< Jeremiah 3 >

1 “Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
E korerotia ana, kite whakarerea e te tangata tana wahine, a ka haere atu ia i tona taha, ka riro i te tane ke, e hoki ano ranei ia ki a ia? E kore ianei taua whenua e poke rawa? Ko koe ia kua kairau ki nga hoa tokomaha: na, hoki mai ki ahau, e a i ta Ihowa.
2 “Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
Kia ara ou kanohi ki nga pukepuke moremore, tirohia; ko tehea te wahi i kore ai koe e puremutia? Nohoia atu ana ratou e koe i nga ara, pera ana me te Arapi i te koraha; a poke iho i a koe te whenua i ou kairautanga, i tau mahi kino.
3 Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
Na reira i kaiponuhia ai nga ua, kahore hoki he ua o muri; engari he rae tou no te wahine kairau, e whakakahore ana ki te whakama.
4 Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
E kore ianei koe e karanga ki ahau i nga wa a muri nei, E toku papa, ko koe te kaiarahi o toku taitamarikitanga?
5 Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
E mau ranei tona riri a ake ake? E whakapumautia tonutia ranei e ia? Nana, kua korerotia e koe, kua mahia nga mea kino, kua rite ki tau.
6 Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
I ki mai ano a Ihowa ki ahau i nga ra o Kingi Hohia, Kua kite ranei koe i nga mahi a Iharaira tahuri ke? kua haere ia ki runga ki nga maunga tiketike katoa, ki raro i nga rakau kouru nui katoa, ki reira kairau ai.
7 Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
I mea ano ahau i muri i tana meatanga i enei mea katoa, Ka hoki mai ia ki ahau; heoi kihai ia i hoki mai, me te titiro ano tona tuakana tinihanga, a Hura.
8 Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
A i kite ahau, i taku peinga atu i a Iharaira tahuri ke mo taua take nei ano, mo tona puremutanga, a i taku hoatutanga he pukapuka whakarere ki a ia, na kihai tona tuakana, a Hura tinihanga i wehi; heoi haere ana ano ia, kairau ana.
9 Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
Na, ko te otinga, kua poke te whenua i te rongo o tona puremutanga, puremu ana ia ki te kohatu, ki te rakau.
10 Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
Na ahakoa ko tenei katoa, kihai i whakapaua te ngakau o tona tuakana tinihanga, o Hura, ki te hoki ki ahau; he hoki teka kau ia, e ai ta Ihowa.
11 Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
Na ka mea a Ihowa ki ahau, A Iharaira tahuri ke, nui atu tana whakatika i a ia i ta Hura, i ta te mea tinihanga.
12 Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
Haere, karangatia enei kupu whaka te raki, mea atu, Hoki mai, e Iharaira tahuri ke, e ai ta Ihowa; e kore ahau e mea i toku riri kia tau ki a koutou; he atawhai hoki ahau, e ai ta Ihowa, e kore ahau e mauahara tonu.
13 Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
Whakina kautia tou he, ara kua kino koe ki a Ihowa, ki tou Atua, kua whakamararatia atu e koe ou ara ki nga tangata ke i raro i nga rakau kouru nui katoa, kihai ano i rongo ki toku reo, e ai ta Ihowa.
14 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
Hoki mai, e nga tamariki tahuri ke, e ai ta Ihowa; kua marenatia hoki koutou e ahau: a ka tangohia koutou e ahau, tetahi i roto i te pa, tokorua hoki i roto i te hapu, ka kawea ano koutou e ahau ki Hiona.
15 Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
A ka hoatu e ahau he hepara mo koutou, ko aku i pai ai, ka whangaia ano koutou e ratou ki te matauranga, ki te whakaaro pai.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
A tenei ake, ina nui, ina hua koutou ki te whenua i aua ra e ai ta Ihowa, heoi ano a ratou kianga ake, Ko te aaka o te kawenata a Ihowa; e kore ano e puta ake ki te ngakau; e kore hoki e maharatia taua mea e ratou, e kore ano ratou e haereere ki reira, kahore hoki he mahinga pera i muri iho.
17 Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
I taua wa ka kiia e ratou a Hiruharama, ko te torona o Ihowa; a ka huihuia nga iwi katoa ki reira, ki te ingoa o Ihowa, ki Hiruharama; a heoi ano to ratou haere i runga i te maro o o ratou ngakau kino.
18 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
I aua ra ka haere tahi te whare o Hura raua ko te whare o Iharaira, ka huihuia ano to ratou haere mai i te whenua i te raki, ki te whenua i hoatu e ahau hei kainga tupu ki o koutou matua.
19 “Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
I mea ano ahau, Me pehea e oti ai koe te whakauru e ahau ki nga tamariki, e hoatu ai e ahau ki a koe he whenua e minaminatia ana, he kainga tupu, he wahi ataahua no nga mano o nga iwi? i mea ano ahau, ka karangatia ahau e koe, E toku papa, e kor e ano koe e tahuri atu i te whai i ahau.
20 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
Rite rawa ki ta te wahine i whakarere tinihanga i tana tahu ta koutou mahi tinihanga ki ahau, e te whare o Iharaira, e ai ta Ihowa?
21 A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
E rangona ana he reo i runga i nga puke moremore, ko te tangi, ko nga inoi hoki a nga tama a Iharaira; mo ratou i whakaparori ke i to ratou ara, wareware ake i a ratou a Ihowa, to ratou Atua.
22 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
Hoki mai, e nga tamariki tahuri ke, maku e rongoa o koutou tahuritanga ketanga. Tenei matou te haere atu nei ki a koe; ko koe hoki a Ihowa, to matou Atua.
23 Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
He pono, he hori kau te awhina e taria ana mai i nga pukepuke, te nge i runga i nga maunga: tika rawa kei a Ihowa, kei to tatou Atua te whakaora mo Iharaira.
24 Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Kua pau hoki i te mea whakama te mauiui o o tatou matua, no to tatou tamarikitanga ake ano; a ratou hipi, a ratou kau, a ratou tama, me a ratou tamahine.
25 Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
Takoto tatou i roto i to tatou whakama, ma to tatou matangerengere tatou e hipoki: kua hara hoki tatou ki a Ihowa, ki to tatou Atua, tatou ko o tatou matua, no to tatou tamarikitanga ake ano a mohoa noa nei; kihai hoki tatou i rongo ki te reo o Ihowa, o to tatou Atua.

< Jeremiah 3 >