< Jeremiah 31 >
1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
En ce temps-là, — oracle de Yahweh, — je serai le Dieu de toutes les familles d’Israël, et elles seront mon peuple.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Ainsi parle Yahweh: Il a trouvé grâce dans le désert, le peuple échappé au glaive; je veux mettre Israël en repos.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Yahweh m’est apparu de loin. Je t’ai aimée d’un amour éternel, aussi j’ai prolongé pour toi la miséricorde.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Je te bâtirai encore, et tu seras rebâtie, vierge d’Israël; tu te pareras encore en main tes tambourins, et tu t’avanceras au milieu des danses joyeuses.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Tu planteras encore tes vignes sur les montagnes de Samarie; ceux qui plantent planteront, et ils recueilleront.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Car le jour vient où les gardes crieront sur la montagne d’Éphraïm: « Levez-vous et montons à Sion vers Yahweh notre Dieu. »
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Car ainsi parle Yahweh: Poussez des cris de joie sur Jacob, éclatez d’allégresse pour la première des nations; faites- vous, entendre, chantez des louanges et dites: « Yahweh, sauve ton peuple, le reste d’Israël! »
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Voici que je les ramène du pays du septentrion, que je les rassemble des extrémités de la terre. Parmi eux seront l’aveugle et le boiteux, la femme enceinte et celle qui enfante; ils reviendront ici en grande foule.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Ils reviendront en pleurant; je les ramènerai au milieu de leurs supplications; je les conduirai aux eaux courantes, par un chemin uni où ils ne broncheront pas; car j’ai été un père à Israël, et Ephraïm est mon premier-né.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Nations, écoutez la parole de Yahweh et annoncez-la aux îles lointaines; dites: « Celui qui a dispersé Israël le rassemblera, et le gardera comme un berger son troupeau.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Car Yahweh a racheté Jacob, Il l’a délivré des mains d’un plus fort que lui. »
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Ils viendront avec des cris de joie sur la hauteur de Sion; ils afflueront vers les biens de Yahweh, vers le blé, vers le vin nouveau, vers l’huile, vers les brebis et les bœufs; leur âme sera comme un jardin arrosé, et ils ne continueront plus de languir.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Alors la jeune fille s’égaiera à la danse, et les jeunes hommes et les vieillards ensemble; je changerai leur deuil en joie, je les consolerai, je les réjouirai après leurs douleurs.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Je rassasierai de graisse l’âme des prêtres, et mon peuple se rassasiera de mes biens, — oracle de Yahweh.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Ainsi parle Yahweh: Une voix a été entendue à Rama, des lamentations et des pleurs amers: Rachel pleurant ses enfants; elle refuse d’être consolée, sur ses enfants, parce qu’ils ne sont plus.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Ainsi parle Yahweh: Retiens ta voix de gémir, et tes yeux de pleurer. Car ton œuvre aura sa récompense, — oracle de Yahweh: ils reviendront du pays de l’ennemi.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Il y a de l’espérance pour tes derniers jours, — oracle de Yahweh, et tes enfants retourneront dans leurs frontières.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
J’ai entendu Éphraïm qui gémit: « Tu m’as châtié, et j’ai été châtié, comme un jeune taureau indompté; fais-moi revenir et je reviendrai, car tu es Yahweh mon Dieu!
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Car après m’être détourné, je me suis repenti, et après avoir compris, j’ai frappé ma cuisse; je suis honteux et confus, car je porte l’opprobre de ma jeunesse. »
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Éphraïm est-il donc pour moi un fils si cher, un enfant favori? Car chaque fois que je parle contre lui, je me ressouviens encore de lui. Aussi pour lui mes entrailles se sont émues; oui, j’aurai pitié de lui, — oracle de Yahweh.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Dresse pour toi des signaux, pose pour toi des jalons; fais attention à la route, au chemin par lequel tu as marché. Reviens, vierge d’Israël, reviens ici, dans tes villes.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Jusques à quand seras-tu errante, fille rebelle? Car Yahweh a créé une chose nouvelle sur la terre: une femme entourera un homme.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Ainsi parle Yahweh des armées, Dieu d’Israël: On dira encore cette parole sur la terre de Juda et dans ses villes, quand je ramènerai leurs captifs: « Que Yahweh te bénisse, demeure de la justice, montagne de la sainteté! »
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Là habiteront Juda et toutes ses villes, les laboureurs et ceux qui conduisent les troupeaux.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Car j’abreuverai l’âme altérée, et je rassasierai l’âme languissante.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Sur cela je me suis réveillé, et j’ai vu que mon sommeil avait été doux.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Des jours viennent — oracle de Yahweh, où j’ensemencerai la maison d’Israël et la maison de Juda d’une semence d’homme et d’une semence d’animaux.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Et il arrivera: comme j’ai veillé sur eux pour arracher et pour abattre, pour ruiner, pour détruire et pour faire du mal, ainsi je veillerai sur eux pour bâtir et pour planter, — oracle de Yahweh.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
En ces jours-là on ne dira plus: « Les pères ont mangé des raisins verts, et les dents des fils en sont agacées. »
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Mais chacun mourra pour son iniquité; tout homme qui mangera des raisins verts, ses dents en seront agacées.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Voici que des jours viennent, — oracle de Yahweh, où je concluerai avec la maison d’Israël et avec la maison de Juda une alliance nouvelle,
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
non comme l’alliance que je conclus avec leurs pères, le jour où je les pris par la main pour les faire sortir du pays d’Égypte, alliance qu’eux ont rompue, quoique je fusse leur époux.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Car voici l’alliance que je ferai avec la maison d’Israël, après ces jours-là, — oracle de Yahweh: Je mettrai ma loi au dedans d’eux, et je l’écrirai sur leur cœur; et je serai leur Dieu, et ils seront mon peuple.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Un homme n’enseignera plus son prochain, ni un homme son frère, en disant: « Connaissez Yahweh! » Car ils me connaîtront tous, depuis les petits jusqu’aux grands, — oracle de Yahweh. Car je pardonnerai leur iniquité, et je ne me souviendrai plus de leur péché.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Ainsi parle Yahweh, qui donne le soleil pour éclairer pendant le jour, et trace des lois à la lune et aux étoiles pour éclairer pendant la nuit, qui soulève la mer et ses flots mugissent, — Yahweh des armées est son nom: —
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Si jamais ces lois cessent devant moi, — oracle de Yahweh, alors aussi la race d’Israël cessera pour toujours d’être une nation devant moi.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Ainsi parle Yahweh: Si les cieux peuvent se mesurer en haut, et les fondements de la terre se sonder en bas, alors aussi je rejetterai toute la race d’Israël, à cause de tout ce qu’ils ont fait, — oracle de Yahweh.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Voici que des jours viennent, — oracle de, où cette ville sera rebâtie pour Yahweh, depuis la tour de Hananéel jusqu’à la porte de l’Angle.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Le cordeau à mesurer sera tiré en droite ligne sur la colline de Gareb, et il tournera vers Goa.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Et toute la vallée des cadavres et des cendres, et tous les champs jusqu’au torrent de Cédron, et jusqu’à l’angle de la porte des Chevaux, vers l’orient, seront des lieux saints à Yahweh, et ils ne seront jamais ni dévastés ni détruits.