< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Perwerdigardin Yeremiyagha kelgen söz: —
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
Israilning Xudasi Perwerdigar mundaq deydu: — Men sanga hazir deydighan mushu barliq sözlirimni yazmigha yazghin;
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Chünki mana, shundaq künler kéliduki, — deydu Perwerdigar, — Men xelqim Israil hem Yehudani sürgünlüktin qayturup eslige keltürimen, ularni ata-bowilirigha teqdim qilghan zémin’gha qayturimen, ular uninggha ige bolidu.
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Perwerdigarning Israil toghruluq we Yehuda toghruluq dégen sözliri töwendikidek: —
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
Chünki Perwerdigar mundaq deydu: — Anglitilidu alaqzadilik hem qorqunchluqning awazi, Bolsun nede aman-tinchliq!
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Soranglar, shuni körüp béqinglarki, er bala tughamdu? Men némishqa emdi tolghaqqa chüshken ayaldek herbir er kishining chatiriqini qoli bilen tutqanliqini körimen? Némishqa yüzliri tatirip ketkendu?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Ayhay, shu küni dehshetliktur! Uninggha héchqandaq kün oxshimaydu; u Yaqupning azab-oqubet künidur; lékin u uningdin qutquzulidu.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
Shu künide emelge ashuruliduki, — deydu samawi qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar, — Men uning boyunturuqini boynungdin élip sunduruwétimen, asaretliringni buzup tashlaymen, yat ademler uni ikkinchi qulluqqa chüshürmeydu.
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
Shuning ornida ular Perwerdigar Xudasining hemde Men ular üchün qaytidin tikleydighan Dawut padishahining qulluqida bolidu.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
Emdi sen, i qulum Yaqup, qorqma, — deydu Perwerdigar; — alaqzade bolma, i Israil; chünki mana, Men séni yiraq yerlerdin, séning neslingni sürgün bolghan zémindin qutquzimen; Yaqup qaytip kélidu, aram tépip azade turidu we héchkim uni qorqutmaydu.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Chünki Men séni qutquzush üchün sen bilen billidurmen, — deydu Perwerdigar; — Men séni tarqitiwetken ellerning hemmisini tügeshtürsemmu, lékin séni pütünley tügeshtürmeymen; peqet üstüngdin höküm chiqirip terbiye-sawaq bérimen; séni jazalimay qoyup qoymaymen.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Chünki Perwerdigar mundaq deydu: Séning zédeng dawalighusiz, séning yarang bolsa intayin éghirdur.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Séning dewayingni soraydighan héchkim yoq, yarangni tangghuchi yoqtur, sanga shipaliq dorilar yoqtur;
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
séning barliq ashniliring séni untughan; ular séning halingni héch sorimaydu. Chünki Men séni düshmendek zerb bilen urghanmen, rehimsiz bir zalimdek sanga sawaq bolsun dep urghanmen; chünki séning qebihliking heddi-hésabsiz, gunahliring heddidin ziyade bolghan.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Némishqa zédeng tüpeylidin, derd-eliming dawalighusiz bolghanliqi tüpeylidin peryad kötürisen? Qebihlikingning heddi-hésabsiz bolghanliqidin, gunahliring heddidin ziyade bolghanliqidin, Men shularni sanga qilghanmen.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
Lékin séni yutuwalghanlarning hemmisi yutuwélinidu; séning barliq küshendiliring bolsa sürgün bolidu; séni bulighanlarning hemmisi bulang-talang qilinidu; séni ow qilghanlarning hemmisini owlinidighan qilimen.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Chünki Men sanga téngiq téngip qoyimen we yariliringni saqaytimen — deydu Perwerdigar; — chünki ular séni: «Ghérib-bichare, héchkim halini sorimaydighan Zion del mushudur» dep haqaretligen.
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Perwerdigar mundaq deydu: — Mana, Men Yaqupning chédirlirini sürgünlüktin qayturup eslige keltürimen, Uning turalghuliri üstige rehim qilimen; Sheher xarabiliri ul qilinip qaytidin qurulidu, Orda-qel’e öz jayida yene ademzatliq bolidu.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Shu jaylardin teshekkür küyliri we shad-xuramliq sadaliri anglinidu; Men ularni köpeytimenki, ular emdi azaymaydu; Men ularning hörmitini ashurimen, ular héch pes bolmaydu.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Ularning baliliri qedimdikidek bolidu; ularning jamaiti aldimda mezmut turghuzulidu; Ularni xorlighanlarning hemmisini jazalaymen.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Ularning béshi özliridin bolidu, Ularning höküm sürgüchisi özliri otturisidin chiqidu; Men uni öz yénimgha keltürimen, shuning bilen u Manga yéqin kélidu; Chünki yénimgha kelgüchi [jénini] tewekkül qilghuchi emesmu? — deydu Perwerdigar.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
— Shuning bilen siler Méning xelqim bolisiler, Men silerning Xudayinglar bolimen.
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Mana, Perwerdigardin chiqqan bir boran-chapqun! Uningdin qehr chiqti; Berheq, dehshetlik bir qara quyun chiqip keldi; U pirqirap rezillerning béshigha chüshidu.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
Könglidiki niyetlirini ada qilip toluq emel qilghuche, Perwerdigarning qattiq ghezipi yanmaydu; Axirqi künlerde siler buni chüshinip yétisiler.

< Jeremiah 30 >