< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
På den tiden, säger HERREN, skall jag vara alla Israels släkters Gud, och de skola vara mitt folk.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Så säger HERREN: Det folk som undslipper svärdet finner nåd i öknen; Israel får draga åstad dit där det får ro.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Fjärran ifrån uppenbarade sig HERREN för mig: »Ja, med evig kärlek har jag älskat dig; därför låter jag min nåd förbliva över dig.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Ännu en gång skall jag upprätta dig, så att du varder upprättad, du jungfru Israel; ännu en gång skall du få utrusta dig med puka och draga ut i dans bland dem som göra sig glada.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Ännu en gång skall du få plantera vingårdar på Samariens berg, och planteringsmännen skola själva skörda frukten.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Ty en dag kommer, då vaktare skola ropa på Efraims berg: 'Upp, låt oss draga till Sion, upp till HERREN, vår Gud.'»
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Ty så säger HERREN: Jublen i glädje över Jakob, höjen fröjderop över honom som är huvudet bland folken, Låten lovsång ljuda och sägen: HERRE, giv frälsning åt ditt folk, åt kvarlevan av Israel.»
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Ja, jag skall föra dem från nordlandet och församla dem från jordens yttersta ända -- bland dem både blinda och halta, både havande kvinnor och barnaföderskor; i en stor skara skola de komma hit tillbaka.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Under gråt skola de komma, men jag skall leda dem, där de gå bedjande fram; Jag skall föra dem till vattenbäckar, på en jämn väg, där de ej skola stappla. Ty jag har blivit en fader för Israel, och Efraim är min förstfödde son.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Hören HERRENS ord, I hednafolk, och förkunnen det i havsländerna i fjärran; sägen: Han som förskingrade Israel skall ock församla det och bevara det, såsom en herde sin hjord.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Ty HERREN skall förlossa Jakob och lösköpa honom ur den övermäktiges hand.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Och de skola komma och jubla på Sions höjd och strömma dit där HERRENS goda är, dit där man får säd, vin och olja och unga hjordar av får och fä; deras själ skall vara lik en vattenrik trädgård, och de skola icke vidare försmäkta.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Då skola jungfrurna förlusta sig med dans; unga och gamla skola glädja sig tillsammans. Jag skall förvandla deras sorg i fröjd, trösta dem och glädja dem efter deras bedrövelse.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Och prästerna skall jag vederkvicka med feta rätter; och mitt folk skall bliva mättat av mitt goda, säger HERREN.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Så säger HERREN: Ett rop höres i Rama, klagan och bitter gråt; det är Rakel som begråter sina barn, hon vill icke låta trösta sig i sorgen över att hennes barn icke mer äro till.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Men så säger HERREN: Hör upp med din högljudda gråt, och låt dina ögon icke mer fälla tårar; ty ditt verk skall få sin lön, säger HERREN, och de skola vända tillbaka från sina fienders land.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Ja, det finnes ett hopp för din framtid, säger HERREN; dina barn skola vända tillbaka till sitt land.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Jag har nogsamt hört huru Efraim klagar: »Du har tuktat mig, ja, jag har blivit tuktad såsom en otämd kalv; tag mig nu åter, så att jag får vända åter; du är ju HERREN, min Gud.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Ty sedan jag har vänt mitt sinne, ångrar jag mig, och sedan jag har kommit till besinning, slår jag mig på länden; jag både blyges och skämmes, då jag nu bär min ungdoms smälek.»
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Är då Efraim for mig en så dyrbar son, är han mitt älsklingsbarn, eftersom jag alltjämt tänker på honom, huru ofta jag än har måst hota honom? Ja, så mycket ömkar sig mitt hjärta över honom; jag måste förbarma mig över honom, säger HERREN.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Sätt upp vägmärken för dig, res åt dig vägvisare; giv akt på vägen, på stigen där du vandrade. Och vänd så tillbaka, du jungfru Israel, vänd tillbaka till dessa dina städer.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Huru länge skall du göra bukter hit och dit, du avfälliga dotter? Se, HERREN vill skapa något nytt i landet: det bliver nu kvinnan som tager mannen i sitt beskärm.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: I Juda land med dess städer skall man ännu en gång, när jag åter har upprättat det, få säga det ordet: »HERREN välsigne dig, du rättfärdighetens boning, du heliga berg.»
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Och Juda folk med alla sina städer skall samlat bo däri, åkermän jämte vandrande herdar.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Ty jag skall vederkvicka trötta själar, och alla försmäktande själar skall jag mätta.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
(Härvid uppvaknade jag och såg mig om, och min sömn hade varit ljuvlig.)
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag skall beså Israels land och Juda land med säd av människor och med säd av djur.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Och likasom jag har vakat över dem till att upprycka, nedbryta, fördärva, förgöra och plåga, så vill jag nu vaka över dem till att uppbygga och plantera, säger HERREN.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
På den tiden skall man icke mer säga: »Fäderna hava ätit sura druvor, och barnens tänder bliva ömma därav.»
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Nej, var och en skall dö genom sin egen missgärning; var man som äter sura druvor, hans tänder skola bliva ömma därav.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag skall sluta ett nytt förbund med Israels hus och med Juda hus;
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
icke ett sådant förbund som det jag slöt med deras fäder på den dag då jag tog dem vid handen till att föra dem ut ur Egyptens land det förbund med mig, som de bröto, fastän jag var deras rätte herre, säger HERREN.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Nej, detta är det förbund som jag skall sluta med Israels hus i kommande dagar, säger HERREN: Jag skall lägga min lag i deras bröst och i deras hjärtan skall jag skriva den, och jag skall vara deras Gud, och de skola vara mitt folk.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Då skola de icke mer behöva undervisa varandra, icke den ene brodern den andre, och säga: »Lär känna HERREN»; ty de skola alla känna mig, från den minste bland dem till den störste, säger HERREN. Ty jag skall förlåta deras missgärning, och deras synd skall jag icke mer komma ihåg.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Så säger HERREN, han som har satt solen till att lysa om dagen och månen och stjärnorna till att lysa om natten, i ordnad gång, han som rör upp havet, så att dess böljor brusa, han vilkens namn är HERREN Sebaot:
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Först när denna ordning icke mer består inför mig, säger HERREN, först då skall Israels släkt upphöra att inför mig alltjämt vara ett folk.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Ja, så säger HERREN: Först när himmelen varder uppmätt därovan och jordens grundvalar utrannsakade därnere, först då skall jag förkasta all Israels släkt, till straff för allt vad de hava gjort, säger HERREN.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Se, dagar skola komma, säger HERREN, då staden åter skall varda uppbyggd till HERRENS ära, från Hananeltornet intill Hörnporten.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Och mätsnöret skall vidare dragas rätt fram mot Garebshöjden och skall sedan vändas mot Goa.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Och hela lik- och askdalen och alla fälten intill bäcken Kidron och intill hörnet vid Hästporten österut skola vara helgade åt HERREN. Aldrig mer skall där tima någon omstörtning eller någon förstöring.

< Jeremiah 31 >