< Jeremiah 29 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
A to [są] słowa listu, który prorok Jeremiasz posłał z Jerozolimy do pozostałych starszych, którzy byli na wygnaniu, i do kapłanów, do proroków i do całego ludu – których Nabuchodonozor uprowadził z Jerozolimy do Babilonu.
2 Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
[Było to] po wyjściu z Jerozolimy króla Jechoniasza, królowej, dworzan, książąt Judy i Jerozolimy oraz cieśli i kowali.
3 Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
[List] w[ysłał] przez Elasę, syna Szafana, i Gemariasza, syna Chilkiasza, których Sedekiasz, król Judy, posłał do Babilonu do Nabuchodonozora, króla Babilonu; [był on] tej treści:
4 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela, do wszystkich wygnańców, których uprowadziłem z Jerozolimy do Babilonu:
5 “Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
Budujcie domy i mieszkajcie [w nich]; zakładajcie ogrody i spożywajcie ich owoce;
6 Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
Pojmujcie żony i płodźcie synów i córki; wybierajcie żony dla waszych synów i wydawajcie swoje córki za mąż, aby rodziły synów i córki. Rozmnażajcie się tam i niech was nie ubywa.
7 Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
Zabiegajcie o pokój dla tego miasta, do którego was uprowadziłem, i módlcie się za nie do PANA, bo od jego pokoju zależy wasz pokój.
8 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
Tak bowiem mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Niech was nie zwodzą wasi prorocy i wróżbici, którzy [są] wśród was, i nie zwracajcie uwagi na wasze sny, które się wam śnią.
9 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
Bo oni prorokują wam kłamliwie w moje imię. Nie posłałem ich, mówi PAN.
10 Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
Tak bowiem mówi PAN: Gdy wypełni się dla Babilonu siedemdziesiąt lat, nawiedzę was i spełnię wobec was swoje dobre słowo, by was sprowadzić z powrotem na to miejsce.
11 Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
Gdyż ja znam myśli, które mam o was, mówi PAN: myśli o pokoju, a nie o utrapieniu, aby zapewnić wam koniec, jakiego oczekujecie.
12 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
Wtedy będziecie mnie wzywać, pójdziecie i będziecie modlić się do mnie, a ja was wysłucham;
13 Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
Będziecie mnie szukać i znajdziecie [mnie], gdy będziecie szukać całym swym sercem.
14 Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
I dam wam się znaleźć, mówi PAN, i odwrócę waszą niewolę, i zgromadzę was ze wszystkich narodów i ze wszystkich miejsc, do których was wygnałem, mówi PAN. I przyprowadzę was na [to] miejsce, z którego was uprowadziłem.
15 Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
A ponieważ mówicie: PAN wzbudził nam proroków w Babilonie;
16 Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
Tak mówi PAN o królu, który zasiada na tronie Dawida, i o całym ludzie, który mieszka w tym mieście, o waszych braciach, którzy nie poszli z wami do niewoli;
17 bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
Tak mówi PAN zastępów: Oto poślę na nich miecz, głód i zarazę i uczynię z nimi jak ze złymi figami, których nie można jeść, bo są tak złe.
18 Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
Będę ich bowiem prześladować mieczem, głodem i zarazą i sprawię, że zostaną wysiedleni do wszystkich królestw ziemi, uczynię ich [przedmiotem] przekleństwa, zdumienia, poświstania i hańby wśród wszystkich narodów, do których ich wypędziłem;
19 Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
Za to, że nie słuchali moich słów, mówi PAN, które posłałem do nich przez swoje sługi, proroków, z wczesnym wstawaniem i przesłaniem. Ale nie słuchaliście, mówi PAN.
20 Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
Dlatego słuchajcie słowa PANA, wy, wszyscy wygnańcy, których wysłałem z Jerozolimy do Babilonu.
21 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela, o Achabie, synu Kolajasza, i o Sedekiaszu, synu Maasejasza, którzy prorokują wam kłamstwo w moje imię: Oto wydam ich w ręce Nabuchodonozora, króla Babilonu, a ten zabije ich na waszych oczach.
22 Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
Od nich będzie wzięte przekleństwo przez wszystkich wygnańców z Judy, którzy są w Babilonie, [wyrażone] w słowach: Niech PAN ci uczyni jak z Sedekiaszem i jak z Achabem, których król Babilonu usmażył w ogniu;
23 Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
Za to, że popełniali nikczemność w Izraelu, cudzołożyli z żonami swoich bliźnich i mówili słowa kłamliwe w moje imię, czego im nie nakazałem. Ja o tym wiem i [jestem tego] świadkiem, mówi PAN.
24 Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
A do Szemajasza Nechalamity powiesz:
25 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Ponieważ we własnym imieniu posłałeś listy do całego ludu, który [jest] w Jerozolimie, i do Sofoniasza, syna Maasejasza, kapłana, i do wszystkich kapłanów, tej treści:
26 ‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
PAN ustanowił cię kapłanem w miejsce kapłana Jehojady i abyście mieli nadzór w domu PANA nad każdym szaleńcem udającym proroka, abyś osadzał takiego w więzieniu i zakuwał w dyby.
27 Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
Dlaczego więc nie skarciłeś Jeremiasza z Anatot, który wam prorokuje?
28 Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’”
Posłał bowiem do nas do Babilonu słowo: Będzie to trwało długo. Budujcie domy i mieszkajcie [w nich], zakładajcie ogrody i spożywajcie ich owoce.
29 Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
A kapłan Sofoniasz odczytał ten list do uszu proroka Jeremiasza.
30 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
I doszło słowo PANA do Jeremiasza mówiące:
31 “Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
Poślij do wszystkich uprowadzonych do niewoli takie słowa: Tak mówi PAN o Szemajaszu Nechalamicie: Ponieważ Szemajasz prorokował wam, chociaż ja go nie posłałem, a wywołuje w was ufność w kłamstwo;
32 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’”
Dlatego tak mówi PAN: Oto nawiedzę Szemajasza Nechalamitę i jego potomstwo. Nie będzie miał nikogo, kto by mieszkał pośród [tego] ludu, ani nie ujrzy tego dobra, które uczynię swemu ludowi, mówi PAN, bo głosił bunt przeciwko PANU.

< Jeremiah 29 >