< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Ĩno nĩyo ndũmĩrĩri ĩrĩa yakinyĩrĩire Jeremia yumĩte kũrĩ Jehova:
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
“Jehova, Ngai wa Isiraeli, ekuuga atĩrĩ: ‘Andĩka ũhoro ũrĩa wothe ngwarĩirie ibuku-inĩ.’
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Tondũ Jehova ekuuga atĩrĩ, ‘Matukũ nĩmarooka, rĩrĩa ngaarehe andũ akwa a Isiraeli na a Juda moime kũrĩa maatwarirwo maatahwo na ndĩmacookie bũrũri ũrĩa ndaheire maithe mao mawĩgwatĩre,’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga.”
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Ũyũ nĩguo ũhoro ũrĩa Jehova aaririe ũkoniĩ Isiraeli na Juda:
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
“Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Nĩtũiguĩte mũkayũrũrũko wa kũmakania, wa itua-nda, no ti wa thayũ.
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Ta tuĩriai ũhoro, muone: Hihi mũndũ mũrũme no ahote gũciara mwana? Nĩ kĩĩ kĩragĩtũma nyone arũme othe arĩa marĩ hinya menyiitĩte nda ta mũtumia ũkũrũmwo, na o mũndũ akagarũrũka agatukia gĩthiithi?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Kaĩ mũthenya ũcio nĩũgakorwo ũrĩ mũrũrũ-ĩ! Gũtirĩ ũngĩ ũkahaana taguo. Gũgaakorwo kũrĩ ihinda rĩa kũnyariirĩka rĩa Jakubu, no nĩakahonokio kuuma harĩ guo.’
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
“Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ, ‘Mũthenya ũcio nĩngoinanga icooki rĩu ndĩrĩeherie ngingo-inĩ ciao, na nduuange nga iria mohetwo nacio; nacio ndũrĩrĩ itigacooka kũmatua ngombo ciao rĩngĩ.
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
Handũ ha ũguo, magaatungatagĩra Jehova Ngai wao, na Daudi mũthamaki wao, ũrĩa niĩ ngaamarahũrĩra.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
“‘Nĩ ũndũ ũcio tiga gwĩtigĩra, wee Jakubu ndungata yakwa; tiga kũmaka, wee Isiraeli,’ nĩguo Jehova ekuuga. ‘Ti-itherũ nĩngakũhonokia ngũrute kũu kũraya, na njiaro ciaku ndĩcirute bũrũri ũrĩa maathaamĩirio. Jakubu nĩagacookererwo nĩ thayũ o na ũgitĩri, na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe ũgaatũma etigĩre.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Ndĩ hamwe nawe na nĩngakũhonokia,’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga. ‘O na ingĩniina ndũrĩrĩ ciothe cia kũrĩa guothe ngũharaganĩirie, wee ndigakũniina biũ. No nĩngakũherithia na kĩhooto; ndikaareka ũthiĩ o ro ũguo itakũherithĩtie.’
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
“Nĩ ũndũ Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Kĩronda gĩaku gĩtingĩhona, nguraro ciaku itirĩ kĩhonia.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Hatirĩ na wa gũgũthaithanĩrĩra, kana ndawa ya kĩronda gĩaku, o na kana gĩa gũkũhonia.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
Athiritũ aku othe nĩmariganĩirwo nĩwe; ndũrĩ kĩene harĩo. Ngũgũthĩte o ta ũrĩa thũ ĩngĩkũgũtha, na ngaakũherithia o ta ũrĩa mũndũ ũtarĩ tha aherithanagia, nĩ ũndũ mahĩtia maku nĩ manene mũno, namo mehia maku makaingĩha makĩria.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Nĩ kĩĩ kĩratũma ũrĩrĩre kĩronda gĩaku, ũkarĩrĩra ruo rwaku rũtarĩ na kĩhonia? Nĩ ũndũ wa ũrĩa mahĩtia maku manenehete na mehia maku magakĩingĩha rĩ, nĩkĩo ngwĩkĩte maũndũ macio.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
“‘No rĩrĩ, andũ arĩa othe magaakũngʼaũrania o nao nĩmakangʼaũranio; thũ ciaku ciothe nĩigatwarwo ithaamĩrio. Arĩa magũtahaga indo ciaku nĩmagatahwo; arĩa othe magũtunyaga indo na niĩ nĩngamatunya.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
No nĩngagũcookeria ũgima waku, na ngũhonie nguraro ciaku,’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga, ‘tondũ wĩtagwo mũndũ mũte, Zayuni itũũra rĩtarĩ mũndũ ũrĩrũmbũyagia.’
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
“Ũũ nĩguo Jehova ekuuga: “‘Nĩngacookia ũgaacĩru wa Jakubu hema-inĩ ciake, nacio ciikaro ciake ndĩciiguĩre tha; itũũra rĩu inene nĩrĩgaakwo rĩngĩ o kũu rĩanangĩirwo, nayo nyũmba ya ũthamaki nĩĩkarũgama harĩa hamĩagĩrĩire.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Kuuma kũu nĩgũkaiguuagwo gũkĩinĩrwo nyĩmbo cia gũcookia ngaatho, na kũiguuagwo mĩgambo ya gĩkeno. Nĩngamaingĩhia na matikanyihanyiiha; nĩngamaheithia gĩtĩĩo, na matikaagithio kĩene.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Ciana ciao igaikaraga o ta matukũ-inĩ marĩa ma tene, nakĩo kĩrĩndĩ kĩao gĩtũũre kĩrũmĩte wega mbere yakwa; nĩngaherithia arĩa othe mamahinyagĩrĩria.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Mũtongoria wao agaakorwo arĩ ũmwe wa andũ ao kĩũmbe; o nake mwathi wao akoima o kũu thĩinĩ wa andũ ao. Nĩngamũreharehe nake oke hakuhĩ na niĩ, nĩ ũndũ-rĩ, nĩ mũndũ ũrĩkũ ũngĩĩrutĩra gũũka hakuhĩ na niĩ?’ ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
‘Nĩ ũndũ ũcio nĩmũgatuĩka andũ akwa, na niĩ nduĩke Ngai wanyu.’”
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Atĩrĩrĩ, mangʼũrĩ ma Jehova nĩmagatuthũka mahaana ta kĩhuhũkanio; ti-itherũ makaahaana ta rũhuho rũkũhurutana mũno, igũrũ rĩa andũ arĩa aaganu.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
Marakara mahiũ ma Jehova matigaathira, o nginya rĩrĩa akaahingia muoroto wa ngoro yake biũ. Matukũ-inĩ marĩa magooka-rĩ, nĩmũgataũkĩrwo nĩ ũhoro ũcio wega.

< Jeremiah 30 >