< Jeremiah 3 >

1 “Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
On dit ordinairement: Si un homme renvoie sa femme, et que, se séparant de lui, elle épouse un autre homme, la reprendra-t-il ensuite? est-ce qu’elle ne sera pas impure et souillée, cette femme? mais toi tu as forniqué avec beaucoup d’amants; cependant, reviens à moi, dit le Seigneur, et moi je te recevrai.
2 “Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
Lève les yeux en haut, et vois où tu ne te sois pas prostituée; tu étais assise sur les chemins, les attendant comme un voleur attend les passants dans la solitude; et tu as souillé la terre par tes fornications et par tes méchancetés.
3 Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
Ce qui a été cause que les gouttes des pluies ont été retenues, et qu’il n’y a pas eu de pluie de l’arrière-saison; le front d’une femme de mauvaise vie est devenu le tien; tu n’as pas voulu rougir.
4 Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
Ainsi au moins maintenant, appelle-moi; et dis: Mon père et le guide de ma virginité, c’est vous.
5 Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
Est-ce que vous serez irrité pour toujours, ou persévérerez-vous jusqu’à la fin? Voilà que tu as parlé, et tu as fait le mal, et tu as prévalu.
6 Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
Et le Seigneur me dit dans les jours du roi Josias: Est-ce que tu n’as pas vu ce qu’a fait la rebelle Israël? elle s’en est allée sur toute montagne, et sous tout arbre touffu, et là, elle a forniqué.
7 Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
Et j’ai dit, lorsqu’elle a eu fait toutes ces choses: Reviens à moi, et elle n’est pas revenue. Et sa sœur, la prévaricatrice Juda, a vu
8 Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
Que parce que la rebelle Israël avait été adultère, je l’avais renvoyée, et que je lui avais donné un acte de répudiation; elle n’a pas craint, la prévaricatrice Juda, sa sœur, mais elle s’en est allée, et elle a forniqué aussi elle-même.
9 Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
Et par la facilité de sa fornication elle a souillé la terre, et elle a commis l’adultère avec la pierre et le bois.
10 Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
Et au milieu de toutes ces choses, la prévaricatrice Juda, sa sœur, n’est pas revenue à moi de tout son cœur, mais avec mensonge, dit le Seigneur.
11 Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
Et le Seigneur me dit: Elle a justifié son âme, la rebelle Israël, en comparaison de la prévaricatrice Juda.
12 Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
Va, et crie ces paroles contre l’aquilon, et tu diras: Reviens, rebelle Israël, dit le Seigneur, et je ne détournerai pas ma face de vous, parce que moi, je suis saint, dit le Seigneur, et je ne serai pas irrité pour toujours.
13 Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
Mais reconnais ton iniquité, parce que tu as prévariqué contre le Seigneur ton Dieu; que tu as dispersé tes voies pour des étrangers, sous tout arbre touffu, et que tu n’as pas écouté ma voix, dit le Seigneur.
14 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
Convertissez-vous, mes fils, en revenant vers moi, dit le Seigneur; parce que je suis votre époux; je vous prendrai, un d’une cité, deux d’une famille, et je vous introduirai dans Sion.
15 Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
Et je vous donnerai des pasteurs selon mon cœur, et ils vous nourriront de science et de doctrine.
16 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
Et lorsque vous vous serez multipliés, et que vous aurez crû sur la terre en ces jours-là, dit le Seigneur, on ne dira plus: L’arche d’alliance du Seigneur; elle ne montera pas sur le cœur, on ne se la rappellera pas, elle ne sera pas visitée, et on ne la refera plus.
17 Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
En ce temps-là, on appellera Jérusalem le trône du Seigneur, et toutes les nations s’y rassembleront au nom du Seigneur, dans Jérusalem, et elles ne courront pas après la perversité de leur cœur très mauvais.
18 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
En ces jours-là, la maison de Juda ira vers la maison d’Israël, et elles viendront ensemble de la terre de l’aquilon dans la terre que j’ai donnée à vos pères.
19 “Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
Pour moi, j’ai dit: Comment te placerai-je parmi mes fils? et te donnerai-je une terre désirable, le bel héritage des armées des nations? Et j’ai dit: Tu m’appelleras ton père, et tu ne cesseras pas de marcher après moi.
20 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
Mais comme si une femme méprisait celui qui l’aime, ainsi m’a méprisé la maison d’Israël, dit le Seigneur,
21 A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
Une voix sur les chemins a été entendue, le pleur et le hurlement des fils d’Israël; parce qu’ils ont rendu inique leur voie, ils ont oublié le Seigneur leur Dieu.
22 “Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
Convertissez-vous, mes fils, en revenant vers moi, et je réparerai vos défections. Nous voici, nous venons à vous; car c’est vous qui êtes le Seigneur notre Dieu.
23 Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
Vraiment menteuses étaient les collines et la multitude des montagnes; vraiment, c’est dans le Seigneur notre Dieu qu’est le salut d’Israël.
24 Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
Dès notre jeunesse la confusion a dévoré le travail de nos pères, leurs troupeaux de menu bétail, et leurs troupeaux de gros bétail, leurs fils et leurs filles.
25 Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
Nous dormirons dans notre confusion, et notre ignominie nous couvrira, parce que contre le Seigneur notre Dieu nous avons péché, nous et nos pères, depuis notre jeunesse jusqu’à ce jour, et que nous n’avons pas entendu la voix du Seigneur notre Dieu.

< Jeremiah 3 >