< Jeremiah 32 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
The word that was maad of the Lord to Jeremye, in the tenthe yeer of Sedechie, kyng of Juda; thilke is the eiytenthe yeer of Nabugodonosor.
2 Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
Thanne the oost of the kyng of Babiloyne bisegide Jerusalem; and Jeremye, the profete, was closid in the porche of the prisoun, that was in the hous of the kyng of Juda.
3 Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
For whi Sedechie, the kyng of Juda, hadde closid hym, and seide, Whi profesiest thou, seiynge, The Lord seith these thingis, Lo! Y schal yyue this citee in the hond of the kyng of Babyloyne, and he schal take it; and Sedechie,
4 Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
the kyng of Juda, schal not ascape fro the hond of Caldeis, but he schal be bitake in to the hond of the kyng of Babiloyne; and his mouth schal speke with the mouth of hym, and hise iyen schulen se the iyen of hym;
5 Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
and he schal lede Sedechie in to Babiloyne, and he schal be there, til Y visyte hym, seith the Lord; forsothe if ye fiyten ayens Caldeis, ye schulen haue no thing in prosperite?
6 Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
And Jeremye seide, The word of the Lord was maad to me, and seide, Lo!
7 Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
Ananeel, the sone of Sellum, the sone of thi fadris brothir, schal come to thee, and seie, Bi thou to thee my feeld, which is in Anathot; for it bifallith to thee by niy kynrede, that thou bie it.
8 “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
And Ananeel, the sone of my fadris brothir, cam to me, bi the word of the Lord, to the porche of the prisoun, and seide to me, Welde thou my feeld, which is in Anathot, in the lond of Beniamyn; for whi the erytage bifallith to thee, and thou art the next of blood, that thou welde it. Forsothe Y vndirstood, that it was the word of the Lord.
9 Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
And Y bouyte the feeld, which is in Anathot, of Ananeel, the sone of my fadris brothir. And Y paiede to hym siluer, seuene stateris, and ten platis of siluer;
10 Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
and Y wroot in a book, and Y seelide, and Y yaf witnessis. And Y weiede siluer in a balaunce;
11 Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
and Y took the book aseelid of possessioun, and axingis and answerys of the seller and bier, and couenauntis, and seelis withoutforth.
12 Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
And Y yaf the book of possessioun to Baruc, the sone of Neri, sone of Maasie, bifore the iyen of Ananeel, the sone of my fadris brother, and bifore the iyen of witnessis that weren writun in the book of biyng, bifore the iyen of alle Jewis, that saten in the porche of the prisoun.
13 “Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
And Y comaundide to Baruc bifore hem,
14 èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
and Y seide, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Take thou these bookis, this seelid book of biyng, and this book which is opyn, and putte thou tho in an erthen vessel, that tho moun dwelle bi many daies.
15 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
For whi the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Yit housis, and feeldis, and vynes schulen be weldid in this lond.
16 “Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
And Y preiede to the Lord, aftir that Y bitook the book of possessioun to Baruc, the sone of Nery; and Y seide, Alas!
17 “Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
alas! alas! Lord God, Lord, thou madist heuene and erthe in thi greet strengthe, and in thin arm stretchid forth; ech word schal not be hard to thee;
18 O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
which doist merci in thousyndis, and yeldist the wickidnesse of fadris in to the bosum of her sones aftir hem. Thou strongeste, greet, myyti, Lord of oostis is name to thee;
19 Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
greet in councel, and vncomprehensible in thouyt, whose iyen ben open on alle the weies of the sones of Adam, that thou yelde to ech aftir hise weies, and aftir the fruyt of hise fyndyngis;
20 O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
which settidist signes and greet woundris in the lond of Egipt, `til to this dai, bothe in Israel and in men; and madist to thee a name, as this dai is.
21 O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
And thou leddist thi puple Israel out of the lond of Egipt, in signes and in greet woundris, and in a strong hond, and in an arm holdun forth, and in greet dreed; and thou yauest to hem this lond,
22 Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
which thou sworist to the fadris of hem, that thou woldist yyue to hem, a lond flowynge with milk and hony.
23 Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
And thei entriden, and hadden it in possessioun; and thei obeieden not to thi vois, and thei yeden not in thi lawe; alle thingis whiche thou comaundidist to hem to do, thei diden not; and alle these yuels bifellen to hem.
24 “Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
Lo! strengthis ben bildid ayens the citee, that it be takun, and the citee is youun in to the hondis of Caldeis, and in to the hondis of the kyng of Babiloyne, that fiyten ayens it, of the face of swerd, and of hungur, and of pestilence; and what euer thingis thou spakest, bifellen, as thou thi silf seest.
25 Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
And Lord God, thou seist to me, Bie thou a feeld for siluer, and yyue thou witnessis, whanne the citee is youun in the hondis of Caldeis.
26 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
And the word of the Lord was maad to Jeremye, and seide, Lo!
27 “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
Y am the Lord God of `al fleisch. Whether ony word schal be hard to me?
28 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
Therfor the Lord seith these thingis, Lo! Y schal bitake this citee in to the hondis of Caldeis, and in to the hond of the kyng of Babiloyne, and he schal take it.
29 Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
And Caldeis schulen come, and fiyte ayens this citee, and thei schulen brenne it with fier, and thei schulen brenne it, and housis, in whose rooues thei sacrifieden to Baal, and offriden moist sacrifices to alien goddis, to terre me to wraththe.
30 “Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
For whi the sones of Israel and the sones of Juda diden yuel contynueli, fro her yonge waxynge age, bifore myn iyen, the sones of Israel, whiche `til to now wraththen me bi the werk of her hondis, seith the Lord.
31 Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
For whi this citee is maad to me in my strong veniaunce and indignacioun, fro the day in which thei bildiden it, `til to this dai, in which it schal be takun awei fro my siyt;
32 Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
for the malice of the sones of Israel, and of the sones of Juda, which thei diden, terrynge me to wrathfulnesse, thei, and the kyngis of hem, the princes of hem, and the prestis, and profetis of hem, the men of Juda, and the dwelleris of Jerusalem.
33 Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
And thei turneden to me the backis, and not the faces, whanne Y tauyte, and enformede hem erli; and thei nolden here, that thei schulden take techyng.
34 Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
And thei settiden her idols in the hous, in which my name is clepid to help, that thei schulden defoule it.
35 Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
And thei bildiden hiy thingis to Baal, that ben in the valei of the sones of Ennon, that thei schulden halewe her sones and her douytris to Moloc, which thing Y comaundide not to hem, nether it stiede in to myn herte, that thei schulden do this abhomynacioun, and brynge Juda in to synne.
36 “Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
And now for these thingis, the Lord God of Israel seith these thingis to this citee, of whiche ye seien, that it schal be bitakun in to the hondis of the kyng of Babiloyne, in swerd, and in hungur, and in pestilence, Lo!
37 Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
Y schal gadere hem fro alle londis, to whiche Y castide hem out in my strong veniaunce, and in my wraththe, and in greet indignacioun; and Y schal brynge hem ayen to this place, and Y schal make hem to dwelle tristili.
38 Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
And thei schulen be in to a puple to me, and Y schal be in to God to hem.
39 Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
And Y schal yyue to hem oon herte and o soule, that thei drede me in alle daies, and that it be wel to hem, and to her sones aftir hem.
40 Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
And Y schal smyte to hem a couenaunt euerlastynge, and Y schal not ceese to do wel to hem, and Y schal yyue my drede in the herte of hem, that thei go not awey fro me.
41 Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
And Y schal be glad on hem, whanne Y schal do wel to hem; and Y schal plaunte hem in this lond in treuthe, in al myn herte, and in al my soule.
42 “Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
For the Lord seith these thingis, As Y brouyte on this puple al this greet yuel, so Y schal brynge on hem al the good, which Y schal speke to hem.
43 Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
And feeldis schulen be weldid in this lond, of which ye seien, that it is desert, for no man and beeste is left; and it is youun in to the hondis of Caldeis.
44 Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”
Feeldis schulen be bouyt for money, and schulen be writun in a book, and a seel schal be preentid; and witnessis schulen be youun, in the lond of Beniamyn, and in the cumpas of Jerusalem, and in the citees of Juda, and in the citees in hilli places, and in the citees in feeldi places, and in the citees that ben at the south; for Y schal turne the caitiftee of hem, seith the Lord.

< Jeremiah 32 >