< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
“Ngalesosikhathi ngizakuba nguNkulunkulu wezizwana zonke zako-Israyeli, bona bazakuba ngabantu bami,” kutsho uThixo.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
UThixo uthi: “Abantu abasilayo enkembeni bazathola umusa enkangala; ngizakuzanika u-Israyeli ukuphumula.”
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
UThixo wabonakala kithi kudala esithi: “Ngikuthandile ngothando olungapheliyo; ngikuhole ngesisa esikhulu.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Ngizakwakha njalo uzakwakhiwa kutsha futhi, wena Israyeli Ntombi emsulwa. Uzathatha amagedla akho futhi uphume uyegida labathokozayo.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Uzalima izivini zakho futhi emaqaqeni aseSamariya; abalimi bazazilima badle izithelo zazo.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Kuzakuba losuku lapho abalindi bezamemeza phezu kwamaqaqa ako-Efrayimi bathi, ‘Wozani, kasiyeni eZiyoni, kuThixo uNkulunkulu wethu.’”
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
UThixo uthi: “Mhlabeleleni uJakhobe ngokuthokoza; nqongolozelani izizwe ezidumileyo. Yenzani ukudumisa kwenu kuzwakale, lisithi, ‘Awu Thixo, bahlenge abantu bakho, insalela ka-Israyeli.’
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Khangelani, ngizababuyisa bevela elizweni lasenyakatho, ngibaqoqe emikhawulweni yomhlaba. Phakathi kwabo kuzakuba leziphofu labaqhulayo; abesifazane abazithweleyo labahelelwayo; ixuku elikhulu lizabuya.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Bazabuya bekhala; bazakhuleka lapho ngibabuyisa. Ngizabaholela ezihotsheni zamanzi endleleni eyendlalekileyo lapho abangayikukhubeka khona, ngoba nginguyise ka-Israyeli, njalo u-Efrayimi yindodana yami elizibulo.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Zwanini ilizwi likaThixo, lina zizwe; limemezeleni emazweni angaselwandle khatshana lithi: ‘Yena owahlakaza u-Israyeli uzamqoqa njalo uzakwelusa umhlambi wakhe njengomelusi.’
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Ngoba uThixo uzamhlenga uJakhobe, abakhulule ezandleni zalabo abalamandla kulabo.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Bazakuza banqongoloze ngentokozo ezingqongeni zeZiyoni; bazathokoza ngokuphana kukaThixo, ngamabele, langewayini elitsha kanye lamafutha e-oliva, ngamazinyane ezimvu langamathole enkomo. Bazakuba njengesivande esithelelwa kuhle, njalo kabasayikuba losizi futhi.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Izintombi zizagida njalo futhi zithabe, enzenjalo amajaha labadala. Ngizaguqula ukukhala kwabo kube yikuthaba; ngizabapha induduzo lentokozo esikhundleni sosizi.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Ngizasuthisa abaphristi ngokunengi, labantu bami bazasutha ngokuphana kwami,” kutsho uThixo.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Nanku okutshiwo nguThixo: “Ilizwi lizwakala eRama, lesililo lokukhala okukhulu, uRasheli ukhalela abantwabakhe njalo esala ukududuzwa, ngoba kabasekho.”
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Nanku akutshoyo uThixo: “Bamba ilizwi lakho ungakhali, lamehlo akho angehlisi inyembezi ngoba umsebenzi wakho uzathola umvuzo,” kutsho uThixo. “Bazabuya bevela elizweni lesitha.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Ngakho kulethemba ensukwini zakho ezizayo,” kutsho uThixo. “Abantwabakho bazabuyela elizweni labo.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Ngikuzwile impela ukukhala kuka-Efrayimi esithi: ‘Wangitshaya njengethole elingathambanga, njalo sengajeziseka. Ngibuyisa, njalo ngizabuya, ngoba unguThixo uNkulunkulu wami.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Emva kokweduka kwami, ngaphenduka; emva kokuba sengizwisisile, ngazitshaya isifuba. Ngaba lenhloni ngadumazeka ngoba ngangilehlazo lasebutsheni bami.’
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
U-Efrayimi kasindodana yami ethandekayo, umntanami engithokoza ngaye na? Lanxa ngihlala ngikhuluma kubi ngaye ngisamkhumbula. Ngakho inhliziyo yami iyamlangatha; ngiyamzwela kakhulu, kutsho uThixo.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Beka izitshengiso zomgwaqo; umise lezinsika zeziqondiso. Nanzelela umgwaqo, indlela ozahamba ngayo. Phenduka, wena Ntombi egcweleyo Israyeli, buyela emadolobheni akho.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Koze kube nini ulokhu uzulazula, wena ndodakazi engathembekanga na? UThixo uzadala into entsha emhlabeni, owesifazane uzavikela indoda.”
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
UThixo uSomandla, uNkulunkulu ka-Israyeli uthi, “Lapho ngibabuyisa bevela ekuthunjweni, abantu abaselizweni lakoJuda lasemadolobheni alo bazawasebenzisa futhi amazwi la athi, ‘UThixo akubusise wena ndawo yokuhlala elungileyo, wena ntaba engcwele.’
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Abantu bazahlala ndawonye koJuda lasemadolobheni akhona wonke, abalimi kanye lalabo abazulazulayo lemihlambi yabo.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Ngizaqinisa abadiniweyo ngisuthise abangelamandla.”
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Lapho-ke ngaphaphama ngakhangela indawana yonke. Ubuthongo bami babubemnandi kimi.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
“Insuku ziyeza, lapho engizahlanyela khona indlu ka-Israyeli lendlu kaJuda lenzalo yabantu lezinyamazana.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Njengoba ngabalinda ukusiphuna lokudiliza, ukuchitha lokubhubhisa kanye lokuletha umonakalo, ngokunjalo ngizabalinda ukwakha lokuhlanyela,” kutsho uThixo.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
“Ngalezonsuku abantu kabasayikutsho ukuthi, ‘Abazali badle amavini amunyu, ngakho amazinyo abantwana asetshelela.’
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Esikhundleni salokho, umuntu wonke uzafela izono zakhe; loba ngubani odla amavini amunyu amazinyo akhe azatshelela.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Isikhathi siyeza, lapho engizakwenza khona isivumelwano esitsha lendlu ka-Israyeli kanye lekaJuda,” kutsho uThixo.
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
“Kasiyikufana lesivumelwano engasenza labokhokho babo lapho engababamba khona ngesandla ukuba ngibakhuphe eGibhithe, ngoba bephula isivumelwano sami, lanxa ngangingumyeni wabo,” kutsho uThixo.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
“Lesi yiso isivumelwano engizasenza lendlu ka-Israyeli ngemva kwalesosikhathi,” kutsho uThixo. “Ngizafaka umthetho wami ezingqondweni zabo, ngiwulobe lasezinhliziyweni zabo. Ngizakuba nguNkulunkulu wabo, bona bazakuba ngabantu bami.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Umuntu kasayikufundisa umakhelwane wakhe, kumbe umfowabo esithi, ‘Mazi uThixo,’ ngoba bonke bazangazi, kusukela komncinyane wabo kusiya komkhulu, kutsho uThixo. Ngoba ngizabathethelela ububi babo, njalo angiyikukhumbula izono zabo futhi.”
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nanku akutshoyo uThixo, yena obeka ilanga ukuba likhanyise emini, omisa inyanga lezinkanyezi ukuba kukhanye ebusuku, onyakazisa ulwandle ukuze amagagasi alo ahlokome, uThixo uSomandla yilo ibizo lakhe, uthi:
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
“Nxa izimiso lezi zinganyamalala ebusweni bami,” kutsho uThixo, “kulapho lenzalo ka-Israyeli ezacina khona ukuba yisizwe phambi kwami.”
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
UThixo uthi: “Nxa amazulu phezulu engalinganiswa lezisekelo zomhlaba ngaphansi zihlolwe, kulapho engingayilahla khona yonke inzalo ka-Israyeli ngenxa yakho konke abakwenzileyo,” kutsho uThixo.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
“Insuku ziyeza,” kutsho uThixo, “lapho idolobho leli ngizalakhelwa kutsha kusukela eMphotshongweni waseHananeli kusiya eSangweni leNgosi.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Intambo yokulinganisa izasukela lapho iqonde eqaqeni lweGarebi ibe isijikela eGowa.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Isigodi sonke lapho okulahlelwa khona izidumbu zabafileyo lomlotha, lawo wonke amasimu kusiyafika esigodini seKhidironi ngasempumalanga kusiyafika ejikweni leSango leBhiza, kuzakuba ngcwele kuThixo. Idolobho kaliyikusitshunwa futhi loba lidilizwe.”

< Jeremiah 31 >