< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
La parole qui fut adressée à Jérémie de la part de Yahvé, en ces mots:
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
Yahvé, le Dieu d'Israël, dit: Écris dans un livre toutes les paroles que je t'ai dites.
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Car voici, les jours viennent, dit Yahvé, où je rétablirai la captivité de mon peuple d'Israël et de Juda, dit Yahvé. Je les ferai retourner dans le pays que j'ai donné à leurs pères, et ils le posséderont. »
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Telles sont les paroles que l'Éternel a prononcées sur Israël et sur Juda.
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
Car Yahvé dit: « Nous avons entendu une voix tremblante; une voix de peur, et non de paix.
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Interrogez maintenant, et voyez si un homme est en train d'accoucher. Pourquoi je vois chaque homme avec les mains sur la taille, comme une femme en travail, et tous les visages sont devenus pâles?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Hélas, car ce jour est grand, si bien qu'il n'y en a pas de semblable! C'est même le temps des problèmes de Jacob; mais il en sera sauvé.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
En ce jour-là, dit l'Éternel des armées, je briserai son joug de dessus votre cou, et brisera vos liens. Les étrangers n'en feront plus leurs esclaves;
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
mais ils serviront Yahvé, leur Dieu, et David leur roi, que je leur susciterai.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
C'est pourquoi n'aie pas peur, Jacob, mon serviteur, dit Yahvé. Ne sois pas consterné, Israël. Car voici, je vous sauverai de loin, et sauve ta progéniture du pays de leur captivité. Jacob reviendra, et sera tranquille et à l'aise. Personne ne lui fera peur.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Car je suis avec vous, dit Yahvé, pour vous sauver; car je ferai disparaître toutes les nations où je vous ai dispersés, mais je n'en finirai pas avec vous; mais je vais vous corriger sur mesure, et ne vous laissera en aucun cas impuni. »
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Car Yahvé dit, « Votre blessure est incurable. Votre blessure est grave.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Il n'y a personne pour plaider ta cause, pour que vous soyez liés. Vous n'avez pas de médicaments de guérison.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
Tous tes amants t'ont oubliée. Ils ne vous cherchent pas. Car je t'ai blessé avec la blessure d'un ennemi, avec le châtiment d'un cruel, pour la grandeur de ton iniquité, parce que vos péchés ont augmenté.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Pourquoi pleurez-vous sur votre blessure? Votre douleur est incurable. Pour la grandeur de votre iniquité, parce que vos péchés ont augmenté, Je vous ai fait ces choses.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
C'est pourquoi tous ceux qui vous dévorent seront dévorés. Tous tes adversaires, chacun d'eux, iront en captivité. Ceux qui vous pillent seront pillés. Je ferai en sorte que tous ceux qui s'en prennent à vous deviennent des proies.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Car je vous rendrai la santé, et je te guérirai de tes blessures, dit Yahvé, « parce qu'ils t'ont traité de paria, en disant: « C'est Sion, que personne ne cherche. »
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Yahvé dit: « Voici, je vais renverser la captivité des tentes de Jacob, et ayez de la compassion pour ses demeures. La ville sera construite sur sa propre colline, et le palais sera habité à sa place.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
L'action de grâce sortira d'eux avec la voix de ceux qui font la fête. Je les multiplierai, et ils ne seront pas peu nombreux; Je vais aussi les glorifier, et ils ne seront pas petits.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Leurs enfants aussi seront comme avant, et leur congrégation sera établie devant moi. Je punirai tous ceux qui les oppriment.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Leur prince sera l'un d'entre eux, et leur chef sortira du milieu d'eux. Je le ferai s'approcher, et il s'approchera de moi; car qui est celui qui a eu l'audace de s'approcher de moi? dit Yahvé.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
« Vous serez mon peuple, et je serai votre Dieu.
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Voici que l'orage de Yahvé, sa colère, a éclaté, une tempête qui balaie tout; elle éclatera sur la tête des méchants.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
L'ardente colère de Yahvé ne reviendra pas avant qu'il ait accompli, et jusqu'à ce qu'il ait accompli les intentions de son cœur. Dans les derniers jours, vous le comprendrez. »

< Jeremiah 30 >