< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Detta är det ord som kom till Jeremia från HERREN; han sade:
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
Så säger HERREN, Israels Gud: Teckna upp åt dig i en bok alla de ord som jag har talat till dig.
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Ty se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag åter skall upprätta mitt folk, Israel och Juda, säger HERREN, och låta dem komma tillbaka till det land som jag har givit åt deras fäder; och de skola taga det i besittning.
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Och detta är vad HERREN har talat om Israel och Juda.
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
Så säger HERREN: Ett förfärans rop fingo vi höra; förskräckelse utan någon räddning!
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Frågen efter och sen till: pläga då män föda barn? Eller varför ser jag alla män hålla sina händer på länderna såsom kvinnor i barnsnöd, och varför hava alla ansikten blivit så dödsbleka?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Ve! Detta är en stor dag, en sådan att ingen är den lik. Ja, en tid av nöd är inne för Jakob; dock skall han bliva frälst därur.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
Och det skall ske på den tiden, Säger HERREN Sebaot, att jag skall bryta sönder oket och taga det från din hals och slita av dina band. Ja, inga främmande skola längre tvinga honom att tjäna sig,
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
utan han skall få tjäna HERREN, sin Gud, och David, sin konung, ty honom skall jag låta uppstå åt dem.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
Så frukta nu icke, du min tjänare Jakob, säger HERREN. och var ej förfärad du Israel; ty se, jag skall frälsa dig ur det avlägsna landet, och dina barn ur deras fångenskaps land. Och Jakob skall få komma tillbaka och leva i ro och säkerhet, och ingen skall förskräcka honom.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Ty jag är med dig, säger HERREN, till att frälsa dig. Ja, jag skall göra ände på alla de folk; bland vilka jag har förstrött dig; men på dig vill jag icke alldeles göra ände, jag vill blott tukta dig med måtta; ty alldeles ostraffad kan jag ju ej låta dig bliva.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Ty så säger HERREN: Ohelbar är din skada, oläkligt det sår du har fått.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Ingen tager sig an din sak, så att han sköter ditt sår; ingen helande läkedom finnes för dig.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
Alla dina älskare hava förgätit dig; de fråga icke efter dig. Ty såsom man slår en fiende, så har jag slagit dig, med grym tuktan, därför att din missgärning var så stor och dina synder så många.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Huru kan du klaga över din skada, över att bot ej finnes för din plåga? Därför att din missgärning var så stor och dina synder så många, har jag gjort dig detta.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
Så skola då alla dina uppätare nu bliva uppätna, och alla dina ovänner skola allasammans gå i fångenskap; dina skövlare skola varda skövlade, och alla dina plundrare skall jag lämna till plundring.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Ty jag vill hela dina sår och läka dig från de slag du har fått, säger HERREN, då man nu kallar dig »den fördrivna», »det Sion som ingen frågar efter».
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Så säger HERREN: Se, jag skall åter upprätta Jakobs hyddor och förbarma mig över hans boningar; staden skall åter bliva uppbyggd på sin höjd, och palatset skall stå på sin rätta plats.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Ifrån folket skall ljuda tacksägelse och rop av glada människor. Jag skall föröka dem, och de skola icke förminskas; jag skall låta dem komma till ära, och de skola ej aktas ringa.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Hans söner skola varda såsom fordom, hans menighet skall bestå inför mig, jag skall hemsöka alla hans förtryckare.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Hans väldige skall stamma från honom själv, och hans herre skall utgå från honom själv, och honom skall jag låta komma mig nära och nalkas mig; ty vilken annan vill våga sitt liv med att nalkas mig? säger HERREN.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
Och I skolen vara mitt folk och jag skall vara eder Gud.
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Se, en stormvind från HERREN är här, hans förtörnelse bryter fram, en härjande storm! Över de ogudaktigas huvuden virvlar den ned.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
HERRENS vredes glöd skall icke upphöra, förrän han har utfört och fullbordat sitt hjärtas tankar; i kommande dagar skolen I förnimma det.

< Jeremiah 30 >