< Jeremiah 3 >

1 “Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
Ei spun: Dacă un bărbat își lasă soția și ea pleacă de la el și devine a altui bărbat, se va întoarce el din nou la ea? Nu va fi țara aceea mult întinată? Dar tu ai făcut pe curva cu mulți apropiați; totuși întoarce-te la mine, spune DOMNUL.
2 “Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
Ridică-ți ochii spre înălțimi și vezi unde nu te-ai culcat cu cineva. Pe căi ai șezut pentru ei, precum arabul în pustie; și ai întinat țara cu curviile tale și cu stricăciunea ta.
3 Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
De aceea ploile au fost oprite și nu a fost ploaie târzie; și tu ai avut fruntea unei curve, ai refuzat să te rușinezi.
4 Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
Nu vrei de acum să strigi către mine: Tatăl meu, tu ești călăuza tinereții mele?
5 Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
Își va reține el mânia pentru totdeauna? O va ține el până la sfârșit? Iată, ai vorbit și ai făcut lucruri rele cât ai putut.
6 Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
DOMNUL mi-a spus de asemenea în zilele împăratului Iosia: Ai văzut ceea ce a făcut Israelul decăzut? S-a urcat pe fiecare munte înalt și sub fiecare copac verde și acolo a făcut pe curva.
7 Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
Și am spus după ce a făcut toate aceste lucruri: Întoarce-te la mine. Dar nu s-a întors. Și perfida ei soră, Iuda, a văzut aceasta.
8 Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
Și am văzut că, după ce pentru toate motivele prin care Israelul decăzut a comis adulter, am alungat-o și i-am dat un act de divorț; totuși perfida ei soră, Iuda, nu s-a temut, ci a mers și de asemenea a făcut pe curva.
9 Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
Și s-a întâmplat prin ușurința curviei ei, că a întinat țara și a comis adulter cu pietre și cu trunchiuri.
10 Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
Și cu toate acestea perfida ei soră, Iuda, nu s-a întors la mine cu toată inima ei, ci cu prefăcătorie, spune DOMNUL.
11 Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
Și DOMNUL mi-a spus: Israelul decăzut s-a declarat drept mai mult decât perfida lui soră, Iuda.
12 Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
Du-te și vestește aceste cuvinte spre nord și spune: Întoarce-te, tu Israele decăzut, spune DOMNUL; și nu voi face ca mânia mea să cadă peste voi, pentru că sunt milostiv, spune DOMNUL și nu voi ține mânie pentru totdeauna.
13 Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
Numai să îți recunoști nelegiuirea, că ai încălcat legea împotriva DOMNULUI Dumnezeului tău și ți-ai împrăștiat căile către străini sub fiecare copac verde, și voi nu ați ascultat de vocea mea, spune DOMNUL.
14 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
Întoarceți-vă, voi copii decăzuți, spune DOMNUL, pentru că sunt căsătorit cu voi; și vă voi lua pe unul dintr-o cetate și pe doi dintr-o familie și vă voi aduce în Sion;
15 Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
Și vă voi da păstori conform cu inima mea care vă vor paște cu înțelegere și cunoștință.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
Și se va întâmpla, când vă veți înmulți și veți crește în țară, în acele zile, spune DOMNUL, că ei nu vor mai spune: Chivotul legământului DOMNULUI; nici nu le va veni în minte, nici nu își vor aminti de el; nici nu îl vor cerceta; nici nu se va mai face aceasta.
17 Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
În acel timp ei vor numi Ierusalimul tronul DOMNULUI; și toate națiunile se vor aduna la el, pentru numele DOMNULUI, la Ierusalim; și nu vor mai umbla după închipuirea inimii lor rele.
18 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
În acele zile casa lui Iuda va umbla cu casa lui Israel și ei vor veni împreună din țara de la nord în țara pe care am dat-o ca moștenire părinților voștri.
19 “Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
Dar eu am spus: Cum să te pun printre copii și să îți dau o țară plăcută, o moștenire frumoasă a oștirilor națiunilor? Și am mai spus: Mă vei numi: Tatăl meu; și nu te vei întoarce de la mine.
20 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
Cu adevărat precum o soție cu perfidie se depărtează de soțul ei, tot astfel v-ați purtat voi cu perfidie cu mine, casă a lui Israel, spune DOMNUL.
21 A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
O voce s-a auzit pe înălțimi, plâns și cereri ale copiilor lui Israel, pentru că și-au pervertit calea și l-au uitat pe DOMNUL Dumnezeul lor.
22 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
Întoarceți-vă, voi copii decăzuți, eu vă voi vindeca decăderile. Iată, noi venim la tine, pentru că tu ești DOMNUL Dumnezeul nostru.
23 Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
Cu adevărat în zadar se așteaptă salvare de la dealuri și de la mulțimea munților. Cu adevărat în DOMNUL Dumnezeul nostru este salvarea lui Israel.
24 Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Fiindcă rușinea a mistuit munca părinților noștri din tinerețea noastră: turmele lor și cirezile lor, pe fiii lor și pe fiicele lor.
25 Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
Noi zăcem în rușinea noastră și ocara noastră ne acoperă, pentru că am păcătuit împotriva DOMNULUI Dumnezeul nostru, noi și părinții noștri, din tinerețea noastră și până în această zi și nu am ascultat de vocea DOMNULUI Dumnezeul nostru.

< Jeremiah 3 >