< Jeremiah 29 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
Nämä ovat sen kirjeen sanat, jonka profeetta Jeremia lähetti Jerusalemista pakkosiirtolaisten vanhimmille, mikä heitä vielä oli jäljellä, papeille ja profeetoille sekä kaikelle kansalle, jotka Nebukadnessar oli siirtänyt Jerusalemista pois Baabeliin,
2 Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
sen jälkeen kuin kuningas Jekonja ja kuninkaan äiti, hoviherrat, Juudan ja Jerusalemin ruhtinaat sekä sepät ja lukkosepät olivat lähteneet Jerusalemista.
3 Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
Hän lähetti kirjeen Elasan, Saafanin pojan, ja Gemarjan, Hilkian pojan, mukana, jotka Sidkia, Juudan kuningas, lähetti Nebukadnessarin, Baabelin kuninkaan, tykö Baabeliin; se kuului näin:
4 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
"Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala, kaikille pakkosiirtolaisille, jotka minä olen siirtänyt Jerusalemista pois Baabeliin:
5 “Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
Rakentakaa taloja ja asukaa niissä, istuttakaa puutarhoja ja syökää niiden hedelmiä.
6 Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
Ottakaa itsellenne vaimoja ja siittäkää poikia ja tyttäriä; ottakaa pojillenne vaimoja ja naittakaa tyttärenne, että he synnyttäisivät poikia ja tyttäriä. Lisääntykää siellä älkääkä vähentykö.
7 Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
Ja harrastakaa sen kaupungin menestystä, johon minä olen teidät siirtänyt, ja rukoilkaa sen puolesta Herraa, sillä sen menestys on teidän menestyksenne.
8 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
Sillä näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Älkää antako profeettainne, joita on keskuudessanne, ja tietäjäinne pettää itseänne, älkääkä totelko unianne, joita te uneksutte.
9 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
Sillä valhetta he ennustavat teille minun nimessäni; minä en ole lähettänyt heitä, sanoo Herra.
10 Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
Sillä näin sanoo Herra: Vasta kun ne seitsemänkymmentä Baabelin vuotta ovat täyttyneet, minä katson teidän puoleenne ja panen täytäntöön teitä kohtaan hyvän lupaukseni ja palautan teidät tähän paikkaan.
11 Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
Sillä minä tunnen ajatukseni, jotka minulla on teitä kohtaan, sanoo Herra: rauhan eikä turmion ajatukset; minä annan teille tulevaisuuden ja toivon.
12 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
Silloin te huudatte minua avuksenne, tulette ja rukoilette minua, ja minä kuulen teitä.
13 Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
Te etsitte minua ja löydätte minut, kun te etsitte minua kaikesta sydämestänne.
14 Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
Ja niin minä annan teidän löytää itseni, sanoo Herra, ja minä käännän teidän kohtalonne ja kokoan teidät kaikista kansoista ja kaikista paikoista, joihin olen teidät karkoittanut, sanoo Herra, ja palautan teidät tähän paikkaan, josta minä siirsin teidät pois.
15 Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
Jos te sanotte: 'Herra on herättänyt meille profeettoja Baabelissa',
16 Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
niin sanoo Herra näin kuninkaasta, joka istuu Daavidin valtaistuimella, ja kaikesta kansasta, joka asuu tässä kaupungissa, teidän veljistänne, joiden ei täytynyt lähteä teidän kanssanne pakkosiirtolaisuuteen:
17 bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
Näin sanoo Herra Sebaot: Katso, minä lähetän heidän sekaansa miekan, nälän ja ruton ja teen heidät inhottaviksi kuin viikunat, jotka ovat niin huonoja, ettei niitä voi syödä.
18 Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
Ja minä ajan heitä takaa miekalla, nälällä ja rutolla ja teen heidät kauhuksi kaikille valtakunnille maan päällä, kiroukseksi ja kauhistukseksi, ivan vihellykseksi ja häväistykseksi kaikkien kansojen keskuudessa, mihin minä heidät karkoitan,
19 Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
sentähden etteivät he kuulleet minun sanojani, sanoo Herra, kun minä lähetin heidän tykönsä palvelijoitani, profeettoja, varhaisesta alkaen. Te ette ole kuulleet, sanoo Herra.
20 Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
Mutta kuulkaa te Herran sana, kaikki te pakkosiirtolaiset, jotka minä olen lähettänyt Jerusalemista Baabeliin.
21 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala, Ahabista, Koolajan pojasta, ja Sidkiasta, Maasejan pojasta, jotka ennustavat teille minun nimessäni valhetta: Katso, minä annan heidät Nebukadressarin, Baabelin kuninkaan, käsiin, ja hän lyö heidät kuoliaaksi teidän silmäinne edessä.
22 Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
Ja heistä tulee kiroussana kaikille Juudan pakkosiirtolaisille, jotka ovat Baabelissa; sanotaan: 'Herra tehköön sinulle niinkuin Sidkialle ja Ahabille, jotka Baabelin kuningas korvensi tulessa'.
23 Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
Sillä he ovat tehneet häpeällisen teon Israelissa, ovat tehneet huorin lähimmäistensä vaimojen kanssa ja puhuneet minun nimessäni valhepuhetta, jota minä en ole käskenyt heidän puhua. Minä olen se, joka sen tiedän ja todistan, sanoo Herra."
24 Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
Ja nehelamilaiselle Semajalle puhu, sanoen:
25 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
"Näin sanoo Herra Sebaot, Israelin Jumala: Sentähden että sinä olet lähettänyt omassa nimessäsi tämän kirjeen kaikelle kansalle, joka on Jerusalemissa, ja pappi Sefanjalle, Maasejan pojalle, ja kaikille papeille:
26 ‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
Herra on asettanut sinut papiksi pappi Joojadan sijaan, että olisi järjestyksen valvojia Herran temppelissä kaikkien hullujen ja ennustajain varalle, ja niin sinä voit panna sellaiset jalkapuuhun ja kaularautaan.
27 Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
Miksi et siis ole nuhdellut anatotilaista Jeremiaa, joka ennustaa teille?
28 Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’”
Niinpä hän on saattanut lähettää meille Baabeliin tämän sanan: 'Se kestää vielä kauan. Rakentakaa taloja ja asukaa niissä, istuttakaa puutarhoja ja syökää niiden hedelmiä.'"
29 Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
Ja pappi Sefanja luki tämän kirjeen profeetta Jeremian kuullen.
30 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
Silloin tuli Jeremialle tämä Herran sana:
31 “Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
"Lähetä kaikille pakkosiirtolaisille tämä sana: Näin sanoo Herra nehelamilaisesta Semajasta: Koska Semaja on ennustanut teille, vaikka minä en ole lähettänyt häntä, ja saattanut teidät turvaamaan valheeseen,
32 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’”
sentähden, näin sanoo Herra: Katso, minä kostan nehelamilaiselle Semajalle ja hänen jälkeläisillensä. Hänellä ei ole oleva ketään, joka saa asua tämän kansan keskuudessa, eikä hän ole näkevä sitä hyvää, jonka minä teen kansalleni, sanoo Herra; sillä hän on julistanut luopumusta Herrasta."

< Jeremiah 29 >