< Jeremiah 31 >
1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
I A manawa, wahi a Iehova, owau auanei ke Akua o na ohana a pau o ka Iseraela, a o lakou auanei ko'u poe kanaka.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Ke i mai nei o Iehova penei, O na kanaka i koe o ka pahikaua, loaa no ia lakou ka lokomaikai ma ka waonahele, o ka Iseraela hoi, ia'u i hele ai e hoomaha ia lakou.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
I ka wa kahiko, ikea o Iehova ia'u, i mai la, Oiaio, ua mau loa ko'u aloha aku ia oe; nolaila, ua hooloihi aku au i ka lokomaikai nou.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
E kukulu hou ana no wau ia oe, a e kukuluia no oe, e ke kaikamahine puupaa o ka Iseraela. E kahiko hou ia no oe i kou mau pahu kani, e hele aku no i ka haa ana o ka poe olioli.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
E kanu hou ana no oe i na kumuwaina ma na mauna o Samaria; e kanu no ka poe kanu, a e ai wale hoi.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
No ka mea, e hiki mai auanei ka la e hea aku ai ka poe kiai maluna o ka mauna o Eperaima, E ala mai oukou, a e pii aku kakou i Ziona, io Iehova la, i ko kakou Akua.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova penei; E mele olioli no Iehova, a e hauoli hoi ma ke poo o na aina; e kala aku, a e halelu, a e olelo iho, E Iehova, e hoola oe i kou poe kanaka i ke koena o ka Iseraela.
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Aia hoi, e lawe no wau ia lakou, mai ka aina o ke kukulu akau mai, a e hoiliili hoi ia lakou, mai na mokuna mai o ka honua, me lakou pu no, ka poe makapo, a me ka poe oopa, a me ka wahine hapai, a me ka wahine hanau keiki ana; he poe nui ka i hoi pu mai.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
E hele mai no lakou me ka uwe, ia lakou e pule ai, e alakai no wau ia lakou; e hoohele no wau ia lakou ma na kahawai, ma ke ala pololei; aole lakou e kulanalana malaila, no ka mea, he Makua no wau no ka Iseraela, a o Eperaima ka'u hiapo.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
E hoolohe oukou i ka olelo a Iehova, e ko na aina, a e kala aku hoi ma na aina loihi e aku, a e olelo, O ka mea i hoopuehu i ka Iseraela, nana no lakou e hoiliili, a e malama ia lakou, e like me ke kahuhipa i kona poe hipa.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
No ka mea, ua hoolapanai o Iehova ia Iakoba me ka uku hoopakele ia ia, mailoko mai o ka lima i oi aku ka ikaika i kona.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
A e hele mai no lakou a e oli ma kahi kiekie o Ziona, a holo pu no lakou i ka maikai o Iehova, no ka huapalaoa, a no ka waina, a no ka aila, a no na keiki o na hipa, a me na bipi; a e like auanei ko lakou uhane me ka mahinaai i mau; aole loa lakou e kaumaha hou aku.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Alaila, e olioli no ka wahine puupaa ma ka haa ana, o na kanaka opiopio a me na elemakule pu; no ka mea, e hoololi au i ko lakou kaumaha ana i olioli, a e hoomaha au ia lakou, a e hoohauoli ia lakou mailoko mai o ko lakou kaumaha.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
A hoomaona aku au i ka uhane o na kahuna i ka momona, a e maona auanei ko'u poe kanaka i ko'u maikai, wahi a Iehova.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Ke i mai nei o Iehova penei; Ua loheia ka leo ma Rama, he pihe, a me ka uwe nui ana; e uwe ana o Rahela no kana mau keiki, a hoole oia, aole e na no kana mau keiki, no ka mea, aole ae nei lakou.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Ke i mai nei o Iehova penei; E uumi oe i kou leo i ka uwe ana, a me kou mau maka i ua waimaka; no ka mea, e ukuia no kau hana. wahi a Iehova; a e hele hou mai no lakou, mai ka aina mai o ka enemi.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
He lana no ka manao i kou hope, wahi a Iehova, i hele hou mai no na keiki i ko lakou mokuna iho.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Oiaio no ua lohe au ia Eperaima e olo pihe ana, Ua paipai mai oe ia'u, a ua paipaiia mai au, e like me ka bipi maa ole. E hoohuli oe ia'u, a e hoohuliia no wau, no ka mea, o oe no o Iehova, ko'u Akua.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
No ka mea, mahope o ko'u hoohuliia, mihi no wau; a mahope o ko'u aoia mai, hahau no wau i ko'u uha. Hilahila no wau, oia, hoopalaimaka no hoi, no ka mea, kaikai no wau i ka hoowahawaha o ko'u wa opiopio.
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
O Eperaima anei ka'u keiki aloha? He keiki anei ia e olioli ai? No ka mea, mai ka wa mai o kau olelo ku e ana ia ia, he oiaio, ke hoomanao mau nei au ia ia: nolaila, e haehae nei ko'u opu nona; he oiaio no e lokomaikai aku no wau ia ia, wahi a Iehova.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
E kukulu oe i ahu, a hana hoi i puu kiekie nou; e kau oe i kou naau ma ke kuamoo, ma ke ala au i hele ai. E huli hou oe, e ke kaikamahine puupaa o ka Iseraela, e huli hou oe i keia mau kulanakauhale ou.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Pehea la ka loihi o kou aea ana aku, e ke kaikamahine hoi hope? No ka mea, ua hana o Iehova i ka mea hou ma ka honua, na ka wahine no e hoomalu i ke kane.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Penei ka olelo ana mai a Iehova o na kaua, ke Akua o ka Iseraela; E olelo hou no lakou i keia mau olelo ma ka aina o ka Iuda, a ma kolaila mau kulanakauhale, i ka wa a'u e hoihoi ai i ko lakou pio ana; Na Iehova e hoopomaikai ia oe, i kahi e noho ai o ka hoopono, ka mauna hoi o ka hemolele.
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
A e noho pu no maloko olaila, ma ka Iuda hoi, a maloko o kolaila mau kulanakauhale a pau ka poe mahiai, a me ka poe malama hipa.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
No ka mea, ua hooana aku au i ka uhane i makewai, a ua hoomaona wau i na uhane a pau i niuniu.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Alaila, ala iho la au, a nana ae la, a ua oluolu ko'u hiamoe ana ia'u.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, e lulu iho ai au i ka ohana a Iuda, i ka hua a ke kanaka a me ka hua a ka holoholona.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
A e like no me ka'u i kiai iho ai maluna o lakou, e uhuki ae, a e uhai iho, a e hoohiolo, a e luku, a e hoopilikia; pela no hoi au e kiai ai maluna iho, e kukulu, a e kanu, wahi a Iehova.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
Ia mau la la, aole lakou e olelo hou ae, Ua ai na makuakane i ka huawaina awahia, a ua oi na niho o na keiki.
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Aka, e make auanei kela mea keia mea no kona hewa iho: o kela kanaka keia kanaka e ai ana i ka huawaina awahia, o kona mau niho no ke oi.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, e hana aku ai au i berita hou me ka ohana a Iseraela, a me ka ohana a Iuda:
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
Aole e like ana me ka berita a'u i hana aku ai me ko lakou poe makaukane, i ka la a'u i lalau aku ai ia lakou ma ka lima, e lawe ia lakou mai ka aina o Aigupita mai; o ua berita la a'u ka lakou i uhai ai, ia'u i noho ai he Kane na lakou, wahi a Iehova:
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Aka, o keia ka berita a'u e hana'i me ka ohana a Iseraela; Mahope iho o ia mau la, wahi a Iehova, e kau no wau i ko'u kanawai maloko o lakou, a e kakau iho ma ko lakou naau; a owau auanei ko lakou Akua, a o lakou hoi ko'u poe kanaka.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Aole lakou e ao hou aku o kela mea keia mea i kona hoalauna, a o kela mea keia mea i kona hoahanau, e olelo ana, E ike ia Iehova; no ka mea, e ike auanei lakou a pau ia'u, mai ka mea liilii loa o lakou a hiki i ko lakou mea nui loa, wahi a Iehova; no ka mea, e kala aku auanei au i ko lakou hala, aole hoi au e hoomanao hou aku i ko lakou hewa.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Penei ka olelo a Iehova, a ka mea haawi mai i ka la i lama no ke ao, a me na kanawai no ka mahina a me na hoku ma ka po, o ka mea hoaleale hoi i ke kai a halulu kona mau ale; o Iehova Sabaota kona inoa.
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Ina e neenee aku keia mau kanawai mai ko'u alo aku, wahi a Iehova, alaila e pau auanei na mamo a Iseraela, aole ia he lahuikanaka imua o'u, a mau loa aku.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Ke olelo mai nei o Iehova penei; Ina e hiki ke anaia ka lani iluna, a e huliia hoi na kumu o ka honua ilalo, alaila, e haalele no au i na mamo a pau o ka Iseraela, no na mea a pau a lakou i hana'i, wahi a Iehova.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, e kukuluia'i ke kulanakauhale no Iehova, mai ka halekiai o Hananeela a hiki i ka pukapa o ke kihi.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
A e hele aku ke kaula-ana ma o aku maluna o ka puu Gareba, a e poai mai i Goata.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
A o ke awawa a pau o na kupapau, a o ka lehuahi, a o na kula a pau a hiki i kahawai o Kiderona, a hiki i ka puka lio ma ka hikina, e laa ia no Iehova; aole ia e uhuki hou ia, aole hoi e hoohiolo hou ia a mau loa aku.