< Jeremiah 32 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
Sana, joka tuli Jeremialle Herralta Sidkian, Juudan kuninkaan, kymmenentenä vuotena, se on Nebukadressarin kahdeksantenatoista vuotena.
2 Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
Silloin Baabelin kuninkaan sotajoukko piiritti Jerusalemia, ja profeetta Jeremia oli suljettuna vankilan pihaan, joka on Juudan kuninkaan linnassa.
3 Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
Sinne oli Sidkia, Juudan kuningas, hänet sulkenut sanoen: "Miksi sinä ennustat näin: Näin sanoo Herra: Katso, minä annan tämän kaupungin Baabelin kuninkaan käsiin, ja hän valloittaa sen?
4 Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
Ja Sidkia, Juudan kuningas, ei pääse kaldealaisten käsistä, vaan hänet annetaan Baabelin kuninkaan käsiin, ja hänen täytyy puhua hänen kanssaan suusta suuhun ja nähdä hänet silmästä silmään.
5 Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
Ja hän kuljettaa Sidkian Baabeliin, ja sinne hän jää, kunnes minä katson hänen puoleensa, sanoo Herra. Kun te taistelette kaldealaisia vastaan, ei teillä ole menestystä."
6 Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Ja Jeremia sanoi: "Minulle tuli tämä Herran sana:
7 Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
Katso, Hanamel, setäsi Sallumin poika, tulee sinun luoksesi ja sanoo: 'Osta minun peltoni, joka on Anatotissa, sillä sinulla on lunastusoikeus, niin että saat ostaa sen'."
8 “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
Ja Hanamel, setäni poika, tuli Herran sanan mukaan minun luokseni vankilan pihaan ja sanoi minulle: "Osta minun peltoni, joka on Anatotissa, Benjaminin maassa, sillä sinulla on perintöoikeus ja sinulla on lunastusoikeus: osta se itsellesi". Silloin minä ymmärsin, että se oli Herran sana.
9 Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
Ja minä ostin Hanamelilta, setäni pojalta, pellon, joka on Anatotissa, ja punnitsin hänelle rahat, seitsemäntoista sekeliä hopeata,
10 Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
kirjoitin kauppakirjan ja sinetöin sen, otin todistajat ja punnitsin rahat vaa'alla.
11 Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
Sitten minä otin sinetöidyn kauppakirjan, sopimuksen ja määräykset sekä avoimen kirjan,
12 Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
ja annoin kauppakirjan Baarukille, Neerian, Mahsejan pojan, pojalle, serkkuni Hanamelin nähden ja todistajain nähden, jotka olivat kirjoittaneet kauppakirjan alle, ja kaikkien juutalaisten nähden, jotka istuivat vankilan pihassa,
13 “Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
ja minä käskin Baarukia heidän nähtensä sanoen:
14 èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
"Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Ota nämä kirjat, tämä kauppakirja, sekä sinetöity että tämä avoin kirja, ja pane ne saviastiaan, että ne säilyisivät kauan aikaa.
15 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
Sillä näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Vielä kerran ostetaan tässä maassa taloja ja peltoja ja viinitarhoja."
16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
Ja annettuani kauppakirjan Baarukille, Neerian pojalle, minä rukoilin Herraa sanoen:
17 “Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
"Oi Herra, Herra! Katso, sinä olet tehnyt taivaan ja maan suurella voimallasi ja ojennetulla käsivarrellasi: ei mikään ole sinulle mahdotonta;
18 O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
sinä, joka teet laupeuden tuhansille, mutta kostat isäin pahat teot heidän jälkeensä heidän lastensa helmaan; sinä suuri, voimallinen Jumala, jonka nimi on Herra Sebaot,
19 Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
suuri neuvossa ja väkevä teossa, sinä, jonka silmät ovat avoimet tarkkaamaan kaikkia ihmislasten teitä, antaaksesi itsekullekin hänen vaelluksensa ja hänen töittensä hedelmän mukaan;
20 O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
sinä, joka teit tunnustekoja ja ihmeitä Egyptin maassa ja olet tehnyt niitä hamaan tähän päivään asti sekä Israelissa että muitten ihmisten seassa, ja joka olet tehnyt itsellesi nimen, senkaltaisen kuin se tänäkin päivänä on.
21 O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
Sinä veit kansasi Israelin pois Egyptin maasta tunnusteoilla ja ihmeillä, väkevällä kädellä ja ojennetulla käsivarrella, suurella peljätyksellä,
22 Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
ja annoit heille tämän maan, jonka sinä heidän isillensä vannotulla valalla olit luvannut antaa heille, maan, joka vuotaa maitoa ja mettä.
23 Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
Mutta kun he olivat tulleet ja ottaneet sen omaksensa, eivät he kuulleet sinun ääntäsi eivätkä vaeltaneet sinun lakisi mukaan; he eivät tehneet mitään siitä, mitä sinä olit käskenyt heidän tehdä. Silloin sinä annoit kaiken tämän onnettomuuden kohdata heitä.
24 “Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
Katso, piiritysvallit ovat edenneet aivan kaupunkiin asti, niin että se valloitetaan, ja kaupunki joutuu miekan, nälän ja ruton pakosta kaldealaisten valtaan, jotka sotivat sitä vastaan. Mitä sinä olet puhunut, on tapahtunut, ja katso, sinä näet sen.
25 Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
Mutta kuitenkin sinä, Herra, Herra, sanoit minulle: 'Osta rahalla itsellesi pelto ja ota todistajat', vaikka kaupunki joutuu kaldealaisten käsiin."
26 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
Ja Jeremialle tuli tämä Herran sana:
27 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
"Katso, minä olen Herra, kaiken lihan Jumala; onko minulle mitään mahdotonta?
28 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
Sentähden, näin sanoo Herra: Katso, minä annan tämän kaupungin kaldealaisten käsiin ja Nebukadressarin, Baabelin kuninkaan, käsiin, ja hän valloittaa sen.
29 Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
Ja kaldealaiset, jotka sotivat tätä kaupunkia vastaan, tulevat ja sytyttävät tämän kaupungin tuleen ja polttavat sen niine taloineen, joiden katoilla on poltettu uhreja Baalille ja vuodatettu juomauhreja vieraille jumalille, minulle mielikarvaudeksi.
30 “Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
Sillä Israelin ja Juudan miehet ovat hamasta nuoruudestaan tehneet vain sitä, mikä on pahaa minun silmissäni, sillä israelilaiset ovat tuottaneet minulle ainoastaan mielikarvautta kättensä teoilla, sanoo Herra.
31 Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
Sillä tämä kaupunki on ollut minulle vihaksi ja kiivastukseksi hamasta siitä päivästä, jona he sen rakensivat, aina tähän päivään asti; ja niin minä heitän sen pois kasvojeni edestä
32 Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
kaiken sen pahan tähden, minkä israelilaiset ja Juudan miehet ovat tehneet minulle mielikarvaudeksi-he, heidän kuninkaansa, ruhtinaansa, pappinsa ja profeettansa sekä Juudan miehet ja Jerusalemin asukkaat.
33 Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
He ovat kääntäneet minulle selkänsä eivätkä kasvojansa; ja vaikka minä olen opettanut heitä varhaisesta alkaen, he eivät ole kuulleet eivätkä ottaneet varteen kuritusta.
34 Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
He ovat asettaneet iljetyksensä temppeliin, joka on otettu minun nimiini, ja saastuttaneet sen.
35 Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
Ja he ovat rakentaneet Baalille uhrikukkulat, jotka ovat Ben-Hinnomin laaksossa, polttaakseen poikiansa ja tyttäriänsä uhrina Molokille, mitä minä en ole käskenyt ja mikä ei ole minun mieleeni tullut. Tällaisia kauhistuksia he tekivät ja saivat Juudan syntiä tekemään.
36 “Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
Mutta nyt sanoo Herra, Israelin Jumala, näin tästä kaupungista, jonka te sanotte joutuvan Baabelin kuninkaan käsiin miekan, nälän ja ruton pakosta:
37 Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
Katso, minä kokoan heidät jälleen kaikista maista, joihin minä heidät vihassani, kiivastuksessani ja suuressa suuttumuksessani karkoitan, ja palautan heidät tähän paikkaan ja annan heidän asua turvassa.
38 Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Silloin he ovat minun kansani, ja minä olen heidän Jumalansa.
39 Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
Ja minä annan heille yhden sydämen ja yhden tien, niin että he pelkäävät minua kaiken elinaikansa, ja niin heidän käy hyvin ja heidän lastensa heidän jälkeensä.
40 Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
Ja minä teen heidän kanssansa iankaikkisen liiton, niin etten käänny heistä pois, vaan teen heille hyvää; ja minä annan pelkoni heidän sydämiinsä, niin etteivät he minusta luovu.
41 Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
Ja minä iloitsen heistä, siitä että teen heille hyvää; minä istutan heidät tähän maahan uskollisesti, kaikesta sydämestäni ja kaikesta sielustani.
42 “Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
Sillä näin sanoo Herra: Niinkuin minä olen tuottanut tälle kansalle kaiken tämän suuren onnettomuuden, niin minä myös tuotan heille kaiken sen hyvän, minkä minä heille lupaan.
43 Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
Vielä ostetaan peltoja tässä maassa, josta te sanotte: 'Se on oleva autio, vailla ihmisiä ja eläimiä, kaldealaisten käsiin annettu'.
44 Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”
Peltoja ostetaan rahalla, kauppakirjoja kirjoitetaan ja sinetöidään ja todistajia otetaan Benjaminin maassa, Jerusalemin ympäristössä ja Juudan kaupungeissa, Vuoriston, Alankomaan ja Etelämaan kaupungeissa, sillä minä käännän heidän kohtalonsa, sanoo Herra."

< Jeremiah 32 >