< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
Tanī laikā, saka Tas Kungs, Es visām Israēla ciltīm būšu par Dievu, un tās Man būs par ļaudīm.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Tā saka Tas Kungs: Tie ļaudis, kas atlikuši no zobena, atraduši žēlastību tuksnesī; Es iešu, Israēli vest pie dusas.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Tas Kungs man parādījies no tālienes: Es tevi esmu mīļojis ar mūžīgu mīlestību, tādēļ Es tevi žēlīgi esmu vilcis pie Sevis.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Es tevi atkal uztaisīšu, un tu tapsi uzcelta, Israēla meita! Tu atkal pušķosies ar savām bungām un iziesi priecīgi diedama.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Tu atkal dēstīsi vīna dārzus Samarijas kalnos, dēstītāji tos dēstīs un droši baudīs.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Jo būs diena, kad sargi sauks uz Efraīma kalniem: ceļaties, ejam augšā uz Ciānu pie Tā Kunga, mūsu Dieva.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Jo tā saka Tas Kungs: sauciet par Jēkabu ar līksmību un gavilējiet par tautu galvu, sludinājiet, teiciet un sakiet: ak Kungs, pestī Savus ļaudis, Israēla atlikušos!
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Redzi, Es tos atvedīšu no ziemeļu zemes un tos sapulcināšu no zemes galiem; viņu starpā būs akli un tizli, grūtas un dzemdētājas kopā, lielā pulkā tie šurp atgriezīsies.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Tie nāks ar raudāšanu, un ar pielūgšanu Es tos gribu vest un vadīt pie ūdens strautiem pa līdzenu ceļu, kur tie nepaklups; jo Es esmu Israēlim palicis par tēvu un Efraīms ir Mans pirmdzimtais.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Klausiet Tā Kunga vārdu, jūs tautas, un sludiniet pa tām salām, kas tālu, un sakāt: kas Israēli izklīdinājis, Tas viņu atkal sapulcinās un to sargās kā gans savu ganāmo pulku.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Jo Tas Kungs Jēkabu atpircis un viņu izglābis no rokas, kas bija stiprāka nekā viņš.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Un tie nāks un gavilēs Ciānas kalnā un plūdīs pie Tā Kunga dāvanām, pie labības un pie vīna un pie eļļas un pie jauniem jēriem un vēršiem, un viņu dvēsele būs kā mitrs dārzs, un tie vairs nebūs noskumuši.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Tad jaunava priecāsies diedama un jaunekļi un sirmgalvji kopā. Jo Es pārvērtīšu viņu skumību par prieku un tos iepriecināšu un ielīksmošu pēc viņu noskumšanas
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Un Es mielošu priesteru dvēseli ar taukumiem, un Mani ļaudis taps pieēdināti ar Manu labumu, saka Tas Kungs.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Tā saka Tas Kungs: brēkšana ir dzirdama Rāmā, žēlošanās un gauža raudāšana; Rahēle apraud savus bērnus, un negribās iepriecinājuma par saviem bērniem, jo to vairs nav.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Tā saka Tas Kungs: atrauj savu balsi no raudāšanas un savas acis no asarām, jo tur ir alga tavam darbam, saka Tas Kungs; tie atgriezīsies no ienaidnieka zemes.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Un cerība ir tavai nākamībai, saka Tas Kungs: jo tavi bērni nāks atpakaļ savās robežās.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Es klausīt esmu klausījies, ka Efraīms žēlojās: Tu mani esi pārmācījis, un es esmu pārmācīts kā nevaldāms teļš. Atgriez mani, tad es atgriezīšos. Jo Tu, Kungs, esi mans Dievs.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Tiešām, kad es nogriezos, tad man nāca žēlums, un kad es to atzinu, tad es situ uz saviem gurniem, jo es esmu apkaunots un kaunā tapis, nesdams savas jaunības negodu.
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Vai Efraīms Man nav dārgs dēls un mīļš bērns, ka cikkārt Es par viņu runāju, pieminēdams Es viņu pieminu? Tāpēc Mana sirds trīc par viņu, ka Es apžēlodamies par viņu apžēlojos, saka Tas Kungs.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Uzcel sev stabus, liec sev zīmes, un ņem vērā to ceļu, ko tu staigājis: Griezies atpakaļ, Israēla meita, griezies atpakaļ uz šīm savām pilsētām.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Cik ilgi tu maldīsies, tu atkāpēja meita? Jo Tas Kungs ir radījis ko jaunu virs zemes: sieva būs ap vīru.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: “šo vārdu tie vēl runās Jūda zemē un viņas pilsētās, kad Es atpakaļ vedīšu viņa cietumniekus: lai Tas Kungs tevi svētī, tu taisnības mājokli, tu svētais kalns!
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Un Jūda ar visām savām pilsētām kopā tur dzīvos, arāji un kas staigā ar ganāmiem pulkiem.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Jo Es dzirdināšu iztvīkušo dvēseli un atspirdzināšu ikkatru noskumušu dvēseli.”
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Tāpēc es uzmodos un skatījos, un mans miegs man bija gards.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka Es Israēla namu un Jūda namu augļošu ar cilvēku dzimumu un ar lopu dzimumu.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Un kā Es pret tiem esmu bijis nomodā, tos izraudams un nolauzdams un postīdams un samaitādams un mocīdams, tā Es par tiem gribu nomodā būt, tos uztaisīdams un dēstīdams, saka Tas Kungs,
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
Tanīs dienās vairs nesacīs: tēvi ēduši skābas vīnogas, un bērniem zobi apmizējuši.
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Bet ikvienam sava nozieguma dēļ būs mirt, ikviens cilvēks, kas ēd skābas vīnogas, tam zobi apmizēs.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka Es jaunu derību celšu ar Israēla namu un ar Jūda namu,
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
Ne tādu derību, kā esmu cēlis ar viņu tēviem, kad tos pie rokas satvēru un izvedu no Ēģiptes zemes; to Manu derību tie iznīcinājuši, tad Es arīdzan par tiem neesmu bēdājis, saka Tas Kungs.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Bet šī ir tā derība, ko Es ar Israēla namu celšu pēc šīm dienām, saka Tas Kungs: Es došu Savu bauslību viņu prātā un to rakstīšu viņu sirdī, un Es tiem būšu par Dievu, un tie Man būs par tautu.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Un tad draugs draugu vairs nemācīs nedz brālis brāli, sacīdams: atzīstiet To Kungu! Jo tie visi Mani atzīs, ir viņu mazie, ir viņu lielie, saka Tas Kungs. Jo Es piedošu viņu noziegumus un nepieminēšu vairs viņu grēkus.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Tā saka Tas Kungs, kas sauli dienā dod pār spīdekli, mēnesi un zvaigznes pēc saviem likumiem par spīdekļiem naktī, kas jūru kustina, ka viņas viļņi kauc, Kungs Cebaot ir Viņa vārds:
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Kad šie likumi Manā priekšā zudīs, saka Tas Kungs, tad arī Israēla dzimums zudīs, ka nebūs vairs tauta Manā priekšā mūžīgi.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Tā saka Tas Kungs: Kad debesis augšām varēs mērot un zemes dibenus apakšā varēs izmanīt, tad Es arī atmetīšu visu Israēla dzimumu, visa tā dēļ, ko tie darījuši, saka Tas Kungs.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka šī pilsēta Tam Kungam taps uzcelta no Hananeēļa torņa līdz stūru vārtiem.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Un mēra aukla izstiepsies tālāki uz priekšu līdz Gāreba pakalnam un griezīsies uz Goātu.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Un visa miroņu un pelnu ieleja, un visi tīrumi līdz Kidronas upei, līdz zirgu vārtu stūrim pret rītiem, būs Tam Kungam svēti; tur vairs neko neizdeldēs nedz nolauzīs ne mūžam.

< Jeremiah 31 >