< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
Niadtong panahona, nagaingon si Jehova: Ako mahimong Dios sa tanang mga banay sa Israel, ug sila mahimong akong katawohan.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
Mao kini ang giingon ni Jehova: Ang katawohan nga nanghibilin sa espada nakakaplag sa akong gracia didto sa kamingawan; bisan ngani ang Israel sa pag-adto ko aron sa pagpapahulay kaniya.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Si Jehova sa kanhi pa nagpakita kanako, nga nagaingon: Oo, gihigugma ko ikaw sa usa ka gugma nga walay katapusan: busa uban sa mahigugmaong-kalolot gidani ko ikaw.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
Tukoron ko ikaw pag-usab, ug ikaw matukod, Oh ulay sa Israel pagadayan-dayanan ka pag-usab uban sa imong mga tambol nga gagmay, ug moadto sa mga sayaw nila nga magakalipay.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Magatanum ikaw pag-usab ug mga kaparrasan ibabaw sa mga bukid sa Samaria; ang mga magtatanum managtanum ug managpahimulos sa bunga niini.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
Kay moabut ang usa ka adlaw, nga ang mga magbalantay sa bukid sa Ephraim maninggit: Tindog kamo, ug mangadto kita sa Sion ngadto kang Jehova nga atong Dios.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
Kay mao kini ang giingon ni Jehova: Mag-awit kamo nga malipayon alang kang Jacob, ug maninggit kamo alang sa pangulo sa mga nasud; manag-mantala kamo, managdayeg kamo, ug manag-ingon: Oh Jehova, luwasa ang imong katawohan; ang nanghibilin sa Israel.
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Ania karon, dad-on ko sila gikan sa amihanan nga yuta, ug tigumon ko sila gikan sa kinatumyang mga bahin sa yuta, ug uban kanila ang buta ug ang bakul, ang babaye nga mabdos ug siya nga nanganak sa tingub; usa ka dakung pundok mobalik sila didto.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Manganhi sila uban ang paghilak; ug uban ang mga pagpakilooy tultolan ko sila: palakton ko sila sa maoy sa ka amahan sa Israel, ug ang Ephraim maoy kamagulangan ko nga anak.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Pamati sa pulong ni Jehova, Oh kamo nga mga nasud, ug ipahayag kini sa mga pulo nga halayo; ug manag-ingon kamo: Siya nga nagpatibulaag sa Israel magatigum kaniya, ug magbantay kaniya samasa usa ka magbalantay nga magabantay sa iyang panon.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
Kay si Jehova naglukat kang Jacob, ug nagtubos kaniya gikan sa kamot niadtong kusgan pa kay kaniya.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
Busa sila manganhi ug manag-awit sa kinahitas-an sa Sion, ug manag-ambahan ngadto sa kaayo ni Jehova, ngadto sa trigo, ug ngadto sa bag-ong vino, ug ngadto sa lana, ug ngadto sa nati sa panon sa carnero ug sa panon sa vaca: ug ang ilang kalag mahisama sa usa ka tanaman nga binobuan sa tubig; ug sila dili na gayud managsubo pag-usab.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Unya ang ulay magamaya diha sa sayaw ug ang mga batan-ong lalake ug mga tigulang sa tingub; kay himoon ko nga kalipay ang ilang pagbalata, ug lipayon ko sila, ug himoon ko nga managmaya sila gikan sa ilang kasub-anan.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
Ug tagbawon ko ang kalag sa mga sacerdote sa katambok, ug ang akong katawohan pagabusgon ko sa akong kaayo, nagaingon si Jehova.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
Mao kini ang giingon ni Jehova: Usa ka tingog nadungog didto sa Rama, ang pagminatay, ug ang mapait nga paghilak, si Raquel naghilak tungod sa iyang mga anak; midumili siya nga pagalipayon tungod sa iyang mga anak, kay sila wala na man.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
Mao kini ang giingon ni Jehova: Pugngi ang imong tingog sa paghilak, ug pugngi ang imong mga mata sa pagpatulo sa mga luha; kay ang imong buhat pagabalusan, nagaingon si Jehova; ug sila moanhi pag-usab gikan sa yuta sa kaaway.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
Ug adunay paglaum alang sa imong kaugmaon, nagaingon si Jehova; ug ang imong mga anak moanhi pag-usab sa ilang kaugalingong utlanan.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
Sa pagkamatuod nadungog ko si Ephraim nga nagabakho sa iyang kaugalingon sa pag-ingon: Gihampak mo ako, ug ako gihampak, sama sa usa ka nati nga vaca nga wala maanad sa yugo: pabalikon mo ako ug ako mobalik; kay ikaw mao si Jehova nga akong Dios.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
Sa pagkamatuod sa human na ako pabalika, ako naghinulsol; ug sa human na ako matudloi, akong gihampak ang akong paa: ako naulaw, oo, nalibog sa ngani, tungod kay ako nag-antus sa pagkatinamay sa akong pagkabatan-on.
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
Si Ephraim ba ang akong minahal nga anak? pinalangga ba siyang anak? kay sa nakadaghan ako magsulti batok kaniya, ako sa mainiton gayud nahanumdum gihapon kaniya: busa ang akong kasingkasing nangandoy kaniya; ako sa pagkamatuod malooy kaniya, nagaingon si Jehova.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Magpatindog ka ug mga mohon sa mga alagianan: magbuhat ka ug mga haligi nga magatultol sa dalan; ipahimutang ang imong kasingkasing ngadto sa dalan, bisan pa sa dalan nga imong giadtoan: bumalik ka pag-usab, Oh, ulay sa Israel, bumalik ka pag-usab niining imong mga ciudad.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Hangtud ba anus-a ang imong paglakat ngadto ug nganhi, Oh ikaw anak nga babaye nga masalaypon? kay si Jehova nagbuhat ug bag-ong butang sa yuta: Usa ka babaye magalimis sa sulod niya sa usa ka lalake.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
Mao kini ang giingon ni Jehova sa mga panon, ang Dios sa Israel: Apan sila managgamit sa pag-usab niining pulonga sa yuta sa Juda ug sa mga ciudad didto, sa diha nga moapabalik ako kanila gikan sa ilang pagkabinihag: Si Jehova magapanalangin kanimo, Oh puloy-anan sa pagkamatarung, Oh bukid sa pagkabalaan.
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
Ug didto magapuyo sa tingub ang Juda ug ang tanang mga ciudad didto, ang mga magbabaul, ug kadtong managsuroysuroy uban sa mga panon.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
Kay gitagbaw ko ang kalag nga gilaayan, ug akong gibusog ang tagsatagsa ka kalag nga masulob-on.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Dinhi niini ako nahigmata, ug nakakita; ug ang akong pagkatulog matam-is man kanako.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Ania karon, ang mga adlaw moabut na, nagaingon si Jehova, aron ako magasabod sa balay sa Israel ug sa balay sa Juda sa binhi sa tawo, ug sa binhi sa mananap.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
Ug mahitabo nga, maingon nga ako nagbantay kanila sa pagluka ug sa pagdaug ug sa paglumpag ug sa paglaglag ug sa pagsakit, mao usab pagabantayan ko sila, sa pagtukod ug sa pagtanum kanila, nagaingon si Jehova.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
Niadtong mga adlawa sila dili na mag-ingon pag-usab: Ang mga amahan nakakaon ug maaslom nga parras, ug ang mga ngipon sa mga anak may kangilo.
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
Apan ang tagsatagsa kanila mamatay tungod sa iyang kaugalingong kasal-anan: ang tagsatagsa ka tawo nga makakaon sa maaslom nga parras, mao ang may kangilo sa iyang mga ngipon.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Ania karon, ang mga adlaw moabut na, nagaingon si Jehova, nga ako magabuhat ug usa ka bag-ong tugon uban sa balay sa Israel, ug uban sa balay sa Juda:
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
Dili sama sa tugon nga gibuhat ko uban sa ilang mga amahan sa adlaw nga giagak ko sila sa kamot sa pagpagula kanila gikan sa yuta sa Egipto; nga ang maong tugon ilang gilapas, bisan ako mao ang ilang bana, nagaingon si Jehova.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
Apan kini mao ang tugon nga pagabuhaton ko uban sa balay sa Israel sa tapus niadtong mga adlawa, nagaingon si Jehova: Ibutang ko ang akong Kasugoan sa ilang sulod nga mga bahin, ug diha sa ilang kasingkasing kini isulat ko; ug ako mahimong ilang Dios, ug sila mahimong akong katawohan.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
Ug sila dili na gayud magtudlo ang tagsatagsa ka tawo sa iyang isigkatawo ug ang tagsatagsa ka tawo sa iyang igsoon, sa pag-ingon: Ilhon mo si Jehova: kay silang tanan managpakaila kanako, gikan sa labing diyutay kanila ngadto sa labing daku kanila, nagaingon si Jehova: kay pasayloon ko ang ilang kasal-anan, ug dili na gayud hinumduman ko ang ilang sala.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Mao kini ang giingon ni Jehova, nga nagahatag sa adlaw sa paghatag kahayag sa adlaw, ug sa mga tulomanon sa bulan ug sa mga bitoon alang sa paghatag sa kahayag sa kagabhion, nga nagakutaw sa dagat, sa pagkaagi nga ang mga balud niini managdaguok; si Jehova sa mga panon mao ang iyang ngalan.
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
Kong kini nga mga tulomanon mahamulag gikan sa akong atubangan, nagaingon si Jehova, nan ang kaliwatan sa Israel mohunong sa pagkahimong nasud sa akong atubangan sa walay katapusan.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Mao kini ang giingon ni Jehova: Kong ang langit sa kahitas-an masukod, ug ang mga patukoranan sa yuta masusi sa kinahiladman, nan isalikway ko usab ang tibook kaliwatan sa Israel tungod sa tanan nilang nabuhat, nagaingon si Jehova.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Ania karon, ang mga adlaw moabut na, nagaingon si Jehova, nga ang ciudad pagatukoron alang kang Jehova gikan sa torre sa Hananeel ngadto sa ganghaan nga nasikohan.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
Ug ang igsulokod nga pisi moabut sa unahan ngadto sa ibabaw sa bungtod sa Gareb, ug moliko ngadto sa Goa.
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
Ug ang tibook nga walog sa mga minatay, ug sa mga abo, ug ang tanang mga uma ngadto sa sapa-sapa sa Cedron, ngadto sa nasikohan sa ganghaan sa kabayo paingon ngadto sa silangan, mahimong balaan alang kang Jehova; kini dili pagalukahon, ni pagalaglagon pag-usab sa walay katapusan.

< Jeremiah 31 >