< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
“Saa bere no,” Awurade na ose, “Mɛyɛ Israel mmusuakuw no nyinaa Nyankopɔn, na wɔbɛyɛ me nkurɔfo.”
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Nea Awurade se ni: “Nnipa a wotumi gyinaa wɔ afoa ano no benya adom wɔ nweatam so; mede ahomegye bɛbrɛ Israel.”
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Awurade daa ne ho adi kyerɛɛ yɛn kan no na ɔkae se, “Mede ɔdɔ a ɛnsa da adɔ mo mede adɔe atwe mo.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Mede mo besi hɔ bio na wɔbɛsan de wo, Ɔbabun Israel, asi hɔ. Wobɛfa wʼakasae bio na woafi adi ne anigyefo akɔsaw.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Bio, mobɛyɛ bobe nturo wɔ Samaria nkoko so; akuafo no bedua na wɔadi so aba.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Da bi bɛba a, awɛmfo bɛteɛ mu wɔ Efraim nkoko so se, ‘Mommra, momma yɛnforo nkɔ Sion, nkɔ Awurade yɛn Nyankopɔn nkyɛn.’”
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Nea Awurade se ni: “Momfa ahosɛpɛw nto nnwom mma Yakob; Monteɛ mu mma amanaman mu kannifo. Momma wɔnte mo ayeyi na monka se, ‘Awurade, gye wo nkurɔfo, Israel nkae no.’
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Hwɛ, mede wɔn befi atifi fam asase so aba na maboa wɔn ano afi nsase ano. Wɔn mu bi bɛyɛ anifuraefo, mpakye, apemfo ne mmea a wɔwɔ awoko mu; dɔm kɛse bɛsan aba.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Wɔde osu na ɛbɛba; wɔbɛbɔ mpae bere a mede wɔn resan aba no. Mede wɔn bɛfa nsuwa ho; ɔkwan tamaa a wɔrenhintiw wɔ so, efisɛ mɛyɛ Israel agya, na Efraim yɛ me babarima piesie.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
“Muntie Awurade asɛm, mo amanaman; mommɔ no dawuru wɔ mpoano nsase a ɛwɔ akyirikyiri so se, ‘Nea ɔbɔɔ Israel petee no bɛboaboa wɔn ano na wahwɛ ne nguankuw so sɛ oguanhwɛfo.’
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Na Awurade begyina mu ama Yakob na wagye wɔn afi wɔn a wɔwɔ ahoɔden sen wɔn no nsam.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Wɔbɛba na wɔde ahurusi ateɛ mu wɔ Sion sorɔnsorɔmmea; wɔbɛsɛpɛw wɔn ho wɔ akyɛde bebrebe a efi Awurade hɔ mu, atoko, nsa foforo ne ngo, nguantenmma ne anantwi. Wɔbɛyɛ sɛ turo a wɔagugu so nsu yiye, na wɔrenni awerɛhow bio.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Afei mmabaa bɛsaw na wɔn ani agye, mmerante ne nkwakoraa nso ka ho. Mɛma wɔn awerɛhow adan anigye; mɛma wɔn ahotɔ ne ahosɛpɛw de asi awerɛhow anan mu.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Mɛma asɔfo no nea ehia wɔn ama abu so, na mama mʼakyɛde bebrebe amee me nkurɔfo,” Awurade, na ose.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Sɛɛ na Awurade se: “Wɔte nne bi wɔ Rama, awerɛhow ne agyaadwotwa bebree, Rahel resu ne mma na ɔmpɛ sɛ wɔkyekye ne werɛ, efisɛ ne mma nni hɔ bio.”
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Sɛɛ na Awurade se: “Hyɛ wo ho so na woansu, mia wʼani na woante nusu, efisɛ wobetua wʼadwumayɛ so ka,” Awurade na ose. “Wɔbɛsan afi atamfo no asase so aba.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Enti anidaso wɔ hɔ ma wo daakye.” Awurade na ose. Wo mma bɛsan aba wɔn ankasa asase so.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
“Ampa ara mate sɛ Efraim resu se, ‘Woteɛteɛɛ me so sɛ nantwi ba a nʼani yɛ den, na manya ahohyɛso. Gye me bio, na mɛsan aba, efisɛ wo ne Awurade, me Nyankopɔn.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Meman akyi no, minyaa adwensakra; na akyiri a minyaa ntease no, mebɔɔ me koko so. Mʼanim guu ase na mefɛree, efisɛ me mmabun mu animguase da so so me.’
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Efraim nyɛ me babarima dɔfo, ɔba a ɔsɔ mʼani ana? Ɛwɔ mu, metaa kasa tia no de, nanso meda so kae no. Enti me koma pere hwehwɛ no; mewɔ ayamhyehye ma no,” sɛɛ na Awurade se.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
“Momfa agyiraehyɛde nsisi akwan ho; munsisi akwankyerɛ afadum. Monhyɛ ɔtempɔn no nsow, ɔkwan a monam so ba. San wʼakyi, Ɔbabun Israel, san bra wo nkurow so.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Wubekyinkyin akosi da bɛn, Ɔbabea Israel sesafo? Awurade bɛyɛ ade foforo wɔ asase so, ɔbea bɛbɔ ɔbarima ho ban.”
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Sɛɛ na Asafo Awurade, Israel Nyankopɔn no se: “Sɛ mesan de wɔn fi nnommum mu ba a, nnipa a wɔwɔ Yuda asase ne nkurow so bɛsan aka saa nsɛm yi se, ‘Awurade nhyira wo, wo yiyeyɛ kuropɔn ne bepɔw kronkron.’
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Nnipa bɛbɔ mu atena ase wɔ Yuda ne ne nkurow nyinaa so, akuafo ne wɔn a wɔde wɔn nguankuw nenam.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Mɛma nea wabrɛ no anya ahoɔden foforo, na nea watɔ piti no nso mɛma no amee.”
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Minyanee, na mehwɛɛ me ho hyiae. Medaa hatee.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
“Nna bi reba,” Awurade na ose, “A mede nnipa mma ne mmoa mma bedua Israel ne Yuda fi.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Sɛnea mehwɛ ma wotutui, wodwiriwii, wobubui, wɔsɛee na wɔde amanehunu bae no, saa ara na mɛhwɛ ama wɔasi na wɔadua,” sɛnea Awurade se ni.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
Saa nna no mu, nnipa renka bio se, “‘Agyanom adi bobe nwennaa, na mma se afem.’
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Mmom, obiara bewu wɔ ɔno ara bɔne ho; nea obedi bobe nwennaa no ɔno na ne se bɛfem.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
“Bere no reba,” Awurade na ose, “a me ne Israelfi ne Yudafi bɛyɛ apam foforo.
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
Ɛrenyɛ sɛ apam a me ne wɔn agyanom yɛe no bere a misoo wɔn nsa, dii wɔn anim fii Misraim, esiane sɛ wobuu mʼapam so, wɔ bere a na meyɛ okunu ma wɔn no,” Awurade na ose.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
“Eyi ne apam a me ne Israelfi bɛyɛ saa bere no akyi,” Awurade na ose. “Mede me mmara bɛhyɛ wɔn adwene mu, na makyerɛw wɔ wɔn koma so. Mɛyɛ wɔn Nyankopɔn, na wɔbɛyɛ me nkurɔfo.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Na obiara renkyerɛkyerɛ ne yɔnko bio, anaa ne nua se, ‘Hu Awurade,’ Efisɛ, wɔn nyinaa behu me, efi wɔn mu akumaa so, kosi ɔkɛse so,” Sɛnea Awurade se ni. “Na mede wɔn amumɔyɛ bɛkyɛ wɔn, na merenkae wɔn bɔne bio.”
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Sɛɛ na Awurade se, nea ɔma owia hyerɛn adekyee, na ɔhyɛ ɔsram ne nsoromma sɛ wɔnhyerɛn anadwo; nea ɔkanyan ɛpo ma nʼasorɔkye bobɔ mu, Asafo Awurade ne ne din.
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
“Saa ahyɛde yi twa mu mʼani so a,” Awurade na ose, “ɛno ansa na Israel begyae ɔmanyɛ wɔ mʼanim.”
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Sɛɛ na Awurade se: “Sɛ wobetumi asusuw wim ntrɛwmu na wɔatumi ahwehwɛ asase ase fapem mu a ɛno de, mɛpo Israel asefo nyinaa, esiane nea wɔayɛ nyinaa nti,” Awurade na ose.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
“Nna no reba,” Awurade na ose, “a wɔbɛkyekye kuropɔn yi bio ama me, fi Hananel abantenten kosi Twɔtwɔw so Pon.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Wɔbɛtwe susuhama no mu, afi hɔ de akosi Gareb koko so, na akɔntɔn akɔ Goa.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Obon a wɔtow afunu ne nsõ gu mu no nyinaa ne asase a ɛkɔ Kidron bon mu wɔ apuei fam, kosi apɔnkɔ pon no twɔtwɔw so bɛyɛ kronkron ama Awurade. Wɔrentutu na wɔrensɛe kuropɔn no da.”

< Jeremiah 31 >