< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Pǝrwǝrdigardin Yǝrǝmiyaƣa kǝlgǝn sɵz: —
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn sanga ⱨazir dǝydiƣan muxu barliⱪ sɵzlirimni yazmiƣa yazƣin;
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Qünki mana, xundaⱪ künlǝr keliduki, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — Mǝn hǝlⱪim Israil ⱨǝm Yǝⱨudani sürgünlüktin ⱪayturup ǝsligǝ kǝltürimǝn, ularni ata-bowiliriƣa tǝⱪdim ⱪilƣan zeminƣa ⱪayturimǝn, ular uningƣa igǝ bolidu.
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Pǝrwǝrdigarning Israil toƣruluⱪ wǝ Yǝⱨuda toƣruluⱪ degǝn sɵzliri tɵwǝndikidǝk: —
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
Qünki Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Anglitilidu alaⱪzadilik ⱨǝm ⱪorⱪunqluⱪning awazi, Bolsun nǝdǝ aman-tinqliⱪ!
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Soranglar, xuni kɵrüp beⱪinglarki, ǝr bala tuƣamdu? Mǝn nemixⱪa ǝmdi tolƣaⱪⱪa qüxkǝn ayaldǝk ⱨǝrbir ǝr kixining qatiriⱪini ⱪoli bilǝn tutⱪanliⱪini kɵrimǝn? Nemixⱪa yüzliri tatirip kǝtkǝndu?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Ayⱨay, xu küni dǝⱨxǝtliktur! Uningƣa ⱨeqⱪandaⱪ kün ohximaydu; u Yaⱪupning azab-oⱪubǝt künidur; lekin u uningdin ⱪutⱪuzulidu.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
Xu künidǝ ǝmǝlgǝ axuruliduki, — dǝydu samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar, — Mǝn uning boyunturuⱪini boynungdin elip sunduruwetimǝn, asarǝtliringni buzup taxlaymǝn, yat adǝmlǝr uni ikkinqi ⱪulluⱪⱪa qüxürmǝydu.
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
Xuning ornida ular Pǝrwǝrdigar Hudasining ⱨǝmdǝ Mǝn ular üqün ⱪaytidin tiklǝydiƣan Dawut padixaⱨining ⱪulluⱪida bolidu.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
Əmdi sǝn, i ⱪulum Yaⱪup, ⱪorⱪma, — dǝydu Pǝrwǝrdigar; — alaⱪzadǝ bolma, i Israil; qünki mana, Mǝn seni yiraⱪ yǝrlǝrdin, sening nǝslingni sürgün bolƣan zemindin ⱪutⱪuzimǝn; Yaⱪup ⱪaytip kelidu, aram tepip azadǝ turidu wǝ ⱨeqkim uni ⱪorⱪutmaydu.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Qünki Mǝn seni ⱪutⱪuzux üqün sǝn bilǝn billidurmǝn, — dǝydu Pǝrwǝrdigar; — Mǝn seni tarⱪitiwǝtkǝn ǝllǝrning ⱨǝmmisini tügǝxtürsǝmmu, lekin seni pütünlǝy tügǝxtürmǝymǝn; pǝⱪǝt üstüngdin ⱨɵküm qiⱪirip tǝrbiyǝ-sawaⱪ berimǝn; seni jazalimay ⱪoyup ⱪoymaymǝn.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Qünki Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: Sening zedǝng dawaliƣusiz, sening yarang bolsa intayin eƣirdur.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Sening dǝwayingni soraydiƣan ⱨeqkim yoⱪ, yarangni tangƣuqi yoⱪtur, sanga xipaliⱪ dorilar yoⱪtur;
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
sening barliⱪ axniliring seni untuƣan; ular sening ⱨalingni ⱨeq sorimaydu. Qünki Mǝn seni düxmǝndǝk zǝrb bilǝn urƣanmǝn, rǝⱨimsiz bir zalimdǝk sanga sawaⱪ bolsun dǝp urƣanmǝn; qünki sening ⱪǝbiⱨliking ⱨǝddi-ⱨesabsiz, gunaⱨliring ⱨǝddidin ziyadǝ bolƣan.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Nemixⱪa zedǝng tüpǝylidin, dǝrd-ǝliming dawaliƣusiz bolƣanliⱪi tüpǝylidin pǝryad kɵtürisǝn? Ⱪǝbiⱨlikingning ⱨǝddi-ⱨesabsiz bolƣanliⱪidin, gunaⱨliring ⱨǝddidin ziyadǝ bolƣanliⱪidin, Mǝn xularni sanga ⱪilƣanmǝn.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
Lekin seni yutuwalƣanlarning ⱨǝmmisi yutuwelinidu; sening barliⱪ küxǝndiliring bolsa sürgün bolidu; seni buliƣanlarning ⱨǝmmisi bulang-talang ⱪilinidu; seni ow ⱪilƣanlarning ⱨǝmmisini owlinidiƣan ⱪilimǝn.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Qünki Mǝn sanga tengiⱪ tengip ⱪoyimǝn wǝ yariliringni saⱪaytimǝn — dǝydu Pǝrwǝrdigar; — qünki ular seni: «Ƣerib-biqarǝ, ⱨeqkim ⱨalini sorimaydiƣan Zion dǝl muxudur» dǝp ⱨaⱪarǝtligǝn.
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn Yaⱪupning qedirlirini sürgünlüktin ⱪayturup ǝsligǝ kǝltürimǝn, Uning turalƣuliri üstigǝ rǝⱨim ⱪilimǝn; Xǝⱨǝr harabiliri ul ⱪilinip ⱪaytidin ⱪurulidu, Orda-ⱪǝl’ǝ ɵz jayida yǝnǝ adǝmzatliⱪ bolidu.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Xu jaylardin tǝxǝkkür küyliri wǝ xad-huramliⱪ sadaliri anglinidu; Mǝn ularni kɵpǝytimǝnki, ular ǝmdi azaymaydu; Mǝn ularning ⱨɵrmitini axurimǝn, ular ⱨeq pǝs bolmaydu.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Ularning baliliri ⱪǝdimdikidǝk bolidu; ularning jamaiti aldimda mǝzmut turƣuzulidu; Ularni horliƣanlarning ⱨǝmmisini jazalaymǝn.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Ularning bexi ɵzliridin bolidu, Ularning ⱨɵküm sürgüqisi ɵzliri otturisidin qiⱪidu; Mǝn uni ɵz yenimƣa kǝltürimǝn, xuning bilǝn u Manga yeⱪin kelidu; Qünki yenimƣa kǝlgüqi [jenini] tǝwǝkkül ⱪilƣuqi ǝmǝsmu? — dǝydu Pǝrwǝrdigar.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
— Xuning bilǝn silǝr Mening hǝlⱪim bolisilǝr, Mǝn silǝrning Hudayinglar bolimǝn.
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Mana, Pǝrwǝrdigardin qiⱪⱪan bir boran-qapⱪun! Uningdin ⱪǝⱨr qiⱪti; Bǝrⱨǝⱪ, dǝⱨxǝtlik bir ⱪara ⱪuyun qiⱪip kǝldi; U pirⱪirap rǝzillǝrning bexiƣa qüxidu.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
Kɵnglidiki niyǝtlirini ada ⱪilip toluⱪ ǝmǝl ⱪilƣuqǝ, Pǝrwǝrdigarning ⱪattiⱪ ƣǝzipi yanmaydu; Ahirⱪi künlǝrdǝ silǝr buni qüxinip yetisilǝr.

< Jeremiah 30 >