< Jeremiah 30 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
Sana, joka tuli Herralta Jeremialle ja kuului näin:
2 “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
"Näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Kirjoita kaikki sanat, jotka minä olen sinulle puhunut, kirjaan.
3 Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
Sillä katso, tulee aika, sanoo Herra, jolloin minä käännän kansani Israelin ja Juudan kohtalon, sanoo Herra, ja palautan heidät maahan, jonka olen antanut heidän isillensä, ja he saavat periä sen."
4 Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
Ja nämä ovat ne sanat, jotka Herra on puhunut Israelista ja Juudasta.
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
Näin sanoo Herra: "Pelon huudon me kuulemme: on hirmu, ei rauha!
6 Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
Kysykää ja katsokaa: synnyttääkö miehenpuoli? Miksi näen kaikkien miesten pitelevän käsin lanteitansa synnyttäväisten tavalla, ja miksi ovat kaikki kasvot käyneet valjuiksi?
7 Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
Voi! Suuri on se päivä, ei ole sen kaltaista. Se on Jaakobille ahdistuksen aika, mutta hän on pelastuva siitä.
8 “‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
Ja sinä päivänä, sanoo Herra Sebaot, minä särjen ikeen sinun kaulastasi ja katkaisen sinun siteesi. Eivät tee enää muukalaiset heitä palvelijoikseen,
9 Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
vaan he saavat palvella Herraa, Jumalaansa, ja Daavidia, kuningastansa, jonka minä heille herätän.
10 “‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
Mutta sinä, minun palvelijani Jaakob, älä pelkää, sanoo Herra, älä säiky, Israel. Sillä katso, minä pelastan sinut kaukaisesta maasta, sinun jälkeläisesi heidän vankeutensa maasta. Ja Jaakob on palajava, elävä rauhassa ja turvassa, kenenkään peljättämättä.
11 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
Sillä minä olen sinun kanssasi, sanoo Herra, ja pelastan sinut. Minä teen lopun kaikista kansoista, joiden sekaan minä olen sinut hajottanut; ainoastaan sinusta minä en loppua tee: minä kuritan sinua kohtuudella, mutta rankaisematta minä en sinua jätä.
12 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
Sillä näin sanoo Herra: Paha on sinun vammasi, kipeä on saamasi isku.
13 Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
Ei kukaan aja sinun asiaasi; sinun haavaasi ei paranneta, se ei kasva umpeen.
14 Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
Kaikki sinun rakastajasi ovat sinut unhottaneet, sinua he eivät kysy. Sillä niinkuin vihollista lyödään, olen minä sinua lyönyt, kovalla kurituksella, koska sinun rikoksesi on suuri, sinun syntisi monilukuiset.
15 Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
Miksi valitat vammaasi, kipusi kovuutta? Koska sinun rikoksesi on suuri, sinun syntisi monilukuiset, olen minä sinulle tämän tehnyt.
16 “‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
Niin myös kaikki sinun syöjäsi syödään, ja kaikki sinun ahdistajasi, kaikki tyynni, vaeltavat vankeuteen; sinun ryöstäjäsi joutuvat ryöstetyiksi, ja kaikki saalistajasi minä annan saaliiksi.
17 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
Sillä minä kasvatan umpeen sinun haavasi ja parannan sinut saamistasi iskuista, sanoo Herra, sinut, Siion, jolla on nimenä 'hyljätty', 'se, josta ei kukaan välitä'.
18 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
Näin sanoo Herra: Katso, minä käännän Jaakobin majojen kohtalon, minä armahdan hänen asuntojansa; kaupunki rakennetaan kukkulallensa, ja linna on oleva oikealla paikallansa.
19 Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
Ja niistä on kaikuva ylistyslaulu ja iloitsevaisten ääni. Minä enennän heidät, eivätkä he vähene; minä saatan heidät kunniaan, eivätkä he halvoiksi jää.
20 Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
Silloin hänen poikansa ovat niinkuin muinoin, ja hänen seurakuntansa pysyy vahvana minun edessäni; minä rankaisen kaikki hänen sortajansa.
21 Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
Ja hänen valtiaansa nousee hänestä itsestänsä, hänen hallitsijansa lähtee hänen keskeltänsä; ja minä sallin hänen käydä tyköni, niin että hän saattaa minua lähestyä. Sillä kuka panee henkensä alttiiksi minua lähestyäkseen? sanoo Herra.
22 ‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
Ja niin te olette minun kansani, ja minä olen teidän Jumalanne."
23 Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
Katso, Herran myrsky, kiivastus, puhkeaa, pyörremyrsky vyöryy kohti jumalattomien päätä.
24 Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.
Eikä Herran vihan hehku asetu, ennenkuin hän on toteuttanut ja täyttänyt sydämensä aivoitukset. Aikojen lopulla te tulette sen ymmärtämään.

< Jeremiah 30 >