est aujourd'hui;
21 O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
et tu as fait sortir ton peuple Israël du pays d'Égypte avec des signes, avec des prodiges, avec une main forte, avec un bras étendu, et avec une grande terreur;
22 Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
et tu leur as donné ce pays, que tu avais juré à leurs pères de leur donner, un pays où coulent le lait et le miel.
23 Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
Ils y sont entrés et l'ont possédé, mais ils n'ont pas obéi à ta voix et n'ont pas suivi ta loi. Ils n'ont rien fait de tout ce que tu leur avais ordonné de faire. C'est pourquoi tu as fait venir sur eux tout ce malheur.
24 “Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
« Voici, on a construit des rampes de siège contre la ville pour la prendre. La ville est livrée entre les mains des Chaldéens qui la combattent, à cause de l'épée, de la famine et de la peste. Ce que tu as dit est arrivé. Voici, tu le vois.
25 Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
Tu m'as dit, Seigneur Yahvé: « Achète le champ à prix d'argent, et appelle des témoins »; mais la ville a été livrée entre les mains des Chaldéens. »
26 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
Alors la parole de Yahvé fut adressée à Jérémie, en ces termes:
27 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
« Voici, je suis Yahvé, le Dieu de toute chair. Y a-t-il quelque chose de trop dur pour moi?
28 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
C'est pourquoi Yahvé dit: Voici, je vais livrer cette ville entre les mains des Chaldéens, entre les mains de Nabuchodonosor, roi de Babylone, et il la prendra.
29 Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
Les Chaldéens, qui combattent cette ville, viendront et mettront le feu à cette ville, et ils la brûleront avec les maisons sur les toits desquelles ils ont offert de l'encens à Baal et versé des libations à d'autres dieux, pour m'irriter.
30 “Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
« Car les enfants d'Israël et les enfants de Juda n'ont fait que ce qui était mauvais à mes yeux dès leur jeunesse; car les enfants d'Israël n'ont fait que m'irriter par l'ouvrage de leurs mains, dit l'Éternel.
31 Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
Car cette ville a été pour moi une provocation à ma colère et à ma fureur, depuis le jour où ils l'ont bâtie jusqu'à ce jour, pour que je l'enlève de devant ma face,
32 Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
à cause de tout le mal que les enfants d'Israël et les enfants de Juda ont fait pour m'irriter, eux, leurs rois, leurs princes, leurs prêtres, leurs prophètes, les hommes de Juda et les habitants de Jérusalem.
33 Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
Ils m'ont tourné le dos, et non le visage. Bien que je les aie instruits, me levant de bonne heure et les instruisant, ils n'ont pas écouté pour recevoir l'instruction.
34 Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
Mais ils ont placé leurs abominations dans la maison qui porte mon nom, pour la souiller.
35 Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
Ils ont bâti les hauts lieux de Baal, qui sont dans la vallée du fils de Hinnom, pour faire passer leurs fils et leurs filles par le feu à Moloch, ce que je ne leur ai pas commandé. Il ne m'est même pas venu à l'esprit qu'ils devaient faire cette abomination, pour faire pécher Juda. »
36 “Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
Maintenant, Yahvé, le Dieu d'Israël, dit au sujet de cette ville dont vous dites: « Elle a été livrée entre les mains du roi de Babylone par l'épée, par la famine et par la peste »:
37 Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
« Voici, je les rassemblerai de tous les pays où je les ai chassés dans ma colère, dans ma fureur et dans ma grande indignation, et je les ramènerai dans ce lieu. Je les ferai habiter en sécurité.
38 Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Alors ils seront mon peuple, et je serai leur Dieu.
39 Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
Je leur donnerai un seul cœur et une seule voie, afin qu'ils me craignent toujours, pour leur bien et celui de leurs enfants après eux.
40 Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
Je conclurai avec eux une alliance éternelle, et je ne me détournerai pas de les suivre pour leur faire du bien. Je mettrai ma crainte dans leur cœur, pour qu'ils ne s'éloignent pas de moi.
41 Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
Oui, je me réjouirai d'eux pour leur faire du bien, et je les planterai dans ce pays avec assurance, de tout mon cœur et de toute mon âme. »
42 “Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
Car Yahvé dit: « De même que j'ai fait venir sur ce peuple tout ce grand malheur, de même je ferai venir sur lui tout le bien que je lui ai promis.
43 Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
On achètera des champs dans ce pays dont vous dites: « Il est désert, sans homme ni bête. Il est livré entre les mains des Chaldéens ».
44 Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”
Onachètera des champs à prix d'argent, on signera les actes, on les scellera, on appellera des témoins, dans le pays de Benjamin, dans les environs de Jérusalem, dans les villes de Juda, dans les villes de la montagne, dans les villes de la plaine, dans les villes du Midi, car je ferai revenir leur captivité, dit Yahvé.

< Jeremiah 32 >