< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Kastoy ti sao ni Yahweh nga immay kenni Jeremias, kinunana,
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
“Kastoy ti pakaammo ni Yahweh a Dios ti Israel, 'Isuratmo iti maysa a nalukot a pagsuratan ti amin a sao nga imbagak kenka.
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Ta denggem, umadanin dagiti al-aldaw—kastoy ti pakaammo ni Yahweh—inton isublikto ti sigud a nasayaat a kasasaad dagiti tattaok nga Israel ken Juda. Siak a ni Yahweh, ti nangibaga iti daytoy. Ta isublikto ida iti daga nga intedko kadagiti kapuonanda, ket tagikuaendanto daytoy.'''
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Dagitoy dagiti sasao nga impakaammo ni Yahweh maipapan iti Israel ken Juda,
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
“Ta kastoy ti kuna ni Yahweh, “Adda nangngegmi a timek nga agpigpigerger gapu iti buteng saan ket a timek gapu iti talna.
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Agsaludsoddkayo ken ammoenyo no makapagpasngay ngata ti maysa a lalaki. Apay ngarud a makitkitak ti tunggal agtutubo a lallaki nga ap-aprusanna ti pus-ongna? Kasla da la babai nga agpaspasikal, apay a pimmusyapusyaw amin dagiti rupada?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Asida pay! Ta daytanto nga aldaw ket agbalinto a naidumduma, nga awan ti kaaspingna. Daytoy ket tiemponto ti pannakariribuk ni Jacob, ngem maispalto isuna manipud iti daytoy.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
Ta iti daytanto nga aldaw—kastoy ti pakaammo ni Yahweh a Mannakabalin-amin—a tukkulekto dagiti sangol iti tenggedyo, ken pugsatekto dagiti kawaryo, isu a saandakayto a tagabuen pay dagiti gangannaet.
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
Ngem dayawendanto ni Yahweh a Diosda ken pagserbianda ni David nga arida, a pagbalinekto nga ari a mangituray kadakuada.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
Isu a sika, Jacob nga adipenko, saanka nga agbuteng—kastoy ti pakaammo ni Yahweh—ken saanka a maupay, Israel. Ta kitaem, umadanin ti panangisublik kenka manipud iti adayo, ken dagiti kaputotam manipud iti daga a nakaipananda a kas balud. Agsublinto ni Jacob ket addaanto isuna iti kapia; natalgedto isuna ket awanto a pulos ti pakaigapuan iti panagbuteng.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Ta addaak kadakayo—kastoy ti pakaammo ni Yahweh— tapno isalakankayo. Ket iyegkonto ti naan-anay a panagpatingga kadagiti amin a nasion a nangiwarawaraak kadakayo. Ngem siguradoek a saankayto a gibusan, uray no aturenkayo iti nainkalintegan ken saanko nga itulok a saankayo a madusa.'
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Ta kastoy ti kuna ni Yahweh, “Saan a maagasan ti dunoryo; nagimpeksiyon dagiti sugatyo.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Awan ti siasinoman a mangipakaasi iti kasasaadyo, awan iti pamuspusan tapno agimbag dagiti sugatyo.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
Amin dagiti kaayan-ayatyo ket nalipatan dakayo. Saandakayto a pagan-ano, ta sinugatkayo iti kas iti sugat ti maysa a kabusor ken kas iti panangatur ti maysa a naranggas nga apo gapu kadagiti adu a nakaro a kinadakesyo ken saan a mabilang a basbasolyo.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Apay pay laeng a dumawatkayo iti tulong para iti dunoryo? Saan a maimbagan ti ut-ot a laklak-amenyo. Gapu kadagiti adu a nakaro a kinadakesyo ken kadagiti saan a mabilang a basbasolyo, inaramidko kadakayo dagitoy a banbanag.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
Isu nga amin a mangdadael kadakayo ket madadaelto met, ken amin dagiti kabusoryo ket maipanawto a kas balud. Ta dagiti nagtakaw kadakayo ket matakawanto met, ken amin dagiti nangsamsam kenka ket masamsamto.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Ta iyegkonto kadakayo ti pannakapaimbagyo; paimbagekto dagiti sugatyo—kastoy ti pakaammo ni Yahweh—aramidekto daytoy ta inawagan dakayo a: Napagtalaw. Awan ti siasinoman a mangisakit iti daytoy a Sion.”'
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Kastoy ti kuna ni Yahweh, “Dumngegkayo, umadanin ti panangisublik kadagiti sigud a nasayaat a kasasaad dagiti tolda ni Jacob ken kaasiakto dagiti pagtaenganna. Ket maibangonto ti maysa a siudad kadagiti gabsuon dagiti nadadael, ken maibangonto manen ti sarikedkedda iti sigud a nakaisaadanna.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Ket addanto iti kanta ti panagdaydayaw ken panagragrag-o nga agtaud kadakuada; ta paaduekto ida a saan ket a kissayan; padayawakto ida isu a saandanto a maibaba.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Ket agbalinto a kas iti sigud dagiti tattaoda, ken mabukelto ti taripnongda iti imatangko inton dusaek amin dagiti mangidaddadanes ita kadakuada.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Agtaudto kadakuada ti panguloda. Agapunto isuna iti nagtetengngaanda inton ayabak isuna ket umasideg kaniak. No saanko nga aramiden daytoy, adda kadi met ngarud iti makaitured nga umasideg kaniak? —kastoy ti pakaammo ni Yahweh.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
Ket agbalinkayonto a tattaok, ken siakto ti Diosyo.
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Kitaenyo, ti pungtot ni Yahweh a maiyarig iti nadawel a bagio ket bimtaken. Saan nga agsardeng daytoy a nadawel a bagio. Agtayyekto daytoy iti ulo dagiti nadadangkes a tattao.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
Saanto nga agsardeng ti pungtot ni Yahweh agingga a maaramidna ken maipatungpalna dagiti panggep ti pusona. Kadagiti maudi nga al-aldaw, maawatanyonto dagitoy.”

< Jeremiah 30 >