< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
"Siihen aikaan, sanoo Herra, minä olen kaikkien Israelin sukukuntien Jumala, ja he ovat minun kansani."
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Näin sanoo Herra: "Kansa, miekalta säästynyt, löysi erämaassa armon; minä menen saattamaan sen, Israelin, rauhaan".
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Kaukaa ilmestyy minulle Herra: "Iankaikkisella rakkaudella minä olen sinua rakastanut, sentähden minä olen vetänyt sinua puoleeni armosta.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Minä rakennan sinut jälleen, ja sinä tulet rakennetuksi, neitsyt Israel. Sinä kaunistat itsesi jälleen käsirummuillasi ja lähdet iloitsevaisten karkeloon.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Sinä istutat jälleen viinitarhoja Samarian vuorille; ne, jotka istuttavat, saavat korjata hedelmätkin.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Sillä päivä on tuleva, jolloin vartijat huutavat Efraimin vuorella: 'Nouskaa, lähtekäämme Siioniin Herran, meidän Jumalamme, tykö'.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Sillä näin sanoo Herra: Riemuitkaa iloiten Jaakobista, kohottakaa riemuhuuto hänelle, joka on kansojen pää; kuuluttakaa, kiittäkää ja sanokaa: 'Auta, Herra, kansaasi, Israelin jäännöstä'.
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Katso, minä tuon heidät pohjoisesta maasta, kokoan heidät maan perimmäisiltä ääriltä. Heissä on sokeita ja rampoja ynnä raskaita ja synnyttäväisiä: suurena joukkona he palajavat tänne.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Itkien he tulevat, ja minä johdatan heitä, kun he kulkevat rukoillen. Minä vien heidät vesipuroille, tasaista tietä, jolla he eivät kompastu. Sillä minä olen Israelin isä, ja Efraim on minun esikoiseni.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Kuulkaa Herran sana, te kansat, ilmoittakaa kaukaisissa merensaarissa ja sanokaa: Hän, joka Israelin hajoitti, on sen kokoava ja varjeleva sitä niinkuin paimen laumaansa.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Sillä Herra on lunastanut Jaakobin ja vapahtanut hänet häntä väkevämmän kädestä.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Ja he tulevat ja riemuitsevat Siionin kukkulalla, tulevat virtanaan Herran hyvyyden tykö, jyväin, viinin ja öljyn ääreen, karitsain ja karjan ääreen. Ja heidän sielunsa on oleva niinkuin runsaasti kasteltu puutarha, eivätkä he enää näänny.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Silloin neitsyt iloitsee karkelossa ja nuorukaiset ja vanhukset yhdessä. Minä muutan heidän surunsa riemuksi, annan heille lohdutuksen ja ilon heidän murheensa jälkeen.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Ja minä virvoitan pappien sielut lihavuuden ääressä, ja minun kansani ravitaan minun hyvyydelläni, sanoo Herra.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Näin sanoo Herra: Kuule, Raamasta kuuluu valitus, katkera itku: Raakel itkee lapsiansa, hän ei lohdutuksesta huoli surussaan lastensa tähden, sillä niitä ei enää ole.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Näin sanoo Herra: Pidätä äänesi itkusta, silmäsi kyyneleistä, sillä sinun työstäsi on tuleva palkka, sanoo Herra, ja he palajavat vihollisen maasta.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Sinulla on tulevaisuuden toivo, sanoo Herra: sinun lapsesi palajavat omalle maalleen.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Minä olen kyllä kuullut Efraimin valittavan: 'Sinä olet kurittanut minua, olen saanut kuritusta niinkuin vikuroiva vasikka. Palauta minut, niin minä palajan; sillä sinä olet Herra, minun Jumalani.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Sillä käännyttyäni minä kadun, ja päästyäni ymmärrykseen minä lyön lanteeseeni. Minä häpeän, tunnen häpeätä, sillä minä kannan nuoruuteni pilkkaa.'
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Eikö Efraim ole minun kallis poikani, minun lempilapseni? Sillä niin usein kuin minä puhunkin häntä vastaan, alati minä häntä muistan. Siksi minun sisimpäni väräjää hänen tähtensä: minun täytyy armahtaa häntä, sanoo Herra.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Pystytä itsellesi kivimerkkejä, aseta itsellesi tienviittoja, paina mieleesi tie, polku, jota olet kulkenut. Palaja, neitsyt Israel, palaja näihin kaupunkeihisi.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Kuinka kauan sinä mutkistelet sinne ja tänne, sinä luopiotytär? Sillä Herra luo maahan uutta: nainen miestä piirittää.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Vielä kerran sanotaan Juudan maassa ja sen kaupungeissa, kun minä käännän heidän kohtalonsa, tämä sana: 'Herra siunatkoon sinua, sinä vanhurskauden asuinsija, sinä pyhä vuori'.
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Ja Juuda kaikkine kaupunkeineen asuu siellä yhdessä, peltomiehet ja ne, jotka vaeltavat laumoineen.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Sillä minä virvoitan väsyneen sielun, ja jokaisen nääntyvän sielun minä ravitsen."
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Siihen minä heräsin ja katselin, ja uneni oli minusta suloinen.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
"Katso, päivät tulevat, sanoo Herra, jolloin minä kylvän Israelin maahan ja Juudan maahan ihmisen siementä ja karjan siementä.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Ja niinkuin minä olen valvonut repiäkseni ja kukistaakseni heitä, hajottaakseni ja hävittääkseni, tuottaakseni onnettomuutta, niin minä olen valvova rakentaakseni ja istuttaakseni heitä, sanoo Herra.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
Niinä päivinä ei enää sanota: 'Isät söivät raakoja rypäleitä, lasten hampaat heltyivät';
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
vaan jokaisen on kuoltava oman syntivelkansa tähden. Jokaiselta ihmiseltä, joka syö raakoja rypäleitä, heltyvät hänen omat hampaansa.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Katso, päivät tulevat, sanoo Herra, jolloin minä teen Israelin heimon ja Juudan heimon kanssa uuden liiton;
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
en sellaista liittoa kuin se, jonka minä tein heidän isäinsä kanssa silloin, kun minä tartuin heidän käteensä ja vein heidät pois Egyptin maasta, ja jonka liittoni he ovat rikkoneet, vaikka minä olin ottanut heidät omikseni, sanoo Herra.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Vaan tämä on se liitto, jonka minä teen Israelin heimon kanssa niiden päivien tultua, sanoo Herra: Minä panen lakini heidän sisimpäänsä ja kirjoitan sen heidän sydämiinsä; ja niin minä olen heidän Jumalansa, ja he ovat minun kansani.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Silloin ei enää toinen opeta toistansa eikä veli veljeänsä sanoen: 'Tuntekaa Herra'. Sillä he kaikki tuntevat minut, pienimmästä suurimpaan, sanoo Herra; sillä minä annan anteeksi heidän rikoksensa enkä enää muista heidän syntejänsä.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Näin sanoo Herra, joka on pannut auringon valaisemaan päivää, kuun ja tähdet lakiensa mukaan valaisemaan yötä, hän, joka liikuttaa meren, niin että sen aallot pauhaavat-Herra Sebaot on hänen nimensä:
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Jos väistyvät nämä lait minun kasvojeni edestä, silloin myös lakkaavat Israelin jälkeläiset olemasta kansa minun kasvojeni edessä ainiaan.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Näin sanoo Herra: Jos voidaan mitata taivaat ylhäällä ja tutkia maan perustukset alhaalla, silloin vasta minä hylkään Israelin jälkeläiset kaikki, kaiken sen tähden, mitä he ovat tehneet, sanoo Herra.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Katso, päivät tulevat, sanoo Herra, jolloin Herran kaupunki rakennetaan jälleen Hananelin-tornista Kulmaporttiin asti.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Ja edelleen mittanuora kulkee suoraan Gaarebin kukkulalle ja kääntyy sitten Gooaan.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Ja koko laakso, ruumiineen ja tuhkineen, ja kaikki keto Kidronin puroon asti, Hevosportin kulmaan saakka itään päin, on oleva Herralle pyhitetty. Ei sitä enää ikinä hävitetä eikä kukisteta."

< Jeremiah 31 >