< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
At that time, Declareth Yahweh, I will become a God, to all the families of Israel; And, they, shall become my people.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Thus, saith Yahweh, —There hath found favour in the desert people escaped from the sword, —I must go to cause him, even Israel, to rest.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
From afar, Yahweh hath appeared unto me, Yea with an age-abiding love, have I loved thee, For this cause, have I prolonged to thee lovingkindness.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Again, will I build thee and thou shalt be built, thou virgin, Israel, —Again, shalt thou deck thyself with thy timbrels, And go forth in the dance of them that make merry:
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Again, shalt thou plant vineyards in the mountains of Samaria, The planters have planted, and have laid open the vineyards,
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
For it is a day the watchmen have proclaimed throughout the hill country of Ephraim, —Arise ye and let us go up to Zion, unto Yahweh our God.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
For, thus, saith Yahweh—Shout ye for Jacob with gladness, Make shrill thy voice, as the head of the nations, —Publish ye praise ye and say, Save thou O Yahweh thy people, the remnant of Israel.
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Behold me bringing them in out of the land of the North, And I will gather them out of the remote parts of the earth, Among them, the blind and the lame The woman with child and she that giveth birth, together, —A great convocation, shall return hither:
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
With weeping, shall they come in, And with supplications, will I lead them, I will bring them unto rivers of waters By a smooth way, wherein they shall not stumble, —For I have become, to Israel, a father, And as for Ephraim, my firstborn, is he!
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Hear ye the word of Yahweh, O ye nations, And declare ye in the Coastlands, afar off, —And say—He that scattereth Israel, will gather him, And watch over him as a shepherd his flock;
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
For Yahweh hath ransomed Jacob, —And redeemed him from the hand of one stronger than he.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Then shall they come in and shall shout in triumph on the height of Zion, And shall stream unto the goodness of Yahweh To the wheat, and to the new wine, and to the oil, and to the young of the flocks and of the herds, —So shall their soul become like a garden well watered, And they shall not again languish any more.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Then shall the virgin rejoice, in the dance, And young men and elders [rejoice] together, And I will turn their mourning into gladness and will comfort them, And will make them rejoice from their sorrow;
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Then will I satiate the soul of the priests with fatness, And my people with my goodness, shall be satisfied, Declareth Yahweh.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Thus, saith Yahweh—A voice, in Ramah, is heard, Wailing, bitter weeping, Rachel weeping for her children, —She refuseth to be comforted for her children, For they are not!
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Thus, saith Yahweh—Restrain thy voice from weeping, And thine eyes from tears, —For there is a reward for thy labour, Declareth Yahweh, So they shall return from the land of the enemy:
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Yea there is hope for thy future Declareth Yahweh, —And thy sons shall return to their own boundary.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
I have, heard, Ephraim bemoaning himself, Thou hast chastised me and I have been chastised, Like a bullock, not broken in, Suffer me to return that I may return, For thou, art Yahweh my God.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Surely after my return, I was filled with regret, And after I came to know myself, I smote upon the thigh, —I turned pale and was even confounded For I had borne the reproach of my youthful days.
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Was Ephraim, a very precious son to me? Was he a most delightful child? For as often as I have spoken against him, I have, remembered, him again! For this cause, have my affections been deeply moved for him, I must have, compassion, upon him, Declareth Yahweh.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Erect thee waymarks Set thee up finger-posts, Apply thy heart to The highway—The road by which thou didst depart, —Return O virgin of Israel, Return unto these thy cities.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
How long wilt thou turn hither and thither, O apostate daughter? For Yahweh hath created a new thing in the earth, A female defendeth, a strong man!
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Thus, saith Yahweh of hosts, God of Israel, Again, shall they say this word, in the land of Judah and in the cities thereof, when I cause their captivity to return, Yahweh, bless thee, Thou home of righteousness! Thou mountain of holiness!
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Then shall there dwell throughout Judah itself and all the cities thereof, together, —Husbandmen, who shall move about with a flock;
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
For I have satiated the weary soul, —And every languishing soul, have I filled.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Upon this, I awoke and considered, —And, my sleep, had been sweet to me!
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Lo! days are coming, Declareth Yahweh—That I will sow, The house of Israel, and The house of Judah, With the seed of men, and With the seed of beasts;
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
And it shall come to pass, that—Just as I watched over them, to root up and to break down and to tear out and to destroy, and to break in pieces, So, will I watch over them, to build and to plant, Declareth Yahweh.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
In those days, shall they say no more, Fathers, did eat sour grapes, —And, children’s teeth, are blunted!
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
But, every one, for his own iniquity, shall die, —Any human being who eateth the sour grapes, his own teeth, shall be blunted.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Lo! days are coming, Declareth Yahweh, —When I will solemnize—With the house of Israel and With the house of Judah, A new covenant:
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
Not like the covenant which I solemnised with their fathers, In the day when I grasped their hand, to bring them forth out of the land of Egypt, —In that, they, brake my covenant Though, I, had become a husband unto them, Declareth Yahweh.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
For, this, is the covenant which I will solemnize with the house of Israel after those days Declareth Yahweh, I will put my law within them, Yea, on their heart, will I write it, —So will I become their God, And they shall become my people.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Then shall they no longer teach Every man his neighbour, and Every man his brother, saying, Know ye Yahweh, —For, they all, shall know me, From the least of them Even unto the greatest of them, Declareth Yahweh, For I will forgive their iniquity, And their sin, will I remember, no more.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Thus, saith Yahweh—Who hath given the sun for a light by day, The ordinances of the moon and the stars for a light by night, —Who excited the sea, and the waves thereof roared Yahweh of hosts, is his name: —
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
If these ordinances depart from before me, Declareth Yahweh, —the seed of Israel also, may cease from being a nation before me, all the days,
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Thus, saith Yahweh—If the heavens above can be measured, Or the foundations of the earth beneath, be searched out I also, may reject all the seed of Israel for all that they have done, Declareth Yahweh.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Lo days, are coming, Declareth Yahweh, That the city shall be built for Yahweh, From the tower of Hananeel, [As far as] the gate of the corner;
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Then shall go forth again the measuring-line straight forward, Over the hill Gareb, And it shall go round to Goah;
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
And, all the vale of the dead bodies, and of the ashes, and all the fields as far as the Kidron torrent-bed, as far as the horse-gate corner on the east, Shall be holy unto Yahweh, —It shall not be rooted up, nor thrown down, any more, unto times age-abiding.

< Jeremiah 31 >